Chronological
Ìbéèrè Jobu
24 “Ṣe bí ìgbà kò pamọ́ lọ́dọ̀ Olódùmarè fún ìdájọ́?
Èéṣe tí ojúlùmọ̀ rẹ̀ kò fi rí ọjọ́ rẹ̀?
2 Wọ́n a sún ààmì ààlà ilẹ̀,
wọ́n á fi agbára kó agbo ẹran lọ, wọ́n a sì bọ́ wọn.
3 Wọ́n á sì da kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ aláìní baba
lọ, wọ́n a sì gba ọ̀dá màlúù opó ní ohun ògo.
4 Wọ́n á bi aláìní kúrò lójú ọ̀nà,
àwọn tálákà ayé a fi agbára sápamọ́.
5 Kíyèsi i, bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó nínú ijù ni àwọn tálákà jáde lọ sí iṣẹ́ wọn,
wọ́n a tètè dìde láti wá ohun ọdẹ;
ijù pèsè oúnjẹ fún wọn àti fún àwọn ọmọ wọn.
6 Olúkúlùkù a sì sá ọkà oúnjẹ ẹran rẹ̀ nínú oko,
wọn a sì ká ọgbà àjàrà ènìyàn búburú.
7 Ní ìhòhò ni wọn máa sùn láìní aṣọ,
tí wọn kò ní ìbora nínú òtútù.
8 Ọ̀wààrà òjò òkè ńlá sì pa wọ́n,
wọ́n sì lẹ̀ mọ́ àpáta nítorí tí kò sí ààbò.
9 Wọ́n já ọmọ aláìní baba kúrò ní ẹnu ọmú,
wọ́n sì gbà ọmọ tálákà nítorí gbèsè.
10 Wọ́n rìn kiri ní ìhòhò láìní aṣọ;
àwọn tí ebi ń pa rẹrù ìdì ọkà,
11 Àwọn ẹni tí ń fún òróró nínú àgbàlá wọn,
tí wọ́n sì ń tẹ ìfúntí àjàrà, síbẹ̀ òǹgbẹ sì ń gbẹ wọn.
12 Àwọn ènìyàn ń kérora láti ìlú wá,
ọkàn àwọn ẹni tí ó gbọgbẹ́ kígbe sókè fún ìrànlọ́wọ́
síbẹ̀ Ọlọ́run kò kíyèsi àṣìṣe náà.
13 “Àwọn ni ó wà nínú àwọn tí ó ṣọ̀tẹ̀ sí ìmọ́lẹ̀;
Wọn kò mọ̀ ipa ọ̀nà rẹ̀,
bẹ́ẹ̀ ni wọn kò dúró nípa ọ̀nà rẹ̀.
14 Apànìyàn a dìde ní àfẹ̀mọ́júmọ́,
a sì pa tálákà àti aláìní,
àti ní òru a di olè.
15 Ojú alágbèrè pẹ̀lú dúró kí ilẹ̀ ṣú díẹ̀;
‘Ó ní, ojú ẹnìkan kì yóò rí mi,’
ó sì fi ìbòjú bojú rẹ̀.
16 Ní òkùnkùn wọn á rúnlẹ̀ wọlé,
tí wọ́n ti fi ojú sọ fún ara wọn ní ọ̀sán,
wọn kò mọ̀ ìmọ́lẹ̀.
17 Nítorí pé bí òru dúdú ní òwúrọ̀ fún gbogbo wọn;
nítorí tí wọn sì mọ̀ ìbẹ̀rù òkùnkùn.
18 “Ó yára lọ bí ẹni lójú omi;
ìpín wọn ní ilé ayé ni a ó parun;
òun kò rìn lọ mọ́ ní ọ̀nà ọgbà àjàrà.
19 Gẹ́gẹ́ bi ọ̀dá àti òru ní í mú omi òjò-dídì yọ́,
bẹ́ẹ̀ ní isà òkú í run àwọn tó dẹ́ṣẹ̀.
20 Inú ìbímọ yóò gbàgbé rẹ̀, kòkòrò
ní yóò máa fi adùn jẹun lára rẹ̀,
a kì yóò rántí ènìyàn búburú
mọ́; Bẹ́ẹ̀ ní a ó sì ṣẹ ìwà búburú bí ẹní ṣẹ́ igi;
21 Ẹni tí o hù ìwà búburú sí àgàn tí
kò ṣe rere sí opó.
22 Ọlọ́run fi ipá agbára rẹ̀ fa alágbára,
bí wọ́n tilẹ̀ fìdímúlẹ̀, kò sí ìrètí ìyè fún wọn.
