Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Chronological

Read the Bible in the chronological order in which its stories and events occurred.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Jobu 6-9

Ìdáhùn Jobu

Jobu sì dáhùn ó si wí pé:

“Háà! À bá lè wọ́n ìbìnújẹ́ mi nínú òṣùwọ̀n,
    kí a sì le gbé ọ̀fọ̀ mi lé orí òṣùwọ̀n ṣọ̀kan pọ̀!
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìbá wúwo jú iyanrìn Òkun lọ:
    nítorí náà ni ọ̀rọ̀ mi ṣe ń tàsé
Nítorí pé ọfà Olódùmarè wọ̀ mi nínú,
    oró èyí tí ọkàn mi mú;
    ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí.
Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko,
    tàbí ọ̀dá màlúù a máa dún lórí ìjẹ rẹ̀?
A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀,
    tàbí adùn ha wà nínú funfun ẹyin?
Ohun ti ọ̀kan mi kọ̀ láti tọ́wò,
    òun ni ó dàbí oúnjẹ tí ó mú mi ṣàárẹ̀.

“Háà! èmi ìbá lè rí ìbéèrè mi gbà;
    àti pé, kí Ọlọ́run lè fi ohun tí èmi ṣàfẹ́rí fún mi.
Àní Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa mí run,
    tí òun ìbá jẹ́ ṣíwọ́ rẹ̀ kì ó sì ké mi kúrò.
10 Nígbà náà ní èmi ìbá ní ìtùnú síbẹ̀,
    àní, èmi ìbá mú ọkàn mi le nínú ìbànújẹ́ mi ti kò dá ni sí:
    nítorí èmi kò fi ọ̀rọ̀ ẹni mímọ́ ni sin rí.

11 “Kí ní agbára mi tí èmi ó fi retí?
    Kí sì ní òpin mi tí èmi ó fi ní sùúrù?
12 Agbára mi ha ṣe agbára òkúta bí?
    Ẹran-ara mi í ṣe idẹ?
13 Ìrànlọ́wọ́ mi kò ha wà nínú mi:
    ọgbọ́n kò ha ti sálọ kúrò lọ́dọ̀ mi bí?

14 “Ẹni tí àyà rẹ̀ yọ́ dànù, ta ni a bá máa ṣàánú fún láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ wá,
    kí ó má ba à kọ ìbẹ̀rù Olódùmarè sílẹ̀?
15 Àwọn ará mi dàbí odò tí kò ṣe gbẹ́kẹ̀lé
    bí ìṣàn omi odò, wọ́n sàn kọjá lọ.
16 Tí ó dúdú nítorí omi dídì,
    àti níbi tí yìnyín dídì gbé di yíyọ́.
17 Nígbàkúgbà tí wọ́n bá gbóná wọn a sì yọ́ sàn lọ,
    nígbà tí oòrùn bá mú, wọn a sì gbẹ kúrò ni ipò wọn.
18 Àwọn oníṣòwò yà kúrò ní ọ̀nà wọn,
    wọ́n gòkè sí ibi asán, wọ́n sì run.
19 Ẹgbẹ́ oníṣòwò Tema ń wá omi,
    àwọn oníṣòwò Ṣeba ń dúró dè wọ́n ní ìrètí.
20 Wọ́n káàárẹ̀, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e;
    wọ́n dé bẹ̀, wọ́n sì dààmú.
21 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin dàbí wọn;
    ẹ̀yin rí ìrẹ̀sílẹ̀ mi àyà sì fò mí.
22 Èmi ó ha wí pé, ‘Ẹ mú ohun fún mi wá,
    tàbí pé ẹ fún mi ní ẹ̀bùn nínú ohun ìní yín?
23 Tàbí, ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá ni,
    tàbí, ẹ rà mí padà kúrò lọ́wọ́ alágbára nì’?

