Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Revised Common Lectionary (Complementary)

Daily Bible readings that follow the church liturgical year, with thematically matched Old and New Testament readings.
Duration: 1245 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Saamu 145:8-9

Olóore-ọ̀fẹ́ ni Olúwa àti aláàánú
    ó lọ́ra láti bínú ó sì ní ìfẹ́ púpọ̀.

Olúwa dára sí ẹni gbogbo;
    ó ní àánú lórí ohun gbogbo tí ó dá.

Saamu 145:14-21

14 Olúwa mú gbogbo àwọn tí ó ṣubú ró
    ó sì gbé gbogbo àwọn tí ó tẹríba dìde.
15 Ojú gbogbo ènìyàn ń wò ọ́,
    ó sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó yẹ
16 Ìwọ ṣí ọwọ́ rẹ
    ìwọ sì tẹ́ ìfẹ́ gbogbo ohun alààyè lọ́rùn.

17 Olúwa jẹ́ olódodo ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀
    àti ìfẹ́ rẹ̀ sí gbogbo ohun tí o dá.
18 Olúwa wà ní tòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é,
    sí gbogbo ẹni tí ń ké pè é ní òtítọ́.
19 Ó mú ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ṣẹ;
    ó gbọ́ igbe wọn, ó sì gbà wọ́n.
20 Olúwa dá gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́ sẹ sí
    ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ẹni
    búburú ní yóò parun.

21 Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ìyìn Olúwa.
    Jẹ́ kí gbogbo ẹ̀dá yín orúkọ rẹ̀ mímọ́ láé àti láéláé.

Isaiah 51:17-23

Ago ìbínú Olúwa

17 Jí, jí!
    Gbéra nílẹ̀ ìwọ Jerusalẹmu,
ìwọ tí o ti mu láti ọwọ́ Olúwa
    ago ìbínú rẹ̀,
ìwọ tí o ti fà á mu dé gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀
    tí ó n mú kí ènìyàn ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
18 Nínú gbogbo ọmọ tí ó bí
    kò sí ọ̀kankan tí ó lè tọ́ ọ ṣọ́nà
nínú gbogbo ọmọ tí ó tọ́
    kò sí èyí tí ó le fà á lọ́wọ́.
19 Àjálù ìlọ́po ìlọ́po yìí ti dé bá ọ—
    ta ni yóò tù ọ́ nínú?
Ìparun àti ìdahoro, ìyàn àti idà
    ta ni yó pẹ̀tù sí ọ lọ́kàn?
20 Àwọn ọmọkùnrin rẹ ti dákú;
    wọ́n sùn sí oríta gbogbo òpópónà,
gẹ́gẹ́ bí etu tí a dé mọ́nú àwọ̀n.
    Ìbínú Olúwa ti kún inú wọn fọ́fọ́
    àti ìbáwí Ọlọ́run yín.

21 Nítorí náà ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí a ti ṣẹ́ níṣẹ̀ẹ́,
    tí ọtí ń pa, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wáìnì
22 Ohun tí Olúwa Olódùmarè yín wí nìyìí,
    Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ń pa ènìyàn rẹ̀ mọ́,
“Kíyèsi i, mo ti mú un kúrò ní ọwọ́ rẹ
    ago tí ó mú ọ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n;
láti inú ago náà, ẹ̀kún ìbínú mi,
    ni ìwọ kì yóò mu mọ́.
23 Èmi yóò fi lé àwọn apọ́nilójú rẹ lọ́wọ́,
    àwọn tí ó wí fún ọ pé,
‘Dọ̀bálẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí a ó fi máa rìn lórí rẹ.’
    Ìwọ náà ṣe ẹ̀yìn rẹ gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀
    gẹ́gẹ́ bí òpópónà láti máa rìn lórí i rẹ̀.”

Romu 9:6-13

(A)Ṣùgbọ́n kì í ṣe pé nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run di asán. Kì í sá í ṣe gbogbo àwọn tí ó ti inú Israẹli wá, àwọn ni Israẹli: (B)Bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe pé, nítorí wọ́n jẹ́ irú-ọmọ Abrahamu, gbogbo wọn ni ọmọ: Ní ọ̀nà mìíràn, “Nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.” (C)Èyí nì ni pé, kì í ṣe àwọn ọmọ nípa ti ara, ni ọmọ Ọlọ́run: ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ìlérí ni a kà ní irú-ọmọ. (D)Nítorí ọ̀rọ̀ ìlérí ni èyí: “Ní ìwòyí àmọ́dún ni èmi yóò wá, Sara yóò sì ní ọmọ ọkùnrin.”

10 (E)Kì í sì í ṣe kìkì èyí; Ṣùgbọ́n nígbà tí Rebeka pẹ̀lú lóyún fún ẹnìkan, fún Isaaki baba wa. 11 Nítorí nígbà tí kò tí ì bí àwọn ọmọ náà, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tí ì ṣe rere tàbí búburú—kí ìpinnu Ọlọ́run nípa ti ìyànfẹ́ kí ó lè dúró, 12 (F)kì í ṣe nípa ti iṣẹ́, bí kò ṣe ti ẹni tí ń peni—a ti sọ fún un pé, “Ẹ̀gbọ́n ni yóò máa sin àbúrò.” 13 (G)Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Jakọbu ni mo fẹ́ràn, ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra.”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.