Revised Common Lectionary (Semicontinuous)
Ti Dafidi.
26 Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa,
nítorí tí mo ti ń rìn nínú ìwà òtítọ́ ọ̀ mi,
mo sì ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa
Ǹjẹ́ ẹsẹ̀ mi kì yóò yẹ̀.
2 Wádìí mi wò, Ìwọ Olúwa, kí o sì dán mi wò,
dán àyà àti ọkàn mi wò;
3 Nítorí ìfẹ́ ẹ̀ rẹ tí ó dúró ṣinṣin ń bẹ níwájú mi,
èmí sì ti rìn nínú òtítọ́ rẹ.
4 Èmi kò jókòó pẹ̀lú aláìṣòótọ́,
bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò bá àwọn àgàbàgebè wọlé;
5 Èmi ti kórìíra àwùjọ àwọn ènìyàn búburú
èmi kì yóò sì bá àwọn ènìyàn ìkà jókòó.
6 Èmí ó wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀,
bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò sì yí pẹpẹ rẹ ká Olúwa.
7 Èmi yóò kọrin sókè àní orin ọpẹ́,
èmi yóò sì máa sọ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.
8 Háà Olúwa, èmí ń fẹ́ ilé rẹ níbi tí ìwọ ń gbé,
àní níbi tí ògo rẹ̀ wà.
9 Má ṣe gbá mi dànù pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,
tàbí ẹ̀mí mi pẹ̀lú àwọn ọkùnrin tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ,
10 Àwọn tí ọwọ́ wọn kún fún ìwà ibi,
tí ọwọ́ ọ̀tún wọn kún fún àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
11 Ṣùgbọ́n èmi ó máa rìn nínú ìwà títọ́;
rà mí padà, kí o sì ṣàánú fún mi.
12 Ẹsẹ̀ mi dúró lórí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú;
nínú ìjọ ńlá èmi yóò fi ìbùkún fún Olúwa.
Jobu ha ni ìrètí bí?
7 “Ṣé ìjà kò ha si fún ènìyàn lórí ilẹ̀?
Ọjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kò ha dàbí ọjọ́ alágbàṣe?
2 Bí ọmọ ọ̀dọ̀ tí máa ń kánjú bojú wo òjìji,
àti bí alágbàṣe ti í kánjú wo ọ̀nà owó iṣẹ́ rẹ̀.
3 Bẹ́ẹ̀ ni a mú mi ní ìbànújẹ́ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oṣù,
òru ìdáni-lágara ni a sì là sílẹ̀ fún mi.
4 Nígbà ti mo dùbúlẹ̀, èmi wí pé, ‘Nígbà wo ni èmi ó dìde?’
Tí òru yóò sì kọjá, ó sì tó fún mi láti yí síhìn-ín yí sọ́hùn-ún, títí yóò fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
5 Kòkòrò àti ògúlùtu erùpẹ̀ ni á fi wọ̀ mi ni aṣọ,
awọ ara mi bù, o sì di bíbàjẹ́.
6 “Ọjọ́ mi yára jù ọkọ̀ ìhunṣọ lọ,
o sì di lílò ní àìní ìrètí.
7 Háà! Rántí pé afẹ́fẹ́ ni ẹ̀mí mi;
ojú mi kì yóò padà rí rere mọ́.
8 Ojú ẹni tí ó rí mi, kì yóò rí mi mọ́;
ojú rẹ̀ tẹ̀ mọ́ra mi, èmi kò sí mọ́.
9 Bí ìkùùkuu tí i túká, tí í sì fò lọ,
bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sí ipò òkú tí kì yóò padà wa mọ́.
10 Kì yóò padà sínú ilé rẹ̀ mọ́,
bẹ́ẹ̀ ní ipò rẹ̀ kì yóò mọ̀ ọn mọ́.
11 “Nítorí náà èmi kì yóò pa ẹnu mi mọ́,
èmi yóò máa sọ nínú ìrora ọkàn mi,
èmi yóò máa ṣe ìráhùn nínú kíkorò ọkàn mi.
12 Èmi a máa ṣe Òkun tàbí ẹ̀mí búburú,
tí ìwọ fi ń yan olùṣọ́ tì mi?
13 Nígbà tí mo wí pé, ibùsùn mi yóò tù mí lára,
ìtẹ́ mi yóò mú ara mi fúyẹ́ pẹ̀lú.
14 Nígbà náà ni ìwọ fi àlá da yọ mi lénu bò mi,
ìwọ sì fi ìran òru dẹ́rùbà mí.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mí yàn láti fún pa
àti ikú ju kí ń wà láààyè ní ipò tí ara mí wà yìí lọ.
16 O sú mi, èmi kò le wà títí:
jọ̀wọ́ mi jẹ́, nítorí pé asán ni ọjọ́ mi.
17 (A)“Kí ni ènìyàn tí ìwọ o máa kókìkí rẹ̀?
Àti tí ìwọ ìbá fi gbé ọkàn rẹ lé e?
18 Àti ti ìwọ ó fi máa wá í bẹ̀ ẹ́ wò ni òròòwúrọ̀,
ti ìwọ o sì máa dán an wò nígbàkúgbà!
19 Yóò ti pẹ́ tó kí ìwọ kí ó tó fi mí sílẹ̀ lọ,
tí ìwọ o fi mí sílẹ̀ jẹ́ẹ́ títí èmi yóò fi lè dá itọ́ mi mì.
20 Èmi ti ṣẹ̀, ki ní èmi ó ṣe sí ọ.
Ìwọ Olùsójú ènìyàn?
Èéṣe tí ìwọ fi fi mí ṣe ààmì itasi níwájú rẹ,
bẹ́ẹ̀ ni èmi sì di ẹrẹ̀ wíwo fún ọ?
21 Èéṣe tí ìwọ kò sì dárí ìrékọjá mi jìn,
kí ìwọ kí ó sì mú àìṣedéédéé mi kúrò?
Ǹjẹ́ nísinsin yìí ni èmi ìbá sùn nínú erùpẹ̀,
ìwọ ìbá sì wá mi kiri ní òwúrọ̀, èmi kì bá tí sí.”
14 Àwọn Farisi, tí wọ́n ní ojúkòkòrò sì gbọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, wọ́n sì yọ ṣùtì sí i. 15 (A)Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni àwọn tí ń dá àre fún ara yín níwájú ènìyàn; ṣùgbọ́n Ọlọ́run mọ ọkàn yín: nítorí ohun ti a gbéga lójú ènìyàn, ìríra ni níwájú Ọlọ́run.
Àfikún àwọn ẹ̀kọ́
16 (B)“Òfin àti àwọn wòlíì ń bẹ títí di ìgbà Johanu: Láti ìgbà náà wá ni a ti ń wàásù ìròyìn ayọ̀ ìjọba Ọlọ́run, olúkúlùkù sì ń fi ipá wọ inú rẹ̀. 17 (C)Ṣùgbọ́n ó rọrùn fún ọ̀run òun ayé láti kọjá lọ, ju kí èyí tí ó kéré jù nínú òfin kí ó yẹ.
18 (D)“Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì gbé ẹlòmíràn ní ìyàwó, ó ṣe panṣágà: ẹnikẹ́ni tí ó bá sì gbé, ẹni tí ọkọ rẹ̀ kọ̀sílẹ̀ ní ìyàwó náà, ó ṣe panṣágà.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.