Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Revised Common Lectionary (Semicontinuous)

Daily Bible readings that follow the church liturgical year, with sequential stories told across multiple weeks.
Duration: 1245 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Saamu 144:9-15

Èmi yóò kọ orin tuntun sí ọ
    Ọlọ́run; lára ohun èlò orin
olókùn mẹ́wàá èmi yóò
    kọ orin sí ọ
10 Òun ni ó fi ìgbàlà fún àwọn ọba,
    ẹni tí ó gba Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ idà ìpanilára.

Lọ́wọ́ pípanirun. 11 Gbà mí kí o sì yọ mí nínú ewu
    kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ àjèjì
tí ẹnu wọn kún fún èké,
    tí ọwọ́ ọ̀tún wọn jẹ́ ọwọ́ ọ̀tún èké.

12 Kí àwọn ọmọkùnrin wa
    kí ó dàbí igi gbígbìn tí ó dàgbà ni ìgbà èwe wọn,
àti ọmọbìnrin wa yóò dàbí òpó ilé
    tí a ṣe ọ̀nà sí bí àfarawé ààfin.
13 Àká wa yóò kún
    pẹ̀lú gbogbo onírúurú oúnjẹ
àgùntàn wa yóò pọ̀ si ní ẹgbẹ̀rún,
    ní ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní oko wa:
14 Àwọn màlúù wa yóò ru ẹrù wúwo
    kí ó má sí ìkọlù,
kí ó má sí ìkólọ sí ìgbèkùn,
    kí ó má sí i igbe ìpọ́njú ní ìgboro wa.
15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn náà tí ó wà ní irú ipò bẹ́ẹ̀,
    Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn náà,
    tí ẹni tí Ọlọ́run Olúwa ń ṣe.

Orin Solomoni 5:2-6:3

Olùfẹ́

Mo ti sùn ṣùgbọ́n ọkàn mi jí.
    Gbọ́! Olólùfẹ́ mi ń kan ìlẹ̀kùn.
“Ṣí i fún mi, arábìnrin mi, olùfẹ́ mi,
    àdàbà mi, aláìlábàwọ́n mi
Orí mi kún fún omi ìrì,
    irun mi kún fún òtútù òru.”
Mo ti bọ́ aṣọ ìgúnwà mi
    ṣé èmi gbọdọ̀ tún gbé e wọ̀?
Mo ti wẹ ẹsẹ̀ mi
    ṣé èmi gbọdọ̀ tún tì í bọ eruku?
Olùfẹ́ mi na ọwọ́ rẹ̀ láti inú ihò ìlẹ̀kùn
    inú mi sì yọ́ sí i
Èmi dìde láti ṣílẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,
    òjìá bẹ̀rẹ̀ sí í kán ní ọwọ́ mi,
òjìá olóòórùn ń ti ara ìka mi ń sàn
    sí orí ìdìmú ìlẹ̀kùn
Èmi ṣí ìlẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,
    ṣùgbọ́n olùfẹ́ mi ti kúrò, ó ti lọ
    ọkàn mi gbọgbẹ́ fún lílọ rẹ̀.
Mo wá a kiri ṣùgbọ́n, n kò rí i.
    Mo pè é ṣùgbọ́n, kò dáhùn
Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlú rí mi
    bí wọ́n ti ṣe ń rìn yí ìlú ká.
Wọ́n nà mí, wọ́n sá mi lọ́gbẹ́;
    wọ́n gba ìborùn mi lọ́wọ́ mi.
    Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ odi!
Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu, mo bẹ̀ yín
    bí ẹ̀yin bá rí olùfẹ́ mi,
kí ni ẹ̀yin yóò wí fún un?
    Ẹ wí fún un pé àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mi.

Ọ̀rẹ́

Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tókù lọ,
    ìwọ arẹwà jùlọ láàrín àwọn obìnrin?
Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tókù lọ
    tí ìwọ fi ń fi wá bú bẹ́ẹ̀?

