Add parallel Print Page Options

Ẹ̀bùn fún kíkọ́ ilé Olúwa

29 Nígbà náà, ọba Dafidi sọ fún gbogbo àpéjọ pé: “Ọmọ mi Solomoni, èyí tí Ọlọ́run ti yàn, sì kéré ó sì jẹ́ aláìmòye. Iṣẹ́ náà tóbi, nítorí ìkọ́lé bí ti ààfin kì í ṣe fún ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa Ọlọ́run. Pẹ̀lú gbogbo ìrànlọ́wọ́ mi èmi ti pèsè fún ilé Ọlọ́run mi wúrà fún iṣẹ́ wúrà, fàdákà fún ti fàdákà, idẹ fún ti idẹ, irin fún ti irin àti igi fún ti igi àti òkúta oníyebíye fún títọ́ rẹ̀, òkúta lóríṣìíríṣìí, àwọ̀ àti oríṣìíríṣìí ẹ̀yà òkúta àti òkúta dáradára kan gbogbo wọ̀nyí ní iye púpọ̀. Yàtọ̀ fún èyí, nínú ìfọkànsìn mi sí ilé Ọlọ́run mi, èmí fi ìṣúra mi tìkára mi ti wúrà àti fàdákà fún ilé Ọlọ́run mi. Jù gbogbo rẹ̀ lọ, èmi ti pèsè fún ilé mímọ́ ti Olúwa yìí: Ẹgbẹ̀rún mẹ́ta (3,000) tálẹ́ǹtì wúrà, ti wúrà ofiri àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin (7,000) tálẹ́ǹtì fàdákà dídára, fún bíbo àwọn ògiri ilé náà. Fún iṣẹ́ wúrà àti fàdákà náà, àti fún oríṣìí iṣẹ́ ti ó yẹ ní ṣíṣe nípasẹ̀ àwọn tí ó ní òye oríṣìíríṣìí iṣẹ́. Nísinsin yìí, ta ni ó ní ìfẹ́ sí yíya ará rẹ̀ sọ́tọ̀ lónìí sí Olúwa?”

Nígbà náà àwọn aṣáájú àwọn ìdílé, àwọn ìjòyè àwọn ẹ̀yà Israẹli, àwọn alákòóso ẹgbẹgbẹ̀wàá àti alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn oníṣẹ́ tí ó wà ní ìdí iṣẹ́ ọba ní ìfẹ́ sí i. Wọ́n fi sílẹ̀ fún iṣẹ́ lórí ilé Ọlọ́run, ẹgbẹ̀rún márùn-ún tálẹ́ǹtì àti ẹgbẹ̀rin mẹ́wàá wúrà, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá tálẹ́ǹtì fàdákà, ẹgbẹ̀rin méjì-dínlógún tálẹ́ǹtì idẹ àti ọgọ́rin ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì irin. Ẹnikẹ́ni tí ó ní òkúta iyebíye fi wọn sí ilé ìṣúra ilé Ọlọ́run ní abẹ́ ìtọ́jú Jehieli ará Gerṣoni. Àwọn ènìyàn láyọ̀ nínú ìṣesí àtọkànwá fi sílẹ̀ àwọn olórí wọn, nítorí tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ọ̀fẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn sí Olúwa. Dafidi ọba pẹ̀lú yọ̀ gidigidi.

Àdúrà Dafidi

10 Dafidi yin Olúwa níwájú gbogbo àwọn tí ó péjọ, wí pé,

“Ìyìn ni fún Ọ, Olúwa,
    Ọlọ́run baba a wa Israẹli,
    láé àti láéláé.
11 Tìrẹ Olúwa ni títóbi àti agbára pẹ̀lú ìyìn
    àti ọláńlá àti dídán,
    nítorí tí gbogbo nǹkan ní ọ̀run àti ayé jẹ́ tìrẹ.
Tìrẹ Olúwa ni ìjọba;
    a gbé ọ ga gẹ́gẹ́ bí orí lórí ohun gbogbo.
12 Ọlá àti ọ̀wọ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Rẹ;
    ìwọ ni alákòóso gbogbo nǹkan.
Ní ọwọ́ rẹ ni ipá àti agbára wà láti gbéga àti
    láti fi agbára fún ohun gbogbo.
13 Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, àwa fi ọpẹ́ fún Ọ,
    a sì fi ìyìn fún orúkọ rẹ̀ tí ó lógo.

