Add parallel Print Page Options

Ọlọ́run ṣe ìpinnu láti bùkún Jerusalẹmu

Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun si tún tọ́ mí wá.

Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Owú ńláńlá ni mo jẹ fún Sioni, pẹ̀lú ìbínú ńláńlá ni mo fi jowú fún un.”

Báyìí ni Olúwa wí: “Mo yípadà sí Sioni èmi ó sì gbé àárín Jerusalẹmu: Nígbà náà ni a ó sì pé Jerusalẹmu ni ìlú ńlá òtítọ́; àti òkè ńlá Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ni a ó pè ní òkè ńlá mímọ́.”

Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Arúgbó ọkùnrin, àti arúgbó obìnrin, yóò gbé ìgboro Jerusalẹmu, àti olúkúlùkù pẹ̀lú ọ̀pá ni ọwọ́ rẹ̀ fún ogbó. Ìgboro ìlú yóò sì kún fún ọmọdékùnrin, àti ọmọdébìnrin, tí ń ṣiré ní ìta wọn.”

Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Bí ó bá ṣe ìyanu ní ojú ìyókù àwọn ènìyàn yìí ni ọjọ́ wọ̀nyí, ǹjẹ́ ó ha lè jẹ́ ìyanu ni ojú mi bí?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Kíyèsi i, èmi ó gba àwọn ènìyàn mi kúrò ni ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti kúrò ni ilẹ̀ ìwọ̀-oòrùn. Èmi ó sì mú wọn padà wá, wọn ó sì máa gbé àárín Jerusalẹmu. Wọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi, èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, ní òtítọ́, àti ní òdodo.”

Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Jẹ́ kí ọwọ́ yín le ẹ̀yin ti ń gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní ọjọ́ wọ̀nyí ni ẹnu àwọn wòlíì tí ó wà ni ọjọ́ tí a fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun lélẹ̀, jẹ́ ki ọwọ́ rẹ̀ le kí a bá lè kọ́ tẹmpili. 10 Nítorí pé, ṣáájú ọjọ́ wọ̀nyí, owó ọ̀yà ènìyàn kò tó nǹkan, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀yà ẹran pẹ̀lú, bẹ́ẹ̀ ni kò sí àlàáfíà fún ẹni ń jáde lọ, tàbí ẹni ti ń wọlé bọ, nítorí ìpọ́njú náà: nítorí mo dojú gbogbo ènìyàn, olúkúlùkù kọ aládùúgbò rẹ̀. 11 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí èmi kì yóò ṣè sí ìyókù àwọn ènìyàn yìí gẹ́gẹ́ bí tí ìgbà àtijọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

12 “Nítorí irúgbìn yóò gbilẹ̀: àjàrà yóò ṣo èso rẹ̀, ilẹ̀ yóò sì hu ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan rẹ̀ jáde, àwọn ọ̀run yóò sì mu ìrì wọn wá; èmi ó sì mu kí èyí jẹ ogún ìní àwọn ìyókù ènìyàn yìí ni gbogbo nǹkan wọ̀nyí. 13 Yóò sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí jẹ́ ègún láàrín àwọn kèfèrí, ẹ̀yin ilé Juda, àti ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó gbà yín sílẹ̀; ẹ̀yin o sì jẹ́ ìbùkún: ẹ má bẹ̀rù, ṣùgbọ́n jẹ́ ki ọwọ́ yín le.”

14 Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Gẹ́gẹ́ bí mo ti rò láti ṣe yín níbi nígbà tí àwọn baba yín mú mi bínú,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, tí èmi kò sì ronúpìwàdà. 15 “Bẹ́ẹ̀ ni èmi sì ti ro ọjọ́ wọ̀nyí láti ṣe rere fún Jerusalẹmu, àti fún ilé Juda: ẹ má bẹ̀rù. 16 (A)Wọ̀nyí ni nǹkan tí ẹ̀yin ó ṣe: ki olúkúlùkù yín kí ó máa ba ọmọnìkejì rẹ̀ sọ òtítọ́; ṣe ìdájọ́ tòótọ́ àti àlàáfíà ní àwọn ibodè yín. 17 Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ro ibi ni ọkàn rẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀; ẹ má fẹ́ ìbúra èké; nítorí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni mo kórìíra,” ni Olúwa wí.

18 Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun sì tọ mi wá wí pé.

19 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwẹ̀ oṣù kẹrin, karùn-ún, keje, àti tí ẹ̀kẹwàá, yóò jẹ́ ayọ̀ àti dídùn inú, àti àpéjọ àríyá fún ilé Juda; nítorí náà, ẹ fẹ́ òtítọ́ àti àlàáfíà.”