Olùfẹ́

10 Olùfẹ́ mi ní ìtànṣán ó sì pọ́n
    ó ní ọlá ju ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá lọ.
11 Orí rẹ̀ rí bí i wúrà tí ó dára jùlọ
    ìdì irun rẹ̀ rí bí i imọ̀ ọ̀pẹ
    ó sì dúdú bí i ẹyẹ ìwò
12 Ojú rẹ̀ rí bí i ti àdàbà
    ní ẹ̀bá odò tí ń sàn,
tí a fi wàrà wẹ̀,
    tí ó jì, tí ó sì dákẹ́ rọ́rọ́
13 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ rí bí ibùsùn tùràrí
    tí ó sun òórùn tùràrí dídùn
Ètè rẹ̀ rí bí i ìtànná lílì
    ó ń kán òjìá olóòórùn dídùn
14 Apá rẹ̀ rí bí i ọ̀pá wúrà,
    tí a to ohun ọ̀ṣọ́ sí yíká
Ara rẹ̀ rí bí i eyín erin dídán
    tí a fi safire ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
15 Ẹsẹ̀ rẹ̀ rí bí i òpó mábù
    tí a gbé ka ihò ìtẹ̀bọ̀ wúrà dáradára
Ìrísí rẹ̀ rí bí igi kedari Lebanoni,
    tí dídára rẹ̀ kò ní ẹgbẹ́.
16 Ẹnu rẹ̀ jẹ́ adùn fún ara rẹ̀
    ó wu ni pátápátá.
Háà! Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu,
    Èyí ni olùfẹ́ mi, èyí sì ni ọ̀rẹ́ mi.

Ọ̀rẹ́

Níbo ni olùfẹ́ rẹ lọ,
    Ìwọ arẹwà jùlọ láàrín àwọn obìnrin?
Níbo ni olùfẹ́ rẹ yà sí,
    kí a lè bá ọ wá a?

Olólùfẹ́

Olùfẹ́ mi ti sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ọgbà rẹ̀,
    sí ibi ibùsùn tùràrí,
láti máa jẹ nínú ọgbà
    láti kó ìtànná lílì jọ.
Èmi ni ti olùfẹ́ mi, olùfẹ́ mi sì ni tèmi,
    Ó ń jẹ láàrín ìtànná lílì.

1 Peteru 2:19-25

19 Nítorí pé èyí ní ìgbóríyìn fún, bí ènìyàn bá fi ara da ìrora, ìjìyà lọ́nà àìtọ́, nítorí ọkàn rere sí Ọlọ́run. 20 Ṣùgbọ́n ògo kín ni ó jẹ́, nígbà tí ẹ ba ṣẹ̀ tí a sì lù yín, bí ẹ bá fi sùúrù gbà á? Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá ń ṣe rere tí ẹ sì ń jìyà, bí ẹ bá fi sùúrù gbà á, ẹ̀yín ní ọpẹ́ lọ́dọ̀ Ọlọ́run. 21 Sí èyí ni a pè yín: nítorí Kristi pẹ̀lú jìyà fún un yin, ó fi àpẹẹrẹ sílẹ̀ fún un yín, kí ẹ̀yin lè máa tọ ipasẹ̀ rẹ̀:

22 (A)“Òun kò dẹ́ṣẹ̀ kankan,
    bẹ́ẹ̀ sì ni, a kò rí ẹ̀tàn kan lẹ́nu rẹ̀.”

23 Ẹni, nígbà tí a kẹ́gàn rẹ̀, tí kò sì padà kẹ́gàn; nígbà tí ó jìyà tí kò sì halẹ̀; ṣùgbọ́n ó fi ọ̀ràn rẹ̀ lé ẹni ti ń ṣe ìdájọ́ òdodo lọ́wọ́. 24 (B)Ẹni tí òun tìkára rẹ̀ fi ara rẹ̀ ru ẹ̀ṣẹ̀ wa lórí igi àgbélébùú, pé kí àwa lè di òkú sí ẹ̀ṣẹ̀, ki a sì di ààyè sí òdodo: nípa ìjìyà ẹni tí ó mú yín láradá. 25 Nítorí tí ẹ̀yin ń ṣáko lọ bí àgùntàn, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ẹ̀yin ti padà sí ọ̀dọ̀ olùṣọ́-àgùntàn àti bíṣọ́ọ̀bù ọkàn yín.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.