Add parallel Print Page Options

Olúwa yóò gba Juda

10 Ẹ béèrè òjò nígbà àrọ̀kúrò ni ọwọ́ Olúwa;
    Olúwa tí o dá mọ̀nàmọ́ná,
tí ó sì fi ọ̀pọ̀ òjò fún ènìyàn,
    fún olúkúlùkù koríko ní pápá.
Nítorí àwọn òrìṣà tí sọ̀rọ̀ asán,
    àwọn aláfọ̀ṣẹ sì tí rí èké,
wọn sì tí rọ àlá èké;
    wọ́n ń tu ni nínú lásán,
nítorí náà àwọn ènìyàn náà ṣáko lọ bí àgùntàn,
    a ṣẹ wọn níṣẹ̀ẹ́, nítorí Olùṣọ́-àgùntàn kò sí.

“Ìbínú mi ru sí àwọn darandaran,
    èmi o sì jẹ àwọn olórí ní yà
nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti bẹ agbo rẹ̀,
    ilé Juda wò,
    yóò sì fi wọn ṣe ẹṣin rẹ̀ dáradára ní ogun.
Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni òkúta igun ilé ti jáde wá,
    láti ọ̀dọ̀ rẹ ni èèkàn àgọ́ tí wá,
    láti ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrún ogun tí wá,
    láti ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn akóniṣiṣẹ́ gbogbo tí wá.
Gbogbo wọn yóò sì dàbí ọkùnrin
    alágbára ni ogun tí ń tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro, wọn ó sì jagun,
nítorí Olúwa wà pẹ̀lú wọn,
    wọn ó sì dààmú àwọn tí ń gun ẹṣin.

“Èmi o sì mú ilé Juda ní agbára,
    èmi o sì gba ilé Josẹfu là,
èmi ó sì tún mú wọn padà
    nítorí mo tí ṣàánú fún wọn,
ó sì dàbí ẹni pé èmi kò ì tì í ta wọ́n nù;
    nítorí èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn,
èmi o sì gbọ́ tiwọn
Efraimu yóò sì ṣe bí alágbára,
ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bi ẹni pé nípa ọtí wáìnì:
àní àwọn ọmọ wọn yóò rí í,
    wọn o sì yọ̀, inú wọn ó sì dùn nínú Olúwa.
Èmi ó kọ sí wọn, èmi ó sì ṣà wọ́n jọ;
    nítorí èmi tí rà wọ́n padà;
wọn ó sì pọ̀ sí i gẹ́gẹ́ bí
    wọ́n tí ń pọ̀ sí í rí.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo tú wọn káàkiri orílẹ̀-èdè:
    síbẹ̀ wọn ó sì rántí mi ni ilẹ̀ jíjìn;
wọn ó sì gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn,
    wọn ó sì tún padà.
10 Èmi ó sì tún mú wọn padà kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti
    pẹ̀lú, èmi ó sì ṣà wọn jọ kúrò ni ilẹ̀ Asiria:
èmi ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ Gileadi àti Lebanoni; a
    a kì yóò sì rí ààyè fún wọn bí ó ti yẹ.
11 Wọn yóò sì la Òkun wàhálà já,
    yóò sì bori rírú omi nínú Òkun,
gbogbo ibú odò ni yóò sì gbẹ,
    a ó sì rẹ ìgbéraga Asiria sílẹ̀,
    ọ̀pá aládé Ejibiti yóò sí lọ kúrò.
12 Èmi ó sì mú wọn ní agbára nínú Olúwa;
    wọn ó sì rìn sókè rìn sódò ni orúkọ rẹ̀,”
    ni Olúwa wí.

The Lord Will Care for Judah

10 Ask the Lord for rain in the springtime;
    it is the Lord who sends the thunderstorms.
He gives showers of rain(A) to all people,
    and plants of the field(B) to everyone.
The idols(C) speak deceitfully,
    diviners(D) see visions that lie;
they tell dreams(E) that are false,
    they give comfort in vain.(F)
Therefore the people wander like sheep
    oppressed for lack of a shepherd.(G)

“My anger burns against the shepherds,
    and I will punish the leaders;(H)
for the Lord Almighty will care
    for his flock, the people of Judah,
    and make them like a proud horse in battle.(I)
From Judah will come the cornerstone,(J)
    from him the tent peg,(K)
from him the battle bow,(L)
    from him every ruler.
Together they[a] will be like warriors in battle
    trampling their enemy into the mud of the streets.(M)
They will fight because the Lord is with them,
    and they will put the enemy horsemen to shame.(N)

“I will strengthen(O) Judah
    and save the tribes of Joseph.
I will restore them
    because I have compassion(P) on them.(Q)
They will be as though
    I had not rejected them,
for I am the Lord their God
    and I will answer(R) them.
The Ephraimites will become like warriors,
    and their hearts will be glad as with wine.(S)
Their children will see it and be joyful;
    their hearts will rejoice(T) in the Lord.
I will signal(U) for them
    and gather them in.
Surely I will redeem them;
    they will be as numerous(V) as before.
Though I scatter them among the peoples,
    yet in distant lands they will remember me.(W)
They and their children will survive,
    and they will return.
10 I will bring them back from Egypt
    and gather them from Assyria.(X)
I will bring them to Gilead(Y) and Lebanon,
    and there will not be room(Z) enough for them.
11 They will pass through the sea of trouble;
    the surging sea will be subdued
    and all the depths of the Nile will dry up.(AA)
Assyria’s pride(AB) will be brought down
    and Egypt’s scepter(AC) will pass away.(AD)
12 I will strengthen(AE) them in the Lord
    and in his name they will live securely,(AF)
declares the Lord.

Footnotes

  1. Zechariah 10:5 Or ruler, all of them together. / They