24 “Ẹ kọ́ mi, èmi ó sì pa ẹnu mi mọ́
    kí ẹ sì mú mi wòye níbi tí mo gbé ti ṣìnà.
25 Wò ó! Bí ọ̀rọ̀ òtítọ́ ti lágbára tó
    ṣùgbọ́n kí ni àròyé ìbáwí yín jásí?
26 Ẹ̀yin ṣè bí ẹ tún ọ̀rọ̀ mi ṣe
    àti ohùn ẹnu tí ó dàbí afẹ́fẹ́ ṣe àárẹ̀.
27 Àní ẹ̀yin ṣe gẹ́gẹ́ bí aláìní baba,
    ẹ̀yin sì da iye lé ọ̀rẹ́ yín.

28 “Nítorí náà, kí èyí kí ó tó fún yín.
    Ẹ má wò mi! Nítorí pé ó hàn gbangba pé:
    Ní ojú yín ni èmi kì yóò ṣèké.
29 Èmi ń bẹ̀ yín, ẹ padà, kí ó má sì ṣe jásí ẹ̀ṣẹ̀;
    àní, ẹ sì tún padà, àre mi ń bẹ nínú ọ̀rọ̀ yìí.
30 Àìṣedéédéé ha wà ní ahọ́n mi?
    Ǹjẹ́ ìtọ́wò ẹnu mi kò kúkú le mọ ohun ti ó burú jù?

Jobu ha ni ìrètí bí?

“Ṣé ìjà kò ha si fún ènìyàn lórí ilẹ̀?
    Ọjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kò ha dàbí ọjọ́ alágbàṣe?
Bí ọmọ ọ̀dọ̀ tí máa ń kánjú bojú wo òjìji,
    àti bí alágbàṣe ti í kánjú wo ọ̀nà owó iṣẹ́ rẹ̀.
Bẹ́ẹ̀ ni a mú mi ní ìbànújẹ́ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oṣù,
    òru ìdáni-lágara ni a sì là sílẹ̀ fún mi.
Nígbà ti mo dùbúlẹ̀, èmi wí pé, ‘Nígbà wo ni èmi ó dìde?’
    Tí òru yóò sì kọjá, ó sì tó fún mi láti yí síhìn-ín yí sọ́hùn-ún, títí yóò fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
Kòkòrò àti ògúlùtu erùpẹ̀ ni á fi wọ̀ mi ni aṣọ,
    awọ ara mi bù, o sì di bíbàjẹ́.

“Ọjọ́ mi yára jù ọkọ̀ ìhunṣọ lọ,
    o sì di lílò ní àìní ìrètí.
Háà! Rántí pé afẹ́fẹ́ ni ẹ̀mí mi;
    ojú mi kì yóò padà rí rere mọ́.
Ojú ẹni tí ó rí mi, kì yóò rí mi mọ́;
    ojú rẹ̀ tẹ̀ mọ́ra mi, èmi kò sí mọ́.
Bí ìkùùkuu tí i túká, tí í sì fò lọ,
    bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sí ipò òkú tí kì yóò padà wa mọ́.
10 Kì yóò padà sínú ilé rẹ̀ mọ́,
    bẹ́ẹ̀ ní ipò rẹ̀ kì yóò mọ̀ ọn mọ́.

11 “Nítorí náà èmi kì yóò pa ẹnu mi mọ́,
    èmi yóò máa sọ nínú ìrora ọkàn mi,
    èmi yóò máa ṣe ìráhùn nínú kíkorò ọkàn mi.
12 Èmi a máa ṣe Òkun tàbí ẹ̀mí búburú,
    tí ìwọ fi ń yan olùṣọ́ tì mi?
13 Nígbà tí mo wí pé, ibùsùn mi yóò tù mí lára,
    ìtẹ́ mi yóò mú ara mi fúyẹ́ pẹ̀lú.
14 Nígbà náà ni ìwọ fi àlá da yọ mi lénu bò mi,
    ìwọ sì fi ìran òru dẹ́rùbà mí.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mí yàn láti fún pa
    àti ikú ju kí ń wà láààyè ní ipò tí ara mí wà yìí lọ.
16 O sú mi, èmi kò le wà títí:
    jọ̀wọ́ mi jẹ́, nítorí pé asán ni ọjọ́ mi.

