Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Revised Common Lectionary (Semicontinuous)

Daily Bible readings that follow the church liturgical year, with sequential stories told across multiple weeks.
Duration: 1245 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Saamu 79:1-9

Saamu ti Asafu.

79 Ọlọ́run, àwọn orílẹ̀-èdè ti wá ilẹ̀ ìní rẹ;
    wọ́n ti ba tẹmpili mímọ́ rẹ jẹ́,
    wọn di Jerusalẹmu kù sí òkìtì àlàpà.
Wọn ti fi ara òkú àwọn ìránṣẹ́ rẹ
    fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní oúnjẹ,
    ẹran-ara àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ fún ẹranko ilẹ̀.
Wọ́n tu ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omi
    yí Jerusalẹmu ká,
    kò sì ṣí àwọn tí yóò sìn wọ́n.
Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí ó yí wa ká,
    àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wa ká.

Nígbà wo, Olúwa? Ní ìwọ ó máa bínú títí láé?
    Yóò ti pẹ́ tó ti owú rẹ yóò ha jò bí iná?
Tú ìbínú rẹ jáde sí orílẹ̀-èdè
    tí kò ní ìmọ̀ rẹ,
lórí àwọn ìjọba
    tí kò pe orúkọ rẹ;
Nítorí wọ́n ti run Jakọbu
    wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ di ahoro.

Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùn
    jẹ́ kí àánú rẹ wá kánkán láti bá wa,
    nítorí tí a rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.
Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa,
    fún ògo orúkọ rẹ;
gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì
    nítorí orúkọ rẹ.

Jeremiah 8:14-17

14 “Èéṣe tí àwa fi jókòó ní ibí yìí?
    A kó ara wa jọ!
Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi
    kí a sì ṣègbé síbẹ̀.
    Nítorí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pinnu pé a ó ṣègbé.
    Yóò sì fún wa ní omi onímájèlé mu,
    nítorí àwa ti ṣẹ̀ sí i.
15 Àwa ń retí àlàáfíà,
    kò sí ìre kan
tí ó wá ní ìgbà ìmúláradá
    bí kò ṣe ìpayà nìkan.
16 Ìró ìfọn imú ẹṣin àwọn ọlọ̀tẹ̀
    là ń gbọ́ láti Dani,
yíyan àwọn akọ ẹṣin
mú gbogbo ilẹ̀ wárìrì.
Wọ́n wá láti pa ilẹ̀ náà run,
    gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,
    ìlú náà àti gbogbo olùgbé ibẹ̀.”

17 “Wò ó, èmi yóò rán àwọn ejò olóró sí àárín yín,
    paramọ́lẹ̀ tí ẹ kò lè pa oró wọn,
yóò sì bù yín jẹ,”
    ni Olúwa wí.

Jeremiah 9:2-11

Háà, èmi ìbá ní ni aginjù
    ilé àgbàwọ̀ fún àwọn arìnrìn-àjò,
kí n ba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀
    kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn:
nítorí gbogbo wọn jẹ́ panṣágà
    àjọ aláìṣòótọ́ ènìyàn.

Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀
    bí ọfà láti fi pa irọ́;
kì í ṣe nípa òtítọ́
    ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà.
Wọ́n ń lọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn;
wọn kò sì náání mi,
    Olúwa wí.
Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ;
    má ṣe gbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹ.
Nítorí pé oníkálùkù arákùnrin jẹ́ atannijẹ,
    oníkálùkù ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì ṣí ẹni
    tó sọ òtítọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn
láti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọn
    di onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
Ó ń gbé ní àárín ẹ̀tàn
    wọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínú
ẹ̀tàn wọn,
    ni Olúwa wí.

Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí:

“Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pé
    kí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóró
    ó ń sọ ẹ̀tàn; oníkálùkù sì ń
fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí
    aládùúgbò rẹ̀; ní inú
    ọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?”
ni Olúwa wí.
    “Èmi kì yóò ha gbẹ̀san ara
    mi lórí irú orílẹ̀-èdè yìí bí?”

10 Èmi yóò sì sọkún, pohùnréré
    ẹkún fún àwọn òkè; àti ẹkún
ìrora lórí pápá oko aginjù wọ̀n-ọn-nì.
    Nítorí wọ́n di ahoro, wọn kò sì
kọjá ní ibẹ̀. A kò sì gbọ́ igbe
    ẹran ọ̀sìn, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run
    sì ti sálọ, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ẹranko sì ti lọ.

11 “Èmi yóò sì sọ Jerusalẹmu di òkìtì
    àlàpà àti ihò àwọn ìkookò.
Èmi ó sì sọ ìlú Juda di ahoro
    tí ẹnikẹ́ni kò sì ní le è gbé.”

Marku 12:41-44

Ọ̀rẹ́ opó

41 (A)Jesu jókòó ní òdìkejì kọjú sí àpótí ìṣúra: ó ń wo ìjọ ènìyàn ti ń sọ owó sínú àpótí ìṣúra, ọ̀pọ̀ àwọn ọlọ́rọ̀ sì sọ púpọ̀ sí i. 42 Ṣùgbọ́n obìnrin opó kan wà, ó sì fi ààbọ̀ owó idẹ méjì síbẹ̀, tí ì ṣe ìdá méjì owó-babà kan sínú rẹ̀.

43 Jesu pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó sọ fún wọn wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yin pé, tálákà opó yìí sọ sínú àpótí ìṣúra ju gbogbo àwọn ìyókù to sọ sínú rẹ lọ. 44 Nítorí pé, àwọn ìyókù mú nínú ọ̀pọ̀ ìní wọ́n, ṣùgbọ́n ní tirẹ̀, nínú àìní rẹ̀, ó sọ gbogbo ohun tí ó ní náà sílẹ̀ àní gbogbo ìní rẹ̀.”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.