Revised Common Lectionary (Complementary)
Saamu. Fún ọpẹ́
100 Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Olúwa, gbogbo ayé
2 Ẹ fi ayọ̀ sin Olúwa:
Ẹ wá síwájú rẹ̀ pẹ̀lú orin dídùn
3 Olúwa Ọlọ́run ni ó dá wa,
kí ẹ̀yin kí ó mọ̀ pé
tirẹ̀ ni àwa; Àwa ní ènìyàn rẹ̀
àti àgùntàn pápá rẹ̀.
4 Ẹ lọ sí ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́
àti sí àgbàlá rẹ̀ pẹ̀lú ìyìn;
ẹ fi ọpẹ́ àti ìyìn fún orúkọ rẹ̀.
5 Nítorí tí Olúwa pọ̀ ní oore
ìfẹ́ rẹ̀ sì wà títí láé;
àti òtítọ́ rẹ̀ láti ìran de ìran.
Àsọtẹ́lẹ̀ ní ti Babeli
50 (A)Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
2 “Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde,
kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀
ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé,
‘a kó Babeli,
ojú tí Beli,
a fọ́ Merodaki túútúú,
ojú ti àwọn ère rẹ̀,
a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
3 Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò
sì máa gbóguntì wọ́n.
Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò
sá kúrò ní ìlú yìí.
4 “Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,”
ni Olúwa wí,
“Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá,
àwọn, àti àwọn ọmọ Juda,
wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí
Olúwa Ọlọ́run wọn
5 Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn
yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a
darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé,
tí a kì yóò gbàgbé.
6 “Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù,
àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà,
wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè
wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré,
wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ
àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi
nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé
òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
17 Ẹ máa gbọ́ ti àwọn tí ń ṣe olórí yín, kí ẹ sì máa tẹríba fún wọ́n: Nítorí wọn ń ṣọ́ ẹ̀ṣọ́ nítorí ọkàn yín, bí àwọn ti yóò ṣe ìṣirò, kí wọn lè fi ayọ̀ ṣe èyí, kì í ṣe pẹ̀lú ìbànújẹ́, nítorí èyí yìí yóò jẹ àìlérè fún yín.
18 Ẹ máa gbàdúrà fún wa: nítorí àwa gbàgbọ́ pé àwa ni ẹ̀rí ọkàn rere, a sì ń fẹ́ láti máa hùwà títọ́ nínú ohun gbogbo. 19 Ṣùgbọ́n èmi ń bẹ̀ yín gidigidi sí i láti máa ṣe èyí, kí a ba lè tètè fi mi fún yín padà.
20 (A)Ǹjẹ́ Ọlọ́run àlàáfíà, ẹni tí o tún mu olùṣọ́-àgùntàn ńlá ti àwọn àgùntàn, ti inú òkú wá, nípa ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú ayérayé, àní Olúwa wa Jesu. 21 Kí ó mú yín pé nínú iṣẹ́ rere gbogbo láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣiṣẹ́ ohun tí i ṣe ìtẹ́wọ́gbà níwájú rẹ̀ nínú yín nípasẹ̀ Jesu Kristi; ẹni tí ògo wà fún láé àti láéláé. Àmín.
22 Èmi sì ń bẹ̀ yín ará, ẹ gbà ọ̀rọ̀ ìyànjú mi; nítorí ìwé kúkúrú ni mo kọ sí yín.
23 Ẹ mọ pé a sá titu Timotiu arákùnrin wa sílẹ̀; bí ó ba tètè dé, èmí pẹ̀lú rẹ̀ yóò rí yín, àti gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́.
24 Ẹ ki gbogbo àwọn tí ń ṣe olórí yín, àti gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́.
Àwọn tí o ti Itali wá ki yín.
25 Kí oore-ọ̀fẹ́ wà pẹ̀lú gbogbo yín.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.