Beginning
24 Má ṣe ṣe ìlara àwọn ènìyàn búburú
má ṣe jẹ́ kí àwùjọ wọn wù ọ́;
2 Nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ohun búburú,
ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ nípa dídá rúgúdù sílẹ̀.
3 Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́
nípa òye sì ni ó ti fìdímúlẹ̀;
4 Nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kún
pẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.
5 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀,
ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára sí i
6 Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà:
nínú ìṣẹ́gun ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.
7 Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrè
àti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.
8 Ẹni tí ń pète ibi
ni a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.
9 Ète òmùgọ̀ ènìyàn jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀,
àwọn ènìyàn sì kórìíra ẹlẹ́gàn.
10 Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmú
báwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!
11 Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ sí ibi ikú là;
fa àwọn tó ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lọ sí ibi ìparun padà.
12 Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkan kan nípa èyí,”
ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsi i? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́n?
Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?
13 Jẹ oyin, ìwọ ọmọ mi, nítorí tí ó dára,
oyin láti inú afárá oyin dùn lẹ́nu.
14 Mọ̀ pẹ̀lú pé ọgbọ́n pẹ̀lú dùn fún ọkàn rẹ
bí ìwọ bá rí i ìrètí ọjọ́ iwájú wà fún ọ
ìrètí rẹ kì yóò sì já ṣófo.
15 Má ṣe ba ní ibùba bí ènìyàn búburú
láti gba ibùjókòó olódodo,
má ṣe fi ibi ìsinmi rẹ̀ ṣe ìjẹ;
16 nítorí bí olódodo ènìyàn bá tilẹ̀ ṣubú ní ìgbà
méje, yóò tún padà dìde sá á ni,
ṣùgbọ́n ìdààmú yóò fa ènìyàn búburú lulẹ̀.
17 Má ṣe yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú;
nígbà tí ó bá kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yọ̀.
18 Àìṣe bẹ́ẹ̀ Olúwa yóò rí i yóò sì bínú
yóò sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
19 Má ṣe fòyà nítorí àwọn ènìyàn ibi
tàbí jowú àwọn ènìyàn búburú,
20 nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájú
a ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.
21 Bẹ̀rù Olúwa àti ọba, ọmọ mi,
má sì ṣe darapọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí kunkun.
22 Nítorí àwọn méjèèjì yóò rán ìparun òjijì sórí wọn,
ta ni ó sì mọ irú ìyọnu tí wọ́n lè mú wá?
Àwọn ọrọ̀ ọlọ́gbọ́n mìíràn
23 Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú tún jẹ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n:
láti ṣe ojúsàájú níbi ìdájọ́ kò dára rárá:
24 Ẹnikẹ́ni tí ó wí fún ẹlẹ́bi pé, “Ìwọ lo jàre”
àwọn ènìyàn yóò ṣẹ́ èpè fún un àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì kọ̀ ọ́.
25 Ṣùgbọ́n yóò dára fún àwọn tí ń dá ẹlẹ́bi lẹ́bi,
ọ̀pọ̀ ìbùkún yóò sì wá sórí wọn.
26 Ìdáhùn òtítọ́
dàbí ìfẹnu-koni-ní-ẹnu.
27 Parí gbogbo iṣẹ́ ajé rẹ
sì rí i pé oko rẹ ti ṣe dáradára;
lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.
28 Má ṣe rojọ́ èké mọ́ aládùúgbò rẹ láìnídìí,
tàbí kí o fi ètè rẹ tannijẹ.
29 Má ṣe wí pé, “Èmi yóò ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún mi;
Èmi yóò san ohun tí ó ṣe fún mi padà fún un.”
30 Mo kọjá níbi oko ọ̀lẹ,
mo kọjá níbi ọgbà àjàrà aláìgbọ́n ènìyàn;
31 ẹ̀gún ti hù ní ibi gbogbo,
koríko ti gba gbogbo oko náà
32 Mo fi ọkàn mi sí nǹkan tí mo kíyèsi
mo sì kẹ́kọ̀ọ́ lára ohun tí mo rí;
33 oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀,
ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi
34 Òsì yóò sì dé bá ọ bí adigunjalè
àti àìní bí olè.
Àwọn òwe mìíràn ti Solomoni
25 Wọ̀nyí ni àwọn òwe mìíràn tí Solomoni pa,
tí àwọn ọkùnrin Hesekiah ọba Juda dà kọ.
2 Ògo Ọlọ́run ní láti fi ọ̀rọ̀ kan pamọ́;
láti rí ìdí ọ̀rọ̀ kan ni ògo àwọn ọba.
3 Bí ọ̀run ṣe ga tó tí ayé sì jì
bẹ́ẹ̀ ni ó ṣòro láti mọ èrò ọkàn ọba.
