Chronological
4 “Tí ìwọ yóò bá yí padà, Ìwọ Israẹli,
padà tọ̀ mí wá,”
ni Olúwa wí.
“Tí ìwọ yóò bá sì mú ìríra rẹ kúrò níwájú mi,
ìwọ kí ó sì rìn kiri.
2 Tí ó bá jẹ́ lóòtítọ́ àti òdodo ni ìwọ búra.
Nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè,
nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò di alábùkún fún nípasẹ̀ rẹ,
àti nínú rẹ̀ ni wọn yóò ṣògo.”
3 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu.
“Hú gbogbo ilẹ̀ tí ẹ kò lò rí,
kí o má sì ṣe gbìn sáàrín ẹ̀gún.”
4 Kọ ara rẹ ní ilà sí Olúwa
kọ ọkàn rẹ ní ilà
ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu,
bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú mi yóò ru jáde yóò sì jó bí iná,
nítorí ibi tí o ti ṣe
kì yóò sí ẹni tí yóò pa á.
Àjálù láti ilẹ̀ gúúsù
5 “Kéde ní Juda, kí o sì polongo ní Jerusalẹmu, kí o sì wí pé:
‘Fun fèrè káàkiri gbogbo ilẹ̀!’
Kí o sì kígbe:
‘Kó ara jọ pọ̀!
Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi.’
6 Fi ààmì láti sálọ sí Sioni hàn,
sálọ fún ààbò láìsí ìdádúró.
Nítorí èmi ó mú àjálù láti àríwá wá,
àní ìparun tí ó burú jọjọ.”
7 Kìnnìún ti sá jáde láti inú ibùgbé rẹ̀,
apanirun orílẹ̀-èdè sì ti jáde.
Ó ti fi ààyè rẹ̀ sílẹ̀
láti ba ilẹ̀ rẹ̀ jẹ́.
Ìlú rẹ yóò di ahoro
láìsí olùgbé.
8 Nítorí náà, gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀
káàánú kí o sì pohùnréré ẹkún,
nítorí ìbínú ńlá Olúwa
kò tí ì kúrò lórí wa.
9 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí pé,
“Àwọn ọba àti ìjòyè yóò pàdánù ẹ̀mí wọn,
àwọn àlùfáà yóò wárìrì,
àwọn wòlíì yóò sì fòyà.”
10 Nígbà náà ni mo sì wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, báwo ni ìwọ ti ṣe tan àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti Jerusalẹmu jẹ nípa sísọ wí pé, ‘Ìwọ yóò wà ní àlàáfíà,’ nígbà tí o jẹ́ wí pé idà wà ní ọ̀fun wa.”
11 Nígbà náà ni a ó sọ fún Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn pé, “Ẹ̀fúùfù líle láti aṣálẹ̀ fẹ́ lu àwọn ènìyàn mi, kì í ṣe láti sọ di mímọ́. 12 Ẹ̀fúùfù líle tí ó wá láti ọ̀dọ̀ mi. Báyìí mo kéde ìdájọ́ mi lórí wọn.”
13 Wò ó! O ń bọ̀ bí ìkùùkuu
kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ sì wá bí ìjì líle
ẹṣin rẹ̀ sì yára ju idì lọ
Ègbé ni fún wa àwa parun.
14 Ìwọ Jerusalẹmu, mú búburú kúrò lọ́kàn rẹ kí o sì yè
Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò mú èrò búburú wà ní ọkàn rẹ?
15 Ohùn kan sì ń kéde ní Dani
o ń kókìkí ìparun láti orí òkè Efraimu wá.
16 “Sọ èyí fún àwọn orílẹ̀-èdè,
kéde rẹ̀ fún Jerusalẹmu pé:
‘Ọmọ-ogun ọ̀tá ń bọ̀ láti ilẹ̀ jíjìn wá
wọ́n sì ń kígbe ogun láti dojúkọ ìlú Juda.
17 Wọ́n yí i ká bí ìgbà tí àwọn ọkùnrin bá ń ṣọ́ pápá,
nítorí pé ó ti dìtẹ̀ sí mi,’ ”
ni Olúwa wí.
18 “Ìwà rẹ àti ìṣe rẹ
ló fa èyí bá ọ
ìjìyà rẹ sì nìyìí,
Báwo ló ti ṣe korò tó!
Báwo ló ti ṣe gún ọkàn rẹ sí!”
19 Háà! Ìrora mi, ìrora mi!
Mo yí nínú ìrora.
Háà, ìrora ọkàn mi!
Ọkàn mi lù kìkì nínú mi,
n kò le è dákẹ́.