14 “Ṣùgbọ́n ta ni èmi, àti ta ni àwọn ènìyàn mi, tí a fi lè ṣe ìrànlọ́wọ́ tinútinú bí irú èyí? Gbogbo nǹkan wá láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ti wá, àwa sì ti fífún ọ láti ara ohun tí ó wá láti ọwọ́ rẹ. 15 Àwa jẹ́ àjèjì àti àlejò ní ojú rẹ gẹ́gẹ́ bí baba ńlá a wa, àwọn ọjọ́ wa lórí ilẹ̀ ayé rí bí òjìji láìsí ìrètí. 16 Olúwa Ọlọ́run wa tí fi gbogbo púpọ̀ yìí tí àwa ti pèsè fún kíkọ́ ilé Olúwa fun orúkọ, mímọ́ rẹ̀, ó wá láti ọwọ́ ọ̀ rẹ, gbogbo rẹ̀ sì jẹ́ tirẹ̀. 17 Èmi mọ̀ Ọlọ́run mi, wí pé ìwọ̀ dán ọkàn wò, ó sì tẹ́ ọ lọ́rùn pẹ̀lú òtítọ́ inú. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti fi sílẹ̀ pẹ̀lú tìfẹ́tìfẹ́ pẹ̀lú òtítọ́. Nísinsin yìí èmi ti rí i pẹ̀lú ayọ̀ bí àwọn ènìyàn yìí tí ó wà níbí ti fi fún ọ pẹ̀lú tìfẹ́tìfẹ́. 18 Olúwa Ọlọ́run àwọn baba a wa Abrahamu, Isaaki àti Israẹli pa ìfẹ́ yìí mọ́ nínú ọkàn àwọn ènìyàn rẹ títí láé pẹ̀lú pípa ọkàn mọ́ lóòtítọ́ sí ọ. 19 Àti fún ọmọ mi Solomoni ní ìfọkànsìn tòótọ́ láti pa àṣẹ rẹ mọ́ àwọn ohun tí ó nílò àti òfin àti láti ṣe ohun gbogbo láti kọ́ ààfin bí ti ọba fún èyí tí mo ti pèsè.”

20 Dafidi sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn pé, Nísinsin yìí, ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín. Gbogbo ènìyàn sì fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì tẹ orí wọn ba, wọ́n wólẹ̀ fún Olúwa àti ọba.

A yan Solomoni gẹ́gẹ́ bí ọba

21 Ni ọjọ́ kejì, wọ́n rú ẹbọ sí Olúwa, wọ́n sì rú ẹbọ sísun sí i: ẹgbẹ̀rún kan akọ màlúù, ẹgbẹ̀rin kan àgbò, àti ẹgbẹ̀rin kan akọ ọ̀dọ́-àgùntàn. Lápapọ̀ pẹ̀lú ọrẹ mímu àti àwọn ẹbọ mìíràn ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún gbogbo Israẹli. 22 Wọ́n jẹ wọ́n sì mu pẹ̀lú ayọ̀ kíkún ní iwájú Olúwa ní ọjọ́ náà.

Nígbà náà wọ́n yan Solomoni ọmọ Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba lẹ́ẹ̀kejì wọ́n fi ààmì òróró yàn án níwájú Olúwa láti ṣe olórí àti Sadoku láti ṣe àlùfáà. 23 (A)Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni jókòó lórí ìtẹ́ Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọba ní ipò baba a rẹ̀ Dafidi. O ṣe àṣeyọrí, gbogbo Israẹli sì gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu. 24 Gbogbo àwọn ìjòyè àti àwọn ọkùnrin alágbára, pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọba Dafidi tẹrí ara wọn ba fún ọba Solomoni.

25 Olúwa gbé Solomoni ga púpọ̀ ní ojú gbogbo Israẹli, ó sì kẹ́ ẹ ní ìkẹ́ ọláńlá, ní irú èyí tí a kò kẹ́ ọba kankan ṣáájú rẹ̀ tí ó jẹ lórí Israẹli.

Ikú Dafidi

26 Dafidi ọmọ Jese jẹ́ ọba lórí gbogbo Israẹli. 27 Ó jẹ ọba lórí Israẹli fún ogójì ọdún; ọdún méje ni ó jẹ ọba ní Hebroni, ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu. 28 Òun sì darúgbó, ó sì kú ikú rere, ó gbádùn ẹ̀mí gígùn, ọlá àti ọrọ̀. Solomoni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

29 Ní ti ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba ọba Dafidi, láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin, a kọ wọ́n sínú ìwé ìrántí ti Samuẹli aríran, ìwé ìrántí ti Natani wòlíì àti ìwé ìrántí ti Gadi aríran, 30 lápapọ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti agbára rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìgbà tí ó kọjá lórí rẹ̀, àti lórí Israẹli, àti lórí gbogbo àwọn ìjọba gbogbo ilẹ̀ náà.

Gifts for Building the Temple

29 Then King David said to the whole assembly: “My son Solomon, the one whom God has chosen, is young and inexperienced.(A) The task is great, because this palatial structure is not for man but for the Lord God. With all my resources I have provided for the temple of my God—gold(B) for the gold work, silver for the silver, bronze for the bronze, iron for the iron and wood for the wood, as well as onyx for the settings, turquoise,[a](C) stones of various colors, and all kinds of fine stone and marble—all of these in large quantities.(D) Besides, in my devotion to the temple of my God I now give my personal treasures of gold and silver for the temple of my God, over and above everything I have provided(E) for this holy temple: three thousand talents[b] of gold (gold of Ophir)(F) and seven thousand talents[c] of refined silver,(G) for the overlaying of the walls of the buildings, for the gold work and the silver work, and for all the work to be done by the craftsmen. Now, who is willing to consecrate themselves to the Lord today?”

