Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Ti Dafidi ìránṣẹ́ Olúwa tí ó kọ sí Olúwa, ọ̀rọ̀ orin tí ó kọ sí Olúwa fún ìdáǹdè kúrò lọ́wọ́ Saulu ọ̀tá rẹ̀. Ó wí pé

18 (A)Mo fẹ́ ọ, Olúwa, agbára mi.

Olúwa ni àpáta àti odi mi, àti olùgbàlà mi;
    Ọlọ́run mi ni àpáta mi, ẹni tí mo fi ṣe ibi ìsádi mi.
    Òun ni àpáta ààbò àti ìwo ìgbàlà mi àti ibi ìsádi mi.

Mo ké pe Olúwa, ẹni tí ìyìn yẹ fún,
    a ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi.
Ìrora ikú yí mi kà,
    àti ìṣàn omi àwọn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
Okùn isà òkú yí mi ká,
    ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí.

Nínú ìpọ́njú mo ké pe Olúwa;
    Mo sọkún sí Olúwa mi fún ìrànlọ́wọ́.
Láti inú tẹmpili rẹ̀, ó gbọ́ igbe mi;
    ẹkún mi wá sí iwájú rẹ̀, sí inú etí rẹ̀.
Ayé wárìrì, ó sì mì tìtì,
    ìpìlẹ̀ àwọn òkè gíga sì ṣídìí;
    wọ́n wárìrì nítorí tí ó ń bínú.
Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá;
    Iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá,
    ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
Ó pín àwọn ọ̀run, Ó sì jáde wá;
    àwọsánmọ̀ dúdú sì wà ní abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
10 Ó gun orí kérúbù, ó sì fò;
    ó ń rábàbà lórí ìyẹ́ apá afẹ́fẹ́.
11 Ó fi òkùnkùn ṣe ibojì rẹ̀, ó fi ṣe ìbòrí yí ara rẹ̀ ká
    kurukuru òjò dúdú ní ojú ọ̀run.
12 Nípa ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀, àwọsánmọ̀ ṣíṣú dudu rẹ kọjá lọ
    pẹ̀lú yìnyín àti ẹ̀yín iná
13 Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá;
    Ọ̀gá-ògo sì fọ ohun rẹ̀; yìnyín àti ẹ̀yin iná.
14 Ó ta àwọn ọfà rẹ̀, ó sì tú àwọn ọ̀tá náà ká,
    ọfà mọ̀nàmọ́ná ńlá sì dà wọ́n rú.
15 A sì fi ìsàlẹ̀ àwọn Òkun hàn,
    a sì rí àwọn ìpìlẹ̀ ayé
nípa ìbáwí rẹ, Olúwa,
    nípa fífún èémí ihò imú rẹ.

16 Ó sọ̀kalẹ̀ láti ibi gíga, ó sì dì mímú;
    Ó fà mí jáde láti inú omi jíjìn.
17 Ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára,
    láti ọwọ́ àwọn ọ̀tá, ti ó lágbára jù fún mi.
18 Wọ́n dojúkọ mí ní ọjọ́ ìpọ́njú mi;
    ṣùgbọ́n Olúwa ni alátìlẹ́yìn mi.
19 Ó mú mi jáde wá sínú ibi ńlá;
    Ó gbà mí nítorí tí ó ní inú dídùn sí mi.

20 Olúwa ti hùwà sí mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;
    gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi, ó ti fi èrè fún mi
21 Nítorí mo ti pa ọ̀nà Olúwa mọ́;
    èmi kò ṣe búburú nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi
22 Gbogbo òfin rẹ̀ ni ó wà níwájú mi;
    èmi kò sì yípadà kúrò nínú ìlànà rẹ̀.
23 Mo ti jẹ́ aláìlẹ́bi níwájú rẹ̀;
    mo sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.
24 Olúwa san ẹ̀san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;
    gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi níwájú rẹ̀.

25 Fún olóòtítọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní olóòtítọ́,
    sí aláìlẹ́bi, ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní aláìlẹ́bi,
26 Sí ọlọ́kàn mímọ́, ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní ọlọ́kàn mímọ́,
    ṣùgbọ́n sí ọlọ́kàn-wíwọ́, ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní òǹrorò.
27 O pa onírẹ̀lẹ̀ mọ́,
    ṣùgbọ́n ó rẹ àwọn ti ń gbéraga sílẹ̀.
28 Ìwọ, Olúwa, jẹ́ kí fìtílà mi
    kí ó máa tàn; Ọlọ́run mi, yí òkùnkùn mi padà sí ìmọ́lẹ̀.
29 Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ rẹ̀, èmi sáré tọ ogun lọ;
    pẹ̀lú Ọlọ́run mi mo lè fo odi kan.

30 Bí ó ṣe ti Ọlọ́run mi, ọ̀nà rẹ̀ pé,
    a ti rídìí ọ̀rọ̀ Olúwa
    òun ni àpáta ààbò fún gbogbo àwọn tí ó fi ṣe ààbò.
31 Nítorí ta ni ṣe Ọlọ́run bí kò ṣe Olúwa?
    Ta ní àpáta bí kò ṣe Olúwa wa?
32 Ọlọ́run ni ẹni tí ó fi agbára dì mí ní àmùrè
    ó sì mú ọ̀nà mi pé.
33 Ó ṣe ẹsẹ̀ mi gẹ́gẹ́ bi ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín;
    ó jẹ́ ki n lè dúró lórí ibi gíga.
34 Ó kọ́ ọwọ́ mi ni ogun jíjà;
    apá mi lè tẹ ọrùn idẹ
35 Ìwọ fi asà ìṣẹ́gun rẹ̀ fún mi,
    ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ gbé mí dúró;
    àti ìwà pẹ̀lẹ́ rẹ̀ sọ mí di ńlá.
36 Ìwọ sọ ìrìn ẹsẹ̀ mi di ńlá ní ìsàlẹ̀ mi,
    kí kókó-ẹsẹ̀ mi má ṣe yẹ̀.