17 (A)“Kí ni ènìyàn tí ìwọ o máa kókìkí rẹ̀?
    Àti tí ìwọ ìbá fi gbé ọkàn rẹ lé e?
18 Àti ti ìwọ ó fi máa wá í bẹ̀ ẹ́ wò ni òròòwúrọ̀,
    ti ìwọ o sì máa dán an wò nígbàkúgbà!
19 Yóò ti pẹ́ tó kí ìwọ kí ó tó fi mí sílẹ̀ lọ,
    tí ìwọ o fi mí sílẹ̀ jẹ́ẹ́ títí èmi yóò fi lè dá itọ́ mi mì.
20 Èmi ti ṣẹ̀, ki ní èmi ó ṣe sí ọ.
    Ìwọ Olùsójú ènìyàn?
Èéṣe tí ìwọ fi fi mí ṣe ààmì itasi níwájú rẹ,
    bẹ́ẹ̀ ni èmi sì di ẹrẹ̀ wíwo fún ọ?
21 Èéṣe tí ìwọ kò sì dárí ìrékọjá mi jìn,
    kí ìwọ kí ó sì mú àìṣedéédéé mi kúrò?
Ǹjẹ́ nísinsin yìí ni èmi ìbá sùn nínú erùpẹ̀,
    ìwọ ìbá sì wá mi kiri ní òwúrọ̀, èmi kì bá tí sí.”

Bilidadi

Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé:

“Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó?
    Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?
Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí?
    Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?
Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i,
    ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.
Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò,
    tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.
Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin:
    ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ,
    òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.
Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í,
    bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.

“Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì
    kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.
Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan,
    nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.
10 Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ?
    Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?
11 Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀
    tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?
12 Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀,
    ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀
13 Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run,
    bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.
14 Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò,
    àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.
15 Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró,
    yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.
16 Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn,
    ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.
17 Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká,
    ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.
18 Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀,
    nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’
19 Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù
    àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.

20 “Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù,
    bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́
21 títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu,
    àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,
22 ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀,
    àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”

Jobu Fún Bilidadi lésì Nípa Ẹ̀kọ́ àti ẹ̀rí Ìdájọ́ Ọlọ́run

Jobu sì dáhùn ó sì wí pé:

“Èmi mọ̀ pe bẹ́ẹ̀ ni ní òtítọ́.
    Báwo ní ènìyàn yóò ha ti ṣe jẹ́ aláre níwájú Ọlọ́run?
Bí ó bá ṣe pé yóò bá a jà,
    òun kì yóò lè dalóhùn kan nínú ẹgbẹ̀rún ọ̀rọ̀.
Ọlọ́gbọ́n nínú àwọn alágbára ní ipa ní Òun;
    ta ni ó ṣe agídí sí i tí ó sì gbé fún rí?
Ẹni tí ó sí òkè nídìí tí wọn kò sì mọ́:
    tí ó taari wọn ṣubú ní ìbínú rẹ̀.
Tí ó mi ilẹ̀ ayé tìtì kúrò ní ipò rẹ̀,
    ọwọ́n rẹ̀ sì mì tìtì.
Ó pàṣẹ fún oòrùn kò sì le è ràn,
    kí ó sì dí ìmọ́lẹ̀ ìràwọ̀ mọ́.
Òun nìkan ṣoṣo ni ó ta ojú ọ̀run,
    ti ó sì ń rìn lórí ìgbì Òkun.
Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Beari, Orioni
    àti Pleiadesi àti ìràwọ̀ púpọ̀ ti gúúsù.
10 Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwárí lọ,
    àní ohun ìyanu láìní iye.
11 Kíyèsi i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi, èmi kò sì rí i,
    ó sì kọjá síwájú, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò rí ojú rẹ̀.
12 Kíyèsi i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà?
    Ta ni yóò bi í pé kí ni ìwọ ń ṣe nì?
13 Ọlọ́run kò ní fa ìbínú rẹ̀ sẹ́yìn,
    àwọn onírànlọ́wọ́ ti Rahabu a sì tẹríba lábẹ́ rẹ̀.

