Revised Common Lectionary (Complementary)
7 Tún wa yípadà, ìwọ, Ọlọ́run alágbára;
jẹ́ kí ojú rẹ tàn sí wa,
kí a ba à lè gbà wá là.
8 Ìwọ mú àjàrà jáde láti Ejibiti;
ìwọ lé àwọn kèfèrí jáde, o sì gbìn ín.
9 Ìwọ ṣí ààyè sílẹ̀ fún un,
ìwọ sì mu ta gbòǹgbò jinlẹ̀
ó sì kún ilẹ̀ náà.
10 A bò àwọn òkè mọ́lẹ̀ òkè pẹ̀lú òjìji rẹ̀,
ẹ̀ka rẹ̀ dàbí kedari Ọlọ́run.
11 O yọ ẹ̀ka rẹ̀ sínú Òkun,
ọwọ́ rẹ̀ sí odò ńlá nì.
12 Èéṣe tí ìwọ fi wó odi rẹ̀
tí àwọn ènìyàn tí ó ń kọjá fi ń ṣa èso rẹ̀?
13 Ìmàdò láti inú igbó ń bá a jẹ́
àti ẹranko igbó ń jẹ ẹ́ run.
14 Yípadà sí wa, àwa ń bẹ̀ ọ́, Ọlọ́run alágbára!
Bojú wolẹ̀ láti ọ̀run kí o sì wò ó!
Kí o sì bẹ àjàrà yìí wò,
15 Gbòǹgbò èyí tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ ti gbìn,
àti ẹ̀ka tí ìwọ ti mú lágbára fún ara rẹ.
23 “Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́;
Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’?
Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì;
wo ohun tí o ṣe.
Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ
tí ń sá síhìn-ín sọ́hùn-ún.
24 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù
tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ,
ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀?
Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara,
nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
25 Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà,
àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ.
Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni!
Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì,
àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
26 “Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u,
bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli—
àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn,
àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
27 Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’
àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’
wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi,
wọn kò kọ ojú sí mi
síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro,
wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
28 Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí
ẹ ṣe fúnrayín ha a wà?
Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì
gbà yín nígbà tí ẹ bá
wà nínú ìṣòro! Nítorí pé
ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́
bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
29 “Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí?
Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,”
ni Olúwa wí.
30 “Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín,
wọn kò sì gba ìbáwí.
Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run,
gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
31 “Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa:
“Mo ha ti di aginjù sí Israẹli
tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri?
Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé,
‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri;
àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
32 Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀,
tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀?
Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
33 Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́!
Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ
34 Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀
àwọn tálákà aláìṣẹ̀
bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́
níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé
35 Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀
kò sì bínú sí mi.’
Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ
nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
36 Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri
láti yí ọ̀nà rẹ padà?
Ejibiti yóò dójútì ọ́
gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria
37 Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀
pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ,
nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn
tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀,
kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan
fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.
14 Ẹ máa ṣe ohun gbogbo láìsí ìkùnsínú àti ìjiyàn. 15 (A)Kí ẹ̀yin lè jẹ́ aláìlẹ́gàn àti oníwà mímọ́, ọmọ Ọlọ́run, aláìlábàwọ́n, láàrín oníwà wíwọ́ àti alárékérekè orílẹ̀-èdè láàrín àwọn ẹni tí a ń rí yín bí ìmọ́lẹ̀ ní ayé. 16 Bí ẹ sì ṣe di ọ̀rọ̀ ìyè mú gírígírí, kí èmi lè ṣògo ni ọjọ́ Kristi pé èmi kò sáré lásán, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ṣe làálàá lásán. 17 Ṣùgbọ́n, bí a tilẹ̀ ń dà mí bí ọtí-ìrúbọ sórí ẹbọ iṣẹ́ ìsìn ìgbàgbọ́ yín, inú mi dùn, mo sì ń bá gbogbo yín yọ̀ pẹ̀lú. 18 Bákan náà ni kí ẹ̀yin máa yọ̀, kí ẹ sì máa bá mi yọ̀ pẹ̀lú.
Kò sí ìgbẹ́kẹ̀lé ẹlẹ́ran ara
3 Ní àkótán ará, ẹ máa yọ̀ nínú Olúwa wa. Kì í ṣe ìnira fún mi láti kọ̀wé ohun kan náà sí yín, ṣùgbọ́n fún yín ó jẹ́ ohun ààbò. 2 Ẹ kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn ajá, ẹ kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn oníṣẹ́ búburú, ẹ sì kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn onílà. 3 (A)Nítorí àwa ni onílà, tí ń sin Ọlọ́run nípa ti Ẹ̀mí, àwa sì ń ṣògo nínú Kristi Jesu, àwa kò sí ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ẹran-ara. 4 (B)Bí èmi tìkára mi pẹ̀lú ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ara.
Bí ẹnikẹ́ni bá rò pé òun ni ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ara, tèmi tilẹ̀ pọ̀:
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.