23 Ọlọ́run sì fi àìléwu fún un,
àti nínú èyí ni a ó sì tì i lẹ́yìn,
ojú rẹ̀ sì wà ní ipa ọ̀nà wọn.
24 A gbé wọn lékè nígbà díẹ̀, wọ́n kọjá lọ;
a sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀; A sì mú wọn kúrò ní ọ̀nà bí àwọn ẹlòmíràn,
a sì ké wọn kúrò bí orí síírí ọkà bàbà.
25 “Ǹjẹ́, bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ nísinsin yìí, ta ni yóò mú mi ní èké,
tí yóò sì sọ ọ̀rọ̀ mi di aláìníláárí?”
Ìdáhùn Bilidadi
25 Nígbà náà ní Bilidadi, ará Ṣuhi, dáhùn wí pé:
2 “Ìjọba àti ẹ̀rù ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀,
òun ní i ṣe ìlàjà ní ibi gíga gíga ọ̀run.
3 Àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ha ní ìyè bí,
tàbí ara ta ni ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ kò tàn sí?
4 Èéha ti ṣe tí a ó fi dá ènìyàn láre lọ́dọ̀ Ọlọ́run?
Tàbí ẹni tí a bí láti inú obìnrin wá yóò ha ṣe mọ́?
5 Kíyèsi i, òṣùpá kò sì lè tàn ìmọ́lẹ̀,
àní àwọn ìràwọ̀ kò mọ́lẹ̀ ní ojú rẹ̀,
6 kí a má sọ ènìyàn tí i ṣe ìdin,
àti ọmọ ènìyàn tí í ṣe kòkòrò!”
Ìdáhùn Jobu
26 Ṣùgbọ́n Jobu sì dáhùn wí pé:
2 Báwo ni ìwọ ń ṣe ìrànlọ́wọ́ ẹni tí kò ní ipá,
báwo ní ìwọ ń ṣe gbe apá ẹni tí kò ní agbára?
3 Báwo ni ìwọ ń ṣe ìgbìmọ̀ fun ẹni tí kò ní ọgbọ́n,
tàbí báwo òye rẹ to pọ to bẹ́ẹ̀?
4 Ta ni ó ràn ọ́ lọ́wọ́ láti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí,
àti ẹ̀mí ta ni ó gba ẹnu rẹ sọ̀rọ̀?
5 “Àwọn aláìlágbára ti isà òkú wárìrì,
lábẹ́ omi pẹ̀lú àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
6 Ìhòhò ni ipò òkú níwájú Ọlọ́run,
ibi ìparun kò sí ní ibojì.
7 Òun ní o nà ìhà àríwá ọ̀run ní ibi òfúrufú,
ó sì so ayé rọ̀ ní ojú asán.
8 Ó di omi pọ̀ nínú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ̀ tí ó nípọn;
àwọsánmọ̀ kò sì ya nísàlẹ̀ wọn.
9 Ó sì fa ojú ìtẹ́ rẹ̀ sẹ́yìn,
ó sì tẹ àwọsánmọ̀ rẹ̀ sí i lórí.
10 Ó fi ìdè yí omi Òkun ká,
títí dé ààlà ìmọ́lẹ̀ àti òkùnkùn.
11 Ọ̀wọ́n òpó ọ̀run wárìrì,
ẹnu sì yà wọ́n sì ìbáwí rẹ̀.
12 Ó fi ipá rẹ̀ dààmú omi Òkun;
nípa òye rẹ̀, ó gé agbéraga sí wẹ́wẹ́.
13 Nípa ẹ̀mí rẹ̀ ni ó ti ṣe ọ̀run ní ọ̀ṣọ́;
ọwọ́ rẹ̀ ni ó fi dá ejò wíwọ́ nì.
14 Kíyèsi i, èyí ní òpin ọ̀nà rẹ̀;
ohùn èyí tí a gbọ́ ti kéré tó!
Ta ni ẹni náà tí òye àrá agbára rẹ̀ lè yé?”
27 Pẹ̀lúpẹ̀lú Jobu sì tún sọkún ọ̀rọ̀ òwe rẹ̀, ó sì wí pé:
2 “Bí Ọlọ́run ti ń bẹ, ẹni tí ó gba ìdájọ́ mi lọ,
àti Olódùmarè tí ó bà mi ní ọkàn jẹ́;
3 (Níwọ́n ìgbà tí ẹ̀mí mi ń bẹ nínú mi,
àti tí ẹ̀mí Ọlọ́run ń bẹ nínú ihò imú mi.)
4 Ètè mi kì yóò sọ̀rọ̀ èké,
Bẹ́ẹ̀ ni ahọ́n mi kì yóò sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.