14 “Kí ní ṣe tí èmi ti n o fi ba ṣàròyé?
    Tí èmi yóò fi ma ṣe àwáwí?
15 Bí ó tilẹ̀ ṣe pé mo ṣe aláìlẹ́bi, èmi kò gbọdọ̀ dá a lóhùn;
    ṣùgbọ́n èmi ó gbàdúrà fún àánú.
16 Bí èmi bá sì ké pè é, tí Òun sì dá mi lóhùn,
    èmi kì yóò sì gbàgbọ́ pé, Òun ti fetí sí ohùn mi.
17 Nítorí pé òun yóò lọ̀ mí lúúlúú pẹ̀lú ìjì ńlá,
    ó sọ ọgbẹ́ mi di púpọ̀ láìnídìí.
18 Òun kì yóò jẹ́ kí èmi kí ó rí ẹ̀mí mi,
    ṣùgbọ́n ó mú ohun kíkorò kún un fún mi.
19 Bí mo bá sọ ti agbára, wò ó!
    Alágbára ni, tàbí ní ti ìdájọ́, ta ni yóò dá àkókò fún mi láti rò?
20 Bí mo tilẹ̀ dá ara mi láre, ẹnu ara mi yóò dá mi lẹ́bi;
    bí mo wí pé olódodo ni èmi yóò sì fi mí hàn ní ẹni ẹ̀bi.

21 “Olóòótọ́ ni mo ṣe,
    síbẹ̀ èmi kò kíyèsi ara mi,
    ayé mi ní èmi ìbá máa gàn.
22 Ohùn kan náà ni, nítorí náà ni èmi ṣe sọ:
    ‘Òun a pa ẹni òtítọ́ àti ènìyàn búburú pẹ̀lú.’
23 Bí ìjàǹbá bá pa ni lójijì,
    yóò rẹ́rìn-ín nínú ìdààmú aláìṣẹ̀.
24 Nígbà tí a bá fi ayé lé ọwọ́ ènìyàn búburú;
    ó sì bo àwọn onídàájọ́ rẹ̀ lójú;
    bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ ǹjẹ́ ta ni?

25 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí ọjọ́ mi yára ju oníṣẹ́ lọ,
    wọ́n fò lọ, wọn kò rí ayọ̀.
26 Wọ́n kọjá lọ bí ọkọ̀ eèsún papirusi tí ń sáré lọ;
    bí idì tí ń yára si ohùn ọdẹ.
27 Bí èmi bá wí pé, ‘Èmi ó gbàgbé arò ìbìnújẹ́ mi,
    èmi ó fi ọkàn lélẹ̀, èmi ó sì rẹ ara mi lẹ́kún.’
28 Ẹ̀rù ìbànújẹ́ mi gbogbo bà mí,
    èmi mọ̀ pé ìwọ kì yóò mú mi bí aláìṣẹ̀.
29 Bí ó bá ṣe pé ènìyàn búburú ni èmi,
    ǹjẹ́ kí ni èmi ń ṣe làálàá lásán sí?
30 Bí mo tilẹ̀ fi ọṣẹ dídì wẹ ara mi,
    tí mo fi omi aró wẹ ọwọ́ mi mọ́,
31 síbẹ̀ ìwọ ó gbé mi wọ inú ihò
    ọ̀gọ̀dọ̀ aṣọ ara mi yóò sọ mi di ìríra.

32 “Nítorí Òun kì í ṣe ènìyàn bí èmi,
    tí èmi ó fi dá a lóhùn tí àwa o fi pàdé ní ìdájọ́.
33 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí alátúnṣe kan ní agbede-méjì wa
    tí ìbá fi ọwọ́ rẹ̀ lé àwa méjèèjì lára.
34 Kí ẹnìkan sá à mú ọ̀pá Ọlọ́run kúrò lára mi,
    kí ìbẹ̀rù rẹ̀ kí ó má sì ṣe dáyà fò mí
35 Nígbà náà ni èmi ìbá sọ̀rọ̀, èmi kì bá sì bẹ̀rù rẹ̀;
    ṣùgbọ́n bí ó tí dúró tì mí, kò ri bẹ́ẹ̀ fún mi.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.