Nítorí mo ti gbọ́ ohùn ìpè,
mo sì ti gbọ́ igbe ogun.
20 Ìparun ń gorí ìparun;
gbogbo ilẹ̀ náà sì ṣubú sínú ìparun
lọ́gán ni a wó àwọn àgọ́ mi,
tí ó jẹ́ ohun ààbò mi níṣẹ́jú kan.
21 Yóò ti pẹ́ tó, tí èmi yóò rí ogun
tí èmi yóò sì gbọ́ ìró fèrè?
22 “Aṣiwèrè ni àwọn ènìyàn mi;
wọn kò mọ̀ mí.
Wọ́n jẹ́ aláìgbọ́n ọmọ;
wọ́n sì jẹ́ aláìlóye.
Wọ́n mọ ibi ni ṣíṣe;
wọn kò mọ bí a ti í ṣe rere.”
23 Mo bojú wo ayé,
ó sì wà ní júujùu, ó sì ṣófo
àti ní ọ̀run,
ìmọ́lẹ̀ wọn kò sì ṣí.
24 Mo wo àwọn òkè ńlá,
wọ́n wárìrì;
gbogbo òkè kéékèèkéé mì jẹ̀jẹ̀.
25 Mo wò yíká n kò rí ẹnìkan;
gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ló ti fò lọ.
26 Mo bojú wò, ilẹ̀ eléso, ó sì di aṣálẹ̀
gbogbo àwọn ìlú inú rẹ̀ sì ṣubú sínú ìparun
níwájú Olúwa àti níwájú ríru ìbínú rẹ̀.
27 Èyí ni ohun tí Olúwa wí
“Gbogbo ìlú náà yóò sì di ahoro,
síbẹ̀ èmi kì yóò pa á run pátápátá.
28 Nítorí náà, ayé yóò pohùnréré ẹkún
àwọn ọ̀run lókè yóò ṣú òòkùn
nítorí mo ti sọ, mo sì ti pète rẹ̀
mo ti pinnu, n kì yóò sì yí i padà.”
29 Nípa ariwo àwọn ẹlẹ́ṣin àti àwọn tafàtafà
gbogbo ìlú yóò sálọ.
Ọ̀pọ̀ sálọ sínú igbó;
ọ̀pọ̀ yóò sì gun orí àpáta lọ.
Gbogbo ìlú náà sì di ahoro;
kò sì ṣí ẹnìkan nínú rẹ̀.
30 Kí ni ò ń ṣe, ìwọ tí o ti di ìjẹ tán?
Ìwọ ìbá wọ ara rẹ ní aṣọ òdodo
kí o sì fi wúrà ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́.
Àwọn olólùfẹ́ rẹ kẹ́gàn rẹ
wọ́n sì ń lépa ẹ̀mí rẹ.
31 Mo gbọ́ ìró kan bí i igbe obìnrin tó ń rọbí,
tí ó ń rọbí, ìrora bí i abiyamọ
ọmọbìnrin Sioni tí ń pohùnréré ẹkún ara rẹ̀.
Tí ó na ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì wí pé,
“Kíyèsi i mo gbé,
Nítorí a ti fi ẹ̀mí mi lé àwọn apani lọ́wọ́.”
Kò sí ọ̀kan tí o jẹ́ olóòtítọ́
5 “Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu
wò yíká, kí o sì mọ̀,
kí o sì wá kiri
Bí o bá le è rí ẹnìkan,
tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo,
n ó dáríjì ìlú yìí.
2 Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’
síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
3 Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́
Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n.
Ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà.
Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ,
wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
4 Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí;
wọn jẹ́ aṣiwèrè,
nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa,
àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
5 Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ,
n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀;
ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa
àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.”
Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́,
wọ́n sì ti já ìdè.
6 Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n,
ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run,
ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín
ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,
nítorí àìgbọ́ràn yín pọ,
ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
7 “Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́?
Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀
àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra.
Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn,
síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà
wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
8 Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó,
tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
9 Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?”
ni Olúwa wí.
“Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi
lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
10 “Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run,
ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá.
Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò,
nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
11 Ilé Israẹli àti ilé Juda
ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,”
ni Olúwa wí.
12 Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa;
wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan!
Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá;
àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
13 Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́,
ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn.
Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
14 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí:
“Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí;
Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná,
àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
15 Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí,
“Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín
Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì
àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀,
tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
16 Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí
gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
17 Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ,
àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin,
wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ,
wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ.
Pẹ̀lú idà ni wọn ó run
ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
18 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá. 19 Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
20 “Kéde èyí fún ilé Jakọbu,
kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
21 (A)Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn,
tí ó lójú ti kò fi ríran
tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
22 Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí.
“Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí?
Mo fi yanrìn pààlà Òkun,
èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé.
Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀;
wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
23 Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀,
wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
24 Wọn kò sọ fún ara wọn pé,
‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa,
ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀,
tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
25 Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò,
ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
26 “Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà
tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ,
àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
27 Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ,
ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn.
Wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
28 Wọ́n sanra wọ́n sì ń dán.
Ìwà búburú wọn kò sì lópin;
wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀.
Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
29 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?”
ni Olúwa wí.
“Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi
lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
30 “Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara
ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
31 Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké,
àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn,
àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí,
kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?
Jerusalẹmu lábẹ́ ìgbèkùn
6 “Ẹ̀yin ènìyàn Benjamini, sá sí ibi ààbò!
Ẹ sá kúrò ní Jerusalẹmu,
Ẹ fọn fèrè ní Tekoa!
Kí ẹ gbé ààmì sókè lórí Beti-Hakeremu!
Nítorí àjálù farahàn láti àríwá,
àní ìparun tí ó lágbára.
2 Èmi yóò pa ọmọbìnrin Sioni run,
tí ó jẹ́ arẹwà àti ẹlẹgẹ́.
3 Olùṣọ́-àgùntàn pẹ̀lú agbo wọn yóò gbóguntì wọ́n.
Wọn yóò pa àgọ́ yí wọn ká,
olúkúlùkù yóò máa jẹ ní ilé rẹ̀.”
4 “Ẹ ya ará yín sí mímọ́ láti bá a jagun!
Dìde, kí a kọlù ú ní ìgbà ọ̀sán!
Ṣùgbọ́n ó ṣe, nítorí ọjọ́ lọ tán,
ọjọ́ alẹ́ náà sì gùn sí i.
5 Nítorí náà, ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú ní àṣálẹ́
kí a sì ba odi alágbára rẹ̀ jẹ́.”
6 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí:
“Ẹ ké àwọn igi náà lulẹ̀
kí ẹ sì mọ odi ààbò yí Jerusalẹmu ká.
Èyí ni ìlú títóbi tí a ó bẹ̀wò,
nítorí pé ó kún fún ìninilára.
7 Gẹ́gẹ́ bí kànga ṣe ń da omi inú rẹ̀ sílẹ̀,
náà ni ó ń tú ìwà búburú rẹ̀ jáde.
Ìwà ipá àti ìparun ń tún pariwo nínú rẹ̀;
nígbà gbogbo ni àìsàn àti ọgbẹ́ rẹ̀ ń wà níwájú mi.
8 Ìwọ Jerusalẹmu, gba ìkìlọ̀
kí Èmi kí ó má ba à lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ,
kí n sì sọ ilẹ̀ rẹ di ahoro,
tí kò ní ní olùgbé.”
9 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:
“Jẹ́ kí wọn pèsè ìyókù Israẹli
ní tónítóní bí àjàrà;
na ọwọ́ rẹ sí àwọn ẹ̀ka nì lẹ́ẹ̀kan sí i
gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan ti í kó èso àjàrà jọ.”
10 Ta ni ẹni tí mo lè bá sọ̀rọ̀ àti
tí mo lè fún ní ìmọ̀ràn? Ta ni
yóò tẹ́tí sílẹ̀ sí mi? Etí wọn
ti di, nítorí náà wọn kò lè gbọ́.
Ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ ohun búburú sí wọn,
wọn kò sì ní inú dídùn nínú rẹ̀.
11 Èmi kún fún ìbínú
Olúwa, èmi kò sì le è pa á mọ́ra.
“Tú u sí orí àwọn ọmọ ńigboro, àti
sórí àwọn ọmọkùnrin tí wọn kó ra
wọn jọ pọ̀, àti ọkọ àti aya ni a ò
mú sínú rẹ̀, àti àwọn arúgbó
tí ó ní ọjọ́ kíkún lórí.
12 Ilé wọn o sì di ti ẹlòmíràn,
oko wọn àti àwọn aya wọn,
nígbà tí èmi bá na ọwọ́ mi
sí àwọn olùgbé ilẹ̀ náà,”
ni Olúwa wí.
13 “Láti orí ẹni tí ó kéré sí orí
ẹni tí ó tóbi ju, gbogbo wọn
ni ó sì ní ojúkòkòrò fún èrè,
àwọn wòlíì àti àlùfáà lápapọ̀
sì kún fún ẹ̀tàn.
14 Wọ́n sì ń wo ọgbẹ́ àwọn ènìyàn
mi bí ẹni pé kò tó nǹkan.