4 Mú ìdàrọ́ kúrò lára fàdákà
ohun èlò yóò sì jáde fún alágbẹ̀dẹ fàdákà
5 Mú ènìyàn búburú kúrò níwájú ọba
a ó sì fìdí ìtẹ́ rẹ múlẹ̀ nípasẹ̀ òdodo.
6 Má ṣe gbé ara rẹ ga níwájú ọba,
má sì ṣe jìjàdù ààyè láàrín àwọn ènìyàn pàtàkì
7 Ó sàn kí ó wí fún ọ pé, “Gòkè wá síhìn-ín”
ju wí pé kí ó dójútì ọ́ níwájú ènìyàn pàtàkì.
8 Ohun tí o ti fi ojú ara rẹ rí
má ṣe kánjú gbé e lọ sílé ẹjọ́ nítorí kí ni ìwọ yóò ṣe ní ìgbẹ̀yìn
bí aládùúgbò rẹ bá dójútì ọ́?
9 Bí o bá ń ṣe àwíjàre rẹ níwájú aládùúgbò rẹ,
má ṣe tú àṣírí tí ẹlòmíràn ní lọ́dọ̀ rẹ,
10 àìṣe bẹ́ẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ le dójútì ọ́
orúkọ búburú tí ìwọ bá sì gba kì yóò tán láéláé.
11 Ọ̀rọ̀ tí a sọ ní àkókò tí ó yẹ
ó dàbí èso wúrà nínú àpẹẹrẹ fàdákà.
12 Bí i yẹtí wúrà tàbí ohun ọ̀ṣọ́ ti wúrà dáradára
ni ìbáwí ọlọ́gbọ́n fún etí tí ó bá fetísílẹ̀.
13 Bí títutù òjò yìnyín ní àsìkò ìkórè
ni ìránṣẹ́ tí ó jẹ́ olóòtítọ́ sí àwọn tí ó rán an
ó ń tu ọ̀gá rẹ̀ nínú.
14 Bí ojú ṣíṣú àti afẹ́fẹ́ láìsí òjò
ni ènìyàn tí ń yangàn nípa ẹ̀bùn tí kò fún ni.
15 Nípa sùúrù a lè yí ọba lọ́kàn padà
ahọ́n tí ń sọ̀rọ̀ rírọ̀ sí egungun.
16 Bí ìwọ bá rí oyin, jẹ ẹ́ ní ìwọ̀nba
bí o bá jẹ ẹ́ jù, ìwọ yóò sì bì í.
17 Má ṣe máa lọ sí ilé aládùúgbò rẹ nígbà gbogbo
tàbí kí ó máa lọ síbẹ̀ lálọ jù, yóò sì kórìíra rẹ.
18 Bí ọ̀pá, idà tàbí ọ̀kọ̀ tí ó mú
ni ènìyàn tí ó jẹ́rìí èké lòdì sí aládùúgbò rẹ̀.
19 Bí eyín tí ó bàjẹ́ tàbí ẹsẹ̀ tí ó rọ
ni ìgbẹ́kẹ̀lé lórí aláìṣòótọ́ ní àsìkò ìdààmú.
20 Bí ẹni tí ó bọ́ra kalẹ̀ ní ọjọ́ tí òtútù mú,
tàbí, bí ọtí kíkan tí a dà sí ojú ọgbẹ́,
ní ẹni tí ń kọ orin fún ẹni tí ọkàn rẹ̀ bàjẹ́.
21 (A)Bí ebi bá ń pa ọ̀tá rẹ, fún un ní oúnjẹ jẹ;
bí òǹgbẹ bá ń gbẹ ẹ́, fún un ní omi mú.
22 Nípa ṣíṣe báyìí, ìwọ yóò wa ẹ̀yín iná lé e lórí
Olúwa yóò sì san ọ ní ẹ̀san rẹ̀ fún ọ.
23 Bí afẹ́fẹ́ gúúsù ti í mú òjò wá,
bí ahọ́n tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀yìn ṣe ń mú ojú ìbínú wá.
24 Ó sàn láti gbé ní ibi igun kan lórí òrùlé
ju láti bá aya oníjà gbé ilé pọ̀.
25 Bí omi tútù sí ọkàn tí ń ṣe àárẹ̀
ni ìròyìn ayọ̀ láti ọ̀nà jíjìn.
26 Bí ìsun tí ó di àbàtà tàbí kànga tí omi rẹ̀ bàjẹ́
ni olódodo tí ó fi ààyè gba ènìyàn búburú.
27 Kò dára láti jẹ oyin àjẹjù,
bẹ́ẹ̀ ni kò pọ́n ni lé láti máa wá ọlá fún ara ẹni.
28 Bí ìlú tí odi rẹ̀ ti wó lulẹ̀
ni ènìyàn tí kò le kó ara rẹ̀ ní ìjánu.
26 Bí òjò-dídì tàbí òjò ní ìgbà ìkórè
ọlá kò yẹ aláìgbọ́n ènìyàn.
