Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Revised Common Lectionary (Complementary)

Daily Bible readings that follow the church liturgical year, with thematically matched Old and New Testament readings.
Duration: 1245 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Saamu 23

Saamu ti Dafidi.

23 Olúwa ni Olùṣọ́ èmi àgùntàn rẹ̀, èmi kì yóò ṣe aláìní.
    (A)Ó mú mi dùbúlẹ̀ sí ibi pápá oko tútù
Ó mú mi lọ sí ibi omi dídákẹ́ rọ́rọ́;
    Ó mú ọkàn mi padà bọ̀ sípò
Ó mú mi lọ sí ọ̀nà òdodo
    nítorí orúkọ rẹ̀.
Bí mo tilẹ̀ ń rìn
    Láàrín àfonífojì òjìji ikú,
èmi kì yóò bẹ̀rù ibi kan;
    nítorí ìwọ wà pẹ̀lú mi;
ọ̀gọ rẹ àti ọ̀pá à rẹ
    wọ́n ń tù mí nínú.

Ìwọ tẹ́ tábìlì oúnjẹ sílẹ̀ níwájú mi
    ní ojú àwọn ọ̀tá à mi;
ìwọ ta òróró sí mi ní orí;
    ago mí sì kún àkúnwọ́sílẹ̀.
Nítòótọ́, ìre àti àánú ni yóò máa tọ̀ mí lẹ́yìn
    ní ọjọ́ ayé è mi gbogbo,
èmi yóò sì máa gbé inú ilé Olúwa
    títí láéláé.

Jeremiah 10:1-16

Ọlọ́run àti àwọn òrìṣà

10 Gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ fún yín ẹ̀yin ilé Israẹli. Báyìí ni Olúwa wí:

“Má ṣe kọ́ ìwà àwọn kèfèrí,
    kí ààmì ọ̀run kí ó má sì dààmú yín,
    nítorí pé wọ́n ń dààmú orílẹ̀-èdè.
Nítorí pé asán ni àṣà àwọn ènìyàn,
    wọ́n gé igi láti inú igbó, oníṣọ̀nà
    sì gbẹ́ ẹ pẹ̀lú àáké rẹ̀.
Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́.
    Wọ́n fi òòlù kàn án àti ìṣó
    kí ó má ba à ṣubú.
Wọ́n wé mọ́ igi bí ẹ̀gúnsí inú oko,
    òrìṣà wọn kò le è fọhùn.
Wọ́n gbọdọ̀ máa gbé
    wọn nítorí pé wọn kò lè rìn.
Má ṣe bẹ̀rù wọn;
    wọn kò le è ṣe ibi kankan
    bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si lè ṣe rere kan.”

Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ Olúwa;
    o tóbi orúkọ rẹ sì tóbi lágbára.
Ta ni kò yẹ kí ó bẹ̀rù rẹ ọba àwọn
    orílẹ̀-èdè? Nítorí tìrẹ ni, láàrín àwọn
ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní orílẹ̀-èdè àti
    gbogbo ìjọba wọn, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ.

Gbogbo wọn jẹ́ aláìlóye àti aṣiwèrè,
    wọ́n ń kọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ère igi tí kò níláárí
Fàdákà tí a ti kàn ni a mú wá láti
    Tarṣiṣi, àti wúrà láti Upasi; èyí tí
àwọn oníṣọ́nà àti alágbẹ̀dẹ ṣe tí wọ́n
    kùn ní àwọ̀ aró àti elése àlùkò,
    èyí jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà.
10 Ṣùgbọ́n Olúwa ni Ọlọ́run tòótọ́,
    òun ni Ọlọ́run alààyè, ọba ayérayé.
Nígbà tí ó bá bínú, ayé yóò wárìrì;
    orílẹ̀-èdè kò lè fi ara da ìbínú rẹ̀.

11 “Sọ èyí fún wọn: ‘Àwọn ọlọ́run kéékèèkéé tí kò dá ọ̀run àti ayé ni yóò ṣègbé láti ayé àti ní abẹ́ ọ̀run.’ ”

12 Ọlọ́run dá ayé pẹ̀lú agbára rẹ̀,
    ó dá àgbáyé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀,
    ó mú kí ọ̀run kí ó fẹ̀ síta nípa òye rẹ̀.
13 Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omi
    lọ́run a sì pariwo, ó mú kí ìkùùkuu ru
sókè láti òpin ayé: ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò,
    ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.

14 Gbogbo ènìyàn jẹ́ aṣiwèrè àti aláìnímọ̀,
    ojú ti gbogbo alágbẹ̀dẹ níwájú ère rẹ̀,
nítorí ère dídá rẹ̀ èké ni,
    kò sì ṣí ẹ̀mí nínú rẹ̀.
15 Asán ni wọ́n, iṣẹ́ ìṣìnà;
    nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn yóò ṣègbé.
16 Ẹni tí ó bá jẹ́ ìpín Jakọbu kò sì dàbí èyí,
    nítorí òun ni ó ṣẹ̀dá ohun gbogbo
àti Israẹli tí ó jẹ́ ẹ̀yà ìjogún rẹ̀.
    Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

Kolose 1:15-23

Títóbi Kristi

15 (A)Kristi ni àwòrán Ọlọ́run tí a kò le rí, àkọ́bí gbogbo ẹ̀dá. 16 Nítorí nípa rẹ̀ ní a dá ohun gbogbo: àwọn ohun tí ń bẹ ní ọ̀run àti ní ayé, ohun tí a rí àti èyí tí a kò rí, wọn ìbá ṣe ìtẹ́, tàbí agbára, tàbí àṣẹ, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo àti fún un. 17 (B)Ó ti wà ṣáájú kí ohunkóhun tó wà, nínú rẹ̀ ni a sì so ohun gbogbo papọ̀ ṣọ̀kan. 18 (C)Òun ni orí fún ara, èyí tí í ṣe ìjọ; òun ni ìbẹ̀rẹ̀ àti àkọ́bí nínú àwọn òkú, pé nínú ohun gbogbo kí òun lè ní ipò tí ó ga jùlọ nínú ohunkóhun. 19 Nítorí ìfẹ́ Ọlọ́run ni pé kí gbogbo ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ òun tìkára rẹ̀ lè máa gbé nínú rẹ̀. 20 Àti nípasẹ̀ rẹ̀ láti bá ohun gbogbo làjà àwọn nǹkan tí ń bẹ láyé àti èyí tí ń bẹ ní ọ̀run, nípa mímú àlàáfíà wá nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, tí a ta sílẹ̀ lórí igi àgbélébùú.

21 Ẹ̀yin ya ara yín nípá kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run nígbà kan rí, ẹ jẹ́ ọ̀tá nínú ọkàn yín nítorí ìwà búburú yín. 22 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti bá yín làjà nípa ara Kristi nípa ikú láti mú un yín lọ sí iwájú rẹ̀ ní mímọ́, aláìlábàwọ́n àti kúrò nínú ìdálẹ́bi, 23 bí ẹ̀yin bá dúró nínú ìgbàgbọ́ yín, tí ẹ fi ẹsẹ̀ múlẹ̀, tí ẹ sì dúró ṣinṣin, láláìyẹsẹ̀ kúrò nínú ìrètí ti ìhìnrere ti ẹ̀yin ti gbọ́, èyí tí a ti wàásù rẹ̀ fún gbogbo ẹ̀dá lábẹ́ ọ̀run, àti èyí ti èmi Paulu ṣe ìránṣẹ́ fún.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.