Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Revised Common Lectionary (Complementary)

Daily Bible readings that follow the church liturgical year, with thematically matched Old and New Testament readings.
Duration: 1245 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Saamu 30

Saamu. Orin. Fún ìyàsímímọ́ Tẹmpili. Ti Dafidi.

30 Èmi yóò kókìkí i rẹ, Olúwa,
    nítorí ìwọ ni ó gbé mi lékè
    tí ìwọ kò sì jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi kí ó yọ̀ mí.
Olúwa Ọlọ́run mi, èmi ké pè ọ́, fún ìrànlọ́wọ́
    ìwọ sì ti wò mí sàn.
Olúwa, ìwọ ti yọ ọkàn mi jáde kúrò nínú isà òkú,
    mú mi padà bọ̀ sípò alààyè kí èmi má ba à lọ sínú ihò.

Kọ orin ìyìn sí Olúwa, ẹ̀yin olódodo;
    kí ẹ sì fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ̀ mímọ́.
Nítorí pé ìbínú rẹ̀ wà fún ìgbà díẹ̀,
    ojúrere rẹ̀ wà títí ayérayé;
Ẹkún lè pẹ́ títí di alẹ́,
    Ṣùgbọ́n ayọ̀ yóò wá ní òwúrọ̀.

Ní ìgbà ayé mi, mo wí pé,
    “a kì yóò ṣí mi ní ipò padà.”
Nípa ojúrere rẹ, Olúwa,
    ìwọ ti gbé mi kalẹ̀ bí òkè tí ó ní agbára;
ìwọ pa ojú rẹ mọ́,
    àyà sì fò mí.

Sí ọ Olúwa, ni mo ké pè é;
    àti sí Olúwa ni mo sọkún fún àánú:
“Èrè kí ni ó wà nínú ikú ìparun mi,
    nínú lílọ sí ihò mi?
Eruku yóò a yìn ọ́ bí?
    Ǹjẹ́ yóò sọ nípa òdodo rẹ?
10 Gbọ́, Olúwa, kí o sì ṣàánú fún mi;
    ìwọ Olúwa, jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi.”

11 Ìwọ ti yí ìkáàánú mi di ijó fún mi;
    ìwọ sì ti bọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ mi, o sì fi aṣọ ayọ̀ wọ̀ mí,
12 nítorí ìdí èyí ni kí ọkàn mi máa yìn ọ́, kí o má sì ṣe dákẹ́.
    Ìwọ Olúwa Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ títí láé.

Ẹkun Jeremiah 2:1-12

Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Sioni
    pẹ̀lú àwọsánmọ̀ ìbínú rẹ̀!
Ó sọ ògo Israẹli kalẹ̀
    Láti ọ̀run sí ayé;
kò rántí àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
    ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.

Láìní àánú ni Olúwa gbé
    ibùgbé Jakọbu mì;
nínú ìrunú rẹ̀, ni ó wó
    ibi gíga ọmọbìnrin Juda lulẹ̀.
Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ-aládé ọkùnrin
    lọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.

Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó ké
    gbogbo ìwo Israẹli.
Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrò
    nígbà tí àwọn ọ̀tá dé.
Ó run ní Jakọbu bí ọ̀wọ́-iná
    ní àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Sioni.

Ó na ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá;
    ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múra
Bí ti ọ̀tá tí ó ti parun
    ó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí iná
sórí àgọ́ ọmọbìnrin Sioni.

Olúwa dàbí ọ̀tá;
    ó gbé Israẹli mì.
Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mì
    ó pa ibi gíga rẹ̀ run.
Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀
    fún àwọn ọmọbìnrin Juda.

Ó mú ìparun bá ibi mímọ́,
    ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run.
Olúwa ti mú Sioni gbàgbé
    àjọ̀dún tí a yàn àti ọ̀sẹ̀ tí ó yàn;
nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó run
    ọba àti olórí àlùfáà.

Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀
    ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀.
Ó sì fi lé ọ̀tá lọ́wọ́
    àwọn odi ààfin rẹ̀;
wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwa
    gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àpèjẹ tí a yàn.

Olúwa pinnu láti fa
    ògiri tí ó yí ọmọbìnrin Sioni ya.
Ó gbé wọn sórí òṣùwọ̀n,
    kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn.
Ó mú kí ilé ìṣọ́ àti odi rẹ̀ ṣọ̀fọ̀
    wọ́n ṣòfò papọ̀.

Ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀;
    òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́.
Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
    kò sí òfin mọ́,
àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí
    ìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.

10 Àwọn àgbàgbà ọmọbìnrin Sioni
    jókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́;
wọ́n da eruku sí orí wọn
    wọ́n sì wọ aṣọ àkísà.
Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jerusalẹmu
    ti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.

11 Ojú mi kọ̀ láti sọkún,
    mo ń jẹ ìrora nínú mi,
mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀
    nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run,
nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kú
    ní òpópó ìlú.

12 Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn,
    “Níbo ni ọkà àti wáìnì wà?” Wò ó
bí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣe
    ní àwọn òpópónà ìlú,
bí ayé wọn ṣe ń ṣòfò
    láti ọwọ́ ìyá wọn.

2 Kọrinti 8:1-7

Ọ̀rọ̀ ìyànjú lórí ìfifúnni

Pẹ̀lúpẹ̀lú, ará, àwa ń sọ fún yín ní ti oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run tí a fífún àwọn ìjọ Makedonia; Bí ó ti jẹ́ pé a dán wọn wò nípa ìpọ́njú, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ayọ̀ àti àìlódiwọ̀n àìní wọn ti kún àkúnwọ́sílẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ ìlawọ́ wọn. (A)Nítorí mo jẹ́rìí pé gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, àní ju agbára wọn, wọ́n ṣe é láti ìfẹ́ inú ara wọn. (B)Wọ́n ń fi ẹ̀bẹ̀ púpọ̀ rọ̀ wá ní ti ẹ̀bùn àtinúwá yìí, láti ba à lè ní ìpín nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn mímọ́. Àti èyí, kì í ṣe bí àwa tí rò rí, ṣùgbọ́n wọ́n tètè kọ́ fi àwọn fúnrawọn fún Olúwa, àti fún wá, nípa ìfẹ́ Ọlọ́run. (C)Tó bẹ́ẹ̀ tí àwa fi gba Titu níyànjú pé, bí ó tí bẹ̀rẹ̀ náà, bẹ́ẹ̀ ni kí ó sì parí ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ yìí nínú yín pẹ̀lú. Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin ti pọ̀ lóhùn gbogbo, ní ìgbàgbọ́, àti ọ̀rọ̀ àti ìmọ̀, àti nínú iṣẹ́ ìhìnrere gbogbo, àti ní ìfẹ́ yín sí wa, ẹ rí i wí pé ẹ̀yin pọ̀ sí i nínú ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ yìí pẹ̀lú.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.