Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Revised Common Lectionary (Complementary)

Daily Bible readings that follow the church liturgical year, with thematically matched Old and New Testament readings.
Duration: 1245 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Saamu 144

Ti Dafidi.

144 Ìyìn sí Olúwa àpáta mi,
    ẹni tí ó kọ́ ọwọ́ mi fún ogun,
    àti ìka mi fún ìjà.
Òun ni Ọlọ́run ìfẹ́ mi àti odi alágbára mi,
    ibi gíga mi àti olùgbàlà mi, asà mi,
ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé,
    ẹni tí ó tẹrí àwọn ènìyàn ba lábẹ́ mi.

Olúwa, kí ni ènìyàn tí ìwọ fi ń ṣàníyàn fún un,
    tàbí ọmọ ènìyàn tí ìwọ fi ń ronú nípa rẹ̀?
Ènìyàn rí bí èmi;
    ọjọ́ rẹ̀ rí bí òjìji tí ń kọjá lọ.

Tẹ ọ̀run rẹ ba, Olúwa, kí o sì sọ̀kalẹ̀;
    tọ́ àwọn òkè ńlá wọn yóò sí rú èéfín.
Rán mọ̀nàmọ́ná kí ó sì fọ́n àwọn ọ̀tá ká;
    ta ọfà rẹ kí ó sì dà wọ́n rú.
Na ọwọ́ rẹ sílẹ̀ láti ibi gíga;
    gbà mí kí o sì yọ mí nínú ewu
kúrò nínú omi ńlá:
    kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ àjèjì.
Ẹnu ẹni tí ó kún fún èké
    ẹni tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ jẹ́ ìrẹ́jẹ.

Èmi yóò kọ orin tuntun sí ọ
    Ọlọ́run; lára ohun èlò orin
olókùn mẹ́wàá èmi yóò
    kọ orin sí ọ
10 Òun ni ó fi ìgbàlà fún àwọn ọba,
    ẹni tí ó gba Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ idà ìpanilára.

Lọ́wọ́ pípanirun. 11 Gbà mí kí o sì yọ mí nínú ewu
    kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ àjèjì
tí ẹnu wọn kún fún èké,
    tí ọwọ́ ọ̀tún wọn jẹ́ ọwọ́ ọ̀tún èké.

12 Kí àwọn ọmọkùnrin wa
    kí ó dàbí igi gbígbìn tí ó dàgbà ni ìgbà èwe wọn,
àti ọmọbìnrin wa yóò dàbí òpó ilé
    tí a ṣe ọ̀nà sí bí àfarawé ààfin.
13 Àká wa yóò kún
    pẹ̀lú gbogbo onírúurú oúnjẹ
àgùntàn wa yóò pọ̀ si ní ẹgbẹ̀rún,
    ní ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní oko wa:
14 Àwọn màlúù wa yóò ru ẹrù wúwo
    kí ó má sí ìkọlù,
kí ó má sí ìkólọ sí ìgbèkùn,
    kí ó má sí i igbe ìpọ́njú ní ìgboro wa.
15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn náà tí ó wà ní irú ipò bẹ́ẹ̀,
    Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn náà,
    tí ẹni tí Ọlọ́run Olúwa ń ṣe.

Isaiah 27:1-6

Ìdáǹdè Israẹli

27 Ní ọjọ́ náà,

Olúwa yóò fi idà rẹ̀ jẹ ni ní yà
    idà rẹ̀ a mú bí iná tí ó tóbi tí ó sì lágbára
Lefitani ejò tí ń yọ̀ tẹ̀ẹ̀rẹ̀ n nì,
    Lefitani ejò tí ń lọ́ bìrìkìtì;
    Òun yóò sì pa ẹ̀mí búburú inú Òkun náà.

Ní ọjọ́ náà

“Kọrin nípa ọgbà àjàrà eléso kan.
    Èmi Olúwa ń bojútó o,
Èmi ó bomirin ín láti ìgbàdégbà.
    Èmi ó ṣọ́ ọ tọ̀sán tòru
    kí ẹnikẹ́ni má ba à pa á lára.
Inú kò bí mi.
    Bí ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n bá dojú ìjà kọ mí!
Èmi yóò dìde sí wọn ní ogun;
    Èmi yóò sì dáná sun gbogbo wọn.
Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí wọn wá sọ́dọ̀ mi fún ààbò;
    jẹ́ kí wọ́n wá àlàáfíà pẹ̀lú mi,
    bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí wọn wá àlàáfíà pẹ̀lú mi.”

Ní ọjọ́ iwájú Jakọbu yóò ta gbòǹgbò,
    Israẹli yóò tanná yóò sì rudi
    èso rẹ̀ yóò sì kún gbogbo ayé.

2 Kọrinti 5:17-21

17 (A)Nítorí náà bí ẹnìkan bá wà nínú Kristi, ó di ẹ̀dá tuntun: ohun àtijọ́ ti kọjá lọ; kíyèsi i, ohun tuntun ti dé. 18 (B)Ohun gbogbo sì ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, ẹni tí ó sì tipasẹ̀ Jesu Kristi bá wa làjà sọ́dọ̀ ara rẹ̀, tí ó sì ti fi iṣẹ́ ìránṣẹ́ ìlàjà fún wa. 19 Èyí ni pé, Ọlọ́run wà nínú Kristi, ó ń bá aráyé làjà sọ́dọ̀ ara rẹ̀, kò sí ka ìrékọjá wọn sí wọn lọ́rùn; ó sì ti fi ọ̀rọ̀ ìlàjà lé wa lọ́wọ́. 20 (C)Nítorí náà àwa ni ikọ̀ fún Kristi, bí ẹni pé Ọlọ́run ń ti ọ̀dọ̀ wa ṣìpẹ̀ fún yín: àwa ń bẹ̀ yín ní ipò Kristi, “Ẹ bá Ọlọ́run làjà,” 21 (D)Nítorí ó tí fi í ṣe ẹ̀ṣẹ̀ nítorí wa, ẹni tí kò mọ ẹ̀ṣẹ̀kẹ́ṣẹ̀ rí: kí àwa lè di òdodo Ọlọ́run nínú rẹ̀.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.