Wọ́n ń wí pé, ‘Àlàáfíà, Àlàáfíà,’
nígbà tí kò sì sí àlàáfíà.
15 Ojú ha a tì wọ́n nítorí ìwà
ìríra wọn bí? Rárá, wọn kò
ní ìtìjú mọ́, wọn kò tilẹ̀ ní oorun ìtìjú
Nítorí náà, wọn ó ṣubú láàrín
àwọn tó ṣubú, a ó sì ké wọn
lulẹ̀ nígbà tí mo bá bẹ̀ wọ́n wò,”
ni Olúwa wí.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Ẹ dúró sí ìkóríta, kí ẹ sì wò,
ẹ béèrè fún ọ̀nà àtijọ́, ẹ béèrè
ẹ béèrè ọ̀nà dáradára nì, kí ẹ rìn nínú rẹ,
ẹ̀yin yóò sì rí ìsinmi fún ọkàn yín.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa kì yóò rìn nínú rẹ̀.’
17 Èmi yan olùṣọ́ fún un yín,
mo sì wí pé:
‘Tẹ́tí sí dídún fèrè náà,’
ẹ̀yìn wí pé, ‘Àwa kì yóò tẹ́tí sílẹ̀.’
18 Nítorí náà, gbọ́ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè
kíyèsi, kí ẹ sì jẹ́ ẹlẹ́rìí
ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí wọn.
19 Gbọ́, ìwọ ayé!
Mò ń mú ìparun bọ̀ sórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,
èso ìrò inú wọn,
nítorí wọn kò fi etí sí ọ̀rọ̀ mi,
wọ́n sì ti kọ òfin mi sílẹ̀.
20 Èrè wo ni ó wà fún mi nínú tùràrí láti Ṣeba wá,
tàbí èso dáradára láti ilẹ̀ jíjìn réré?
Ẹbọ sísun yín kò ṣe ìtẹ́wọ́gbà,
ọrẹ yín kò sì wù mí.”
21 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Èmi yóò gbé ohun ìdènà síwájú
àwọn ènìyàn wọ̀nyí, àwọn baba
àti ọmọ yóò jùmọ̀ ṣubú lù wọ́n,
àwọn aládùúgbò àti ọ̀rẹ́ yóò ṣègbé.”
22 Báyìí ni Olúwa wí:
“Wò ó, àwọn ọmọ-ogun ń bọ̀ wá láti ilẹ̀ àríwá,
a ó sì gbé orílẹ̀-èdè ńlá dìde
láti òpin ayé wá.
23 Wọ́n sì dìmọ́ra pẹ̀lú ọrun àti ọ̀kọ̀,
Wọ́n jẹ́ ẹni ibi, wọn kò sì ní àánú
wọ́n ń hó bí omi Òkun, bí wọ́n
ti ṣe ń gun àwọn ẹṣin wọn lọ;
wọ́n sì wá bí ọkùnrin tí yóò
jà ọ́ lógun, ìwọ ọmọbìnrin Sioni.”
24 Àwa ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn,
ọwọ́ wa sì di rírọ, ìrora sì mú wa
bí obìnrin tí ń rọbí.
25 Má ṣe jáde lọ sí orí pápá
tàbí kí o máa rìn ní àwọn
ojú ọ̀nà, nítorí ọ̀tá náà ní idà,
ìpayà sì wà níbi gbogbo.
26 Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀,
kí ẹ sì sùn nínú eérú,
ẹ ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ìpohùnréré ẹkún
gẹ́gẹ́ bí i lórí ọmọkùnrin yín kan ṣoṣo
nítorí pé lójijì ni àwọn apanirun yóò kọlù wá.
27 “Èmi ti fi ẹ́ ṣe ẹni tí yóò máa yọ́
irú àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bi irin
tútù, kí wọn kí ó lè ṣe àkíyèsí,
kí ó sì dán ọ̀nà wọn wò.
28 Ọlọ́tẹ̀ tí ọkàn rẹ̀ le ní gbogbo wọn.
Wọ́n ń lọ káàkiri láti sọ̀rọ̀-òdì.
Wọ́n jẹ́ idẹ àti irin,
wọ́n sì kún fún ìwà ìbàjẹ́.
29 Ewìrì a fẹ́ná kíkankíkan,
kí ó lè yọ́ òjé,
ẹni tí ń yọ́ ọ ń yọ́ ọ lásán;
a kò si ya ènìyàn búburú kúrò.
30 A pè wọ́n ní fàdákà tí a kọ̀sílẹ̀,
nítorí Olúwa ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀.”
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.