Then the leaders of families, the officers of the tribes of Israel, the commanders of thousands and commanders of hundreds, and the officials(H) in charge of the king’s work gave willingly.(I) They(J) gave toward the work on the temple of God five thousand talents[d] and ten thousand darics[e] of gold, ten thousand talents[f] of silver, eighteen thousand talents[g] of bronze and a hundred thousand talents[h] of iron. Anyone who had precious stones(K) gave them to the treasury of the temple of the Lord in the custody of Jehiel the Gershonite.(L) The people rejoiced at the willing response of their leaders, for they had given freely and wholeheartedly(M) to the Lord. David the king also rejoiced greatly.

David’s Prayer

10 David praised the Lord in the presence of the whole assembly, saying,

“Praise be to you, Lord,
    the God of our father Israel,
    from everlasting to everlasting.
11 Yours, Lord, is the greatness and the power(N)
    and the glory and the majesty and the splendor,
    for everything in heaven and earth is yours.(O)
Yours, Lord, is the kingdom;
    you are exalted as head over all.(P)
12 Wealth and honor(Q) come from you;
    you are the ruler(R) of all things.
In your hands are strength and power
    to exalt and give strength to all.
13 Now, our God, we give you thanks,
    and praise your glorious name.

14 “But who am I, and who are my people, that we should be able to give as generously as this?(S) Everything comes from you, and we have given you only what comes from your hand.(T) 15 We are foreigners and strangers(U) in your sight, as were all our ancestors. Our days on earth are like a shadow,(V) without hope. 16 Lord our God, all this abundance that we have provided for building you a temple for your Holy Name comes from your hand, and all of it belongs to you. 17 I know, my God, that you test the heart(W) and are pleased with integrity. All these things I have given willingly and with honest intent. And now I have seen with joy how willingly your people who are here have given to you.(X) 18 Lord, the God of our fathers Abraham, Isaac and Israel, keep these desires and thoughts in the hearts of your people forever, and keep their hearts loyal to you. 19 And give my son Solomon the wholehearted devotion(Y) to keep your commands, statutes and decrees(Z) and to do everything to build the palatial structure for which I have provided.”(AA)

20 Then David said to the whole assembly, “Praise the Lord your God.” So they all praised the Lord, the God of their fathers; they bowed down, prostrating themselves before the Lord and the king.

Solomon Acknowledged as King(AB)

21 The next day they made sacrifices to the Lord and presented burnt offerings to him:(AC) a thousand bulls, a thousand rams and a thousand male lambs, together with their drink offerings, and other sacrifices in abundance for all Israel.(AD) 22 They ate and drank with great joy(AE) in the presence of the Lord that day.

Then they acknowledged Solomon son of David as king a second time, anointing him before the Lord to be ruler and Zadok(AF) to be priest. 23 So Solomon sat(AG) on the throne(AH) of the Lord as king in place of his father David. He prospered and all Israel obeyed him. 24 All the officers and warriors, as well as all of King David’s sons,(AI) pledged their submission to King Solomon.

25 The Lord highly exalted(AJ) Solomon in the sight of all Israel and bestowed on him royal splendor(AK) such as no king over Israel ever had before.(AL)

The Death of David(AM)

26 David son of Jesse was king(AN) over all Israel.(AO) 27 He ruled over Israel forty years—seven in Hebron(AP) and thirty-three in Jerusalem.(AQ) 28 He died(AR) at a good old age, having enjoyed long life, wealth and honor. His son Solomon succeeded him as king.(AS)

29 As for the events of King David’s reign, from beginning to end, they are written in the records of Samuel the seer,(AT) the records of Nathan(AU) the prophet and the records of Gad(AV) the seer, 30 together with the details of his reign and power, and the circumstances that surrounded him and Israel and the kingdoms of all the other lands.

Footnotes

  1. 1 Chronicles 29:2 The meaning of the Hebrew for this word is uncertain.
  2. 1 Chronicles 29:4 That is, about 110 tons or about 100 metric tons
  3. 1 Chronicles 29:4 That is, about 260 tons or about 235 metric tons
  4. 1 Chronicles 29:7 That is, about 190 tons or about 170 metric tons
  5. 1 Chronicles 29:7 That is, about 185 pounds or about 84 kilograms
  6. 1 Chronicles 29:7 That is, about 380 tons or about 340 metric tons
  7. 1 Chronicles 29:7 That is, about 675 tons or about 610 metric tons
  8. 1 Chronicles 29:7 That is, about 3,800 tons or about 3,400 metric tons