5 Kí a má rí i pé èmi ń dá yín láre;
títí èmi ó fi kú, èmi kì yóò ṣí ìwà òtítọ́ mi kúrò lọ́dọ̀ mi.
6 Òdodo mi ni èmi dìímú ṣinṣin, èmi kì yóò sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́;
àyà mi kì yóò sì gan ọjọ́ kan nínú ọjọ́ ayé mi.
7 “Kí ọ̀tá mi kí ó dàbí ènìyàn búburú,
àti ẹni tí ń dìde sí mi kí ó dàbí ẹni aláìṣòdodo.
8 Nítorí kí ni ìrètí àgàbàgebè,
nígbà tí Ọlọ́run bá ké ẹ̀mí rẹ̀ kúrò, nígbà tí ó sì fà á jáde?
9 Ọlọ́run yóò ha gbọ́ àdúrà rẹ̀,
nígbà tí ìpọ́njú bá dé sí i?
10 Òun ha le ní inú dídùn sí Olódùmarè?
Òun ha lé máa ké pe Ọlọ́run nígbà gbogbo?
11 “Èmi ó kọ́ yín ní ẹ̀kọ́ ní ti ọwọ́ Ọlọ́run:
ọ̀nà tí ń bẹ lọ́dọ̀ Olódùmarè ni èmi kì yóò fi pamọ́.
12 Kíyèsi i, gbogbo yín ni ó ti rí i;
kín ni ìdí ọ̀rọ̀ asán yín?
13 “Ẹ̀yin ni ìpín ènìyàn búburú lọ́dọ̀ Ọlọ́run,
àti ogún àwọn aninilára, tí wọ́n ó gbà lọ́wọ́ Olódùmarè:
14 Bí àwọn ọmọ rẹ bá di púpọ̀, fún idà ni;
àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ kì yóò yó fún oúnjẹ.
15 Àwọn tí ó kù nínú tirẹ̀ ni a ó sìnkú nínú àjàkálẹ̀-ààrùn:
àwọn opó rẹ̀ kì yóò sì sọkún fún wọn.
16 Bí ó tilẹ̀ kó fàdákà jọ bí erùpẹ̀,
tí ó sì dá aṣọ jọ bí amọ̀;
17 àwọn ohun tí ó tò jọ àwọn olóòtítọ́ ni yóò lò ó;
àwọn aláìṣẹ̀ ni yóò sì pín fàdákà rẹ̀.
18 Òun kọ́ ilé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí kòkòrò aṣọ,
àti bí ahéré tí olùṣọ́ kọ́.
19 Ọlọ́rọ̀ yóò dùbúlẹ̀, ṣùgbọ́n òun kì yóò túnṣe bẹ́ẹ̀ mọ́;
Nígbà tí ó bá la ojú rẹ̀, gbogbo rẹ̀ a lọ
20 Ẹ̀rù ńlá bà á bí omi ṣíṣàn;
ẹ̀fúùfù ńlá jí gbé lọ ní òru.
21 Ẹ̀fúùfù ìlà-oòrùn gbé e lọ, òun sì lọ;
àti bí ìjì ńlá ó sì fà á kúrò ní ipò rẹ̀.
22 Nítorí pé Olódùmarè yóò kọlù ú, kì yóò sì dá sí;
òun ìbá yọ̀ láti sá kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
23 Àwọn ènìyàn yóò sì ṣápẹ́ sí i lórí,
wọn yóò sì ṣe síọ̀ sí i kúrò ní ipò rẹ̀.”
Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n àti òye Jobu
28 Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ,
àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
2 Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin,
bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
3 Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn,
ó sì ṣe àwárí ìṣúra
láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
4 Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè,
àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀,
wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
5 Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá,
àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná
6 Òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta Safire,
o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
7 Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀,
àti ojú gúnnugún kò rí i rí;
8 Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí,
bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
9 Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta,
ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
10 Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta,
ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
11 Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya,
ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.
12 Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí,
níbo sì ni òye ń gbe?
13 Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀,
bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
14 Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”;
omi Òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”
15 A kò le è fi wúrà rà á,
bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òṣùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
16 A kò le è fi wúrà ofiri,
tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta Safire díye lé e.
17 Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;
bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.
18 A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi;
iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.
19 Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;
bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
20 Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá?
Tàbí níbo ni òye ń gbé?
21 A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo,
ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
22 Ibi ìparun àti ikú wí pé,
àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
23 Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀,
òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.
24 Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé,
ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
25 Láti dà òṣùwọ̀n fún afẹ́fẹ́,
ó sì fi òṣùwọ̀n wọ́n omi.
26 Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò,
tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
27 Nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde;
ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
28 Àti fún ènìyàn ni ó wí pé,
“Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n,
àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.