20 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwọn ènìyàn yóò sá à tún wa, àti ẹni tí yóò gbe ìlú ńlá púpọ̀. 21 Àwọn ẹni tí ń gbé ìlú ńlá kan yóò lọ sí òmíràn, wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a yára lọ gbàdúrà kí a sì wá ojúrere Olúwa, àti láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi pẹ̀lú yóò sì lọ.’ 22 Nítòótọ́, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn àti àwọn alágbára orílẹ̀-èdè yóò wá láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní Jerusalẹmu; àti láti gbàdúrà, àti láti wá ojúrere Olúwa.”

23 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí ni ọkùnrin mẹ́wàá láti inú gbogbo èdè àti orílẹ̀-èdè yóò dìímú, àní yóò di etí aṣọ ẹni tí i ṣe Júù mú, wí pé, ‘Àwa yóò ba ọ lọ, nítorí àwa tí gbọ́ pé, Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.’ ”

The Lord Promises to Bless Jerusalem

The word of the Lord Almighty came to me.

This is what the Lord Almighty says: “I am very jealous(A) for Zion; I am burning with jealousy for her.”

This is what the Lord says: “I will return(B) to Zion(C) and dwell in Jerusalem.(D) Then Jerusalem will be called the Faithful City,(E) and the mountain(F) of the Lord Almighty will be called the Holy Mountain.(G)

This is what the Lord Almighty says: “Once again men and women of ripe old age will sit in the streets of Jerusalem,(H) each of them with cane in hand because of their age. The city streets will be filled with boys and girls playing there.(I)

This is what the Lord Almighty says: “It may seem marvelous to the remnant of this people at that time,(J) but will it seem marvelous to me?(K)” declares the Lord Almighty.

This is what the Lord Almighty says: “I will save my people from the countries of the east and the west.(L) I will bring them back(M) to live(N) in Jerusalem; they will be my people,(O) and I will be faithful and righteous to them as their God.(P)

This is what the Lord Almighty says: “Now hear these words, ‘Let your hands be strong(Q) so that the temple may be built.’ This is also what the prophets(R) said who were present when the foundation(S) was laid for the house of the Lord Almighty. 10 Before that time there were no wages(T) for people or hire for animals. No one could go about their business safely(U) because of their enemies, since I had turned everyone against their neighbor. 11 But now I will not deal with the remnant of this people as I did in the past,”(V) declares the Lord Almighty.

12 “The seed will grow well, the vine will yield its fruit,(W) the ground will produce its crops,(X) and the heavens will drop their dew.(Y) I will give all these things as an inheritance(Z) to the remnant of this people.(AA) 13 Just as you, Judah and Israel, have been a curse[a](AB) among the nations, so I will save(AC) you, and you will be a blessing.[b](AD) Do not be afraid,(AE) but let your hands be strong.(AF)

14 This is what the Lord Almighty says: “Just as I had determined to bring disaster(AG) on you and showed no pity when your ancestors angered me,” says the Lord Almighty, 15 “so now I have determined to do good(AH) again to Jerusalem and Judah.(AI) Do not be afraid. 16 These are the things you are to do: Speak the truth(AJ) to each other, and render true and sound judgment(AK) in your courts;(AL) 17 do not plot evil(AM) against each other, and do not love to swear falsely.(AN) I hate all this,” declares the Lord.

18 The word of the Lord Almighty came to me.

19 This is what the Lord Almighty says: “The fasts of the fourth,(AO) fifth,(AP) seventh(AQ) and tenth(AR) months will become joyful(AS) and glad occasions and happy festivals for Judah. Therefore love truth(AT) and peace.”

20 This is what the Lord Almighty says: “Many peoples and the inhabitants of many cities will yet come, 21 and the inhabitants of one city will go to another and say, ‘Let us go at once to entreat(AU) the Lord and seek(AV) the Lord Almighty. I myself am going.’ 22 And many peoples and powerful nations will come to Jerusalem to seek the Lord Almighty and to entreat him.”(AW)

23 This is what the Lord Almighty says: “In those days ten people from all languages and nations will take firm hold of one Jew by the hem of his robe and say, ‘Let us go with you, because we have heard that God is with you.’”(AX)

Footnotes

  1. Zechariah 8:13 That is, your name has been used in cursing (see Jer. 29:22); or, you have been regarded as under a curse.
  2. Zechariah 8:13 Or and your name will be used in blessings (see Gen. 48:20); or and you will be seen as blessed