2 Bí ológoṣẹ́ tí ń ṣí kiri tàbí alápáǹdẹ̀dẹ̀ tí ń rábàbà
èpè kò le è mọ́ ẹni tí kò ṣiṣẹ́ èpè
èpè kì í jani bí a kò bá ṣiṣẹ́ èpè.
3 Ẹgba fún ẹṣin, ìjánu fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́
àti pàṣán fún ẹ̀yìn aṣiwèrè.
4 Má ṣe dá aláìgbọ́n lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà òmùgọ̀ rẹ̀
àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ pẹ̀lú yóò dàbí i rẹ̀.
5 Dá aláìgbọ́n lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà òmùgọ̀ rẹ̀
àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò dàbí ọlọ́gbọ́n lójú ara rẹ̀.
6 Bí ìgbà tí ènìyàn gé ẹsẹ̀ ara rẹ̀ tàbí mú ìwà ipá
ni kí a ránṣẹ́ nípasẹ̀ aṣiwèrè.
7 Bí ẹsẹ̀ arọ tí ó ń mi dirodiro
ni òwe lẹ́nu aṣiwèrè.
8 Bí ìgbà tí a so òkúta mọ́ okùn títa
ni fífún aláìgbọ́n ní ọlá.
9 Bí ẹ̀gún èṣùṣú lọ́wọ́ ọ̀mùtí
ni òwe lẹ́nu aláìgbọ́n.
10 Bí tafàtafà ti ń ṣe ni léṣe lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan
ni ẹni tí ó gba aṣiwèrè ṣíṣẹ́ tàbí ẹni tí ń kọjá lọ.
11 (B)Bí ajá ti í padà sí èébì rẹ̀
bẹ́ẹ̀ ni aṣiwèrè tún ń hu ìwà òmùgọ̀ rẹ̀.
12 Ǹjẹ́ o rí ènìyàn tí ó jẹ́ ọlọ́gbọ́n ní ojú ara rẹ̀?
Ìrètí ń bẹ fún aláìgbọ́n ènìyàn jù ú lọ.
13 Ọ̀lẹ wí pé: “Kìnnìún wà lójú ọ̀nà
kìnnìún búburú ń ké ní ojú ọ̀nà.”
14 Bí ìlẹ̀kùn ti ń yí lórí ìsolẹ̀kùn rẹ̀,
bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ ń yí lórí ibùsùn rẹ̀.
15 Ọ̀lẹ ki ọwọ́ rẹ̀ bọ inú àwo oúnjẹ,
ó lẹ dé bi pé kò le è mú u padà wá sí ẹnu rẹ̀.
16 Ọ̀lẹ gbọ́n ní ojú ara rẹ̀,
ju ènìyàn méje tí wọ́n le è fún un ní ìdáhùn ọlọ́gbọ́n.
17 Bí ènìyàn tí ó di ajá ní etí mú
ni ẹni tí ń kọjá lọ tí ó dá sí ọ̀rọ̀ ìjà tí kì í ṣe tirẹ̀.
18 Bí i asínwín ti ń ju
ọfà àti ọfà tí ń ṣe kú pa ni
19 ni ènìyàn tí ń tan aládùúgbò rẹ̀ jẹ
tí ó sì wí pé, “Àwàdà lásán ni mo ń ṣe.”
20 Láìsí igi, iná yóò kú
láìsí ọ̀rọ̀ ẹ̀yìn, ìjà máa ń parí.
21 Bí èédú ti rí sí ẹyin iná, igi fún iná,
bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn oníjà fún ìjà dídá sílẹ̀.
22 Ọ̀rọ̀ ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀yìn dàbí àṣàyàn òkèlè
wọ́n a sì wọ ìsàlẹ̀ inú lọ.
23 Ètè jíjóni, àti àyà búburú,
dà bí ìdàrọ́ fàdákà tí a fi bo ìkòkò.
24 Ènìyàn tí ó kórìíra máa ń fi ètè rẹ̀ bo àṣírí ara rẹ̀
ṣùgbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ ni ìtànjẹ wà.
25 Bí ọ̀rọ̀ rẹ̀ tilẹ̀ fanimọ́ra, má ṣe gbà á gbọ́
nítorí ìríra méje ni ó kún inú ọkàn rẹ̀.
26 Ìkórìíra rẹ le è fi ara sin nípa ẹ̀tàn
ṣùgbọ́n àṣírí ìwà búburú rẹ̀ yóò tú ní gbangba.
27 Bí ènìyàn kan bá gbẹ́ kòtò, yóò ṣubú sínú rẹ̀.
Bí ẹnìkan bá ju òkúta, yóò padà sọ́dọ̀ òun tìkára rẹ̀.
28 Ahọ́n ẹ̀tàn máa ń kórìíra àwọn tí ó ṣe ní ìkà,
ẹnu ìtànjẹ sì máa ń pa ni run.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.