37 Èmi lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì bá wọn
    èmi kò sì padà lẹ́yìn wọn títí a fi run wọ́n.
38 Èmi sá wọn ní ọgbẹ́ tí wọn ko fi le è dìde;
    Wọ́n ṣubú ní abẹ́ ẹsẹ̀ mi.
39 Nítorí ìwọ fi agbára dì mí ní àmùrè fún ogun náà;
    ìwọ ti mú àwọn tí ó dìde si mí tẹríba ní abẹ́ ẹsẹ̀ mi
40 Ìwọ yí ẹ̀yìn àwọn ọ̀tá mí padà sí mi
    èmi sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
41 Wọ́n kígbe fún ìrànlọ́wọ́, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbà wọ́n,
    àní sí Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá wọn lóhùn.
42 Mo lù wọ́n gẹ́gẹ́ bí eruku níwájú afẹ́fẹ́;
    mo dà wọ́n síta gẹ́gẹ́ bí ẹrọ̀fọ̀.
43 Ìwọ ti gbà mí lọ́wọ́ ìkọlù àwọn ènìyàn;
    Ìwọ ti fi mí ṣe olórí àwọn orílẹ̀-èdè.
Àwọn ènìyàn ti èmi kò mọ, yóò sì máa sìn mí,
44     ni wéré ti wọ́n gbọ́ ohùn mi, wọ́n pa àṣẹ mi mọ́;
    àwọn ọmọ àjèjì yóò tẹríba fún mi.
45 Àyà yóò pá àlejò;
    wọn yóò sì fi ìbẹ̀rù jáde láti ibi kọ́lọ́fín wọn.

46 Olúwa wà láààyè! Olùbùkún ni àpáta mi!
    Gbígbéga ní Ọlọ́run Olùgbàlà mi.
47 Òun ni Ọlọ́run tí ó ń gbẹ̀san mi,
    tí ó sì ń ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà ní abẹ́ mi,
48     tí ó pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mí.
Ìwọ gbé mi ga ju àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí mi lọ;
    lọ́wọ́ àwọn ènìyàn alágbára ni ìwọ ti gbà mí.
49 (B)Títí láéláé, èmi yóò máa yìn ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ Olúwa;
    Èmi yóò sì máa kọ orin ìyìn sí orúkọ rẹ.

50 Ó fún ọba rẹ̀ ni ìṣẹ́gun ńlá;
    ó fi ìkáàánú àìṣẹ̀tàn fún ẹni ààmì òróró rẹ̀,
    fún Dafidi àti ìran rẹ̀ títí láé.

The Lord Is My Rock and My Fortress

To the choirmaster. A Psalm of David, (A)the servant of the Lord, (B)who addressed the words of this (C)song to the Lord on the day when the Lord delivered him from the hand of all his enemies, and from the hand of Saul. He said:

18 I love you, O Lord, my strength.
The Lord is my (D)rock and my (E)fortress and my deliverer,
    my God, my (F)rock, in (G)whom I take refuge,
    my (H)shield, and (I)the horn of my salvation, my (J)stronghold.
I call upon the Lord, who is (K)worthy to be praised,
    and I am saved from my enemies.

(L)The cords of death encompassed me;
    (M)the torrents of destruction assailed me;[a]
(N)the cords of Sheol entangled me;
    the snares of death confronted me.

(O)In my distress I called upon the Lord;
    to my God I cried for help.
From his (P)temple he heard my voice,
    and my cry to him reached his ears.

Then the earth (Q)reeled and rocked;
    the foundations also of the mountains trembled
    and quaked, because he was angry.
Smoke went up from his nostrils,[b]
    and devouring (R)fire from his mouth;
    glowing coals flamed forth from him.
He (S)bowed the heavens and (T)came down;
    (U)thick darkness was under his feet.
10 He rode on a cherub and flew;
    he came swiftly on (V)the wings of the wind.
11 He made darkness his covering, his (W)canopy around him,
    thick clouds (X)dark with water.
12 Out of the brightness before him
    (Y)hailstones and coals of fire broke through his clouds.

13 The Lord also (Z)thundered in the heavens,
    and the Most High uttered his (AA)voice,
    hailstones and coals of fire.
14 And he sent out his (AB)arrows and scattered them;
    he flashed forth lightnings and (AC)routed them.
15 Then (AD)the channels of the sea were seen,
    and the foundations of the world were laid bare
at your (AE)rebuke, O Lord,
    at the blast of (AF)the breath of your nostrils.

16 He (AG)sent from on high, he took me;
    he (AH)drew me out of (AI)many waters.
17 He rescued me from my strong enemy
    and from those who hated me,
    for they were (AJ)too mighty for me.
18 They confronted me in the day of my calamity,
    but the Lord was my support.
19 He brought me out into (AK)a broad place;
    he rescued me, because he (AL)delighted in me.

20 The Lord dealt with me (AM)according to my righteousness;
    according to (AN)the cleanness of my hands he rewarded me.
21 For I have (AO)kept the ways of the Lord,
    and have not wickedly departed from my God.
22 For (AP)all his rules[c] were before me,
    and his statutes I did not put away from me.
23 I was (AQ)blameless before him,
    and I kept myself from my guilt.
24 So the Lord has rewarded me according to my righteousness,
    according to the cleanness of my hands in his sight.

25 With (AR)the merciful you show yourself merciful;
    with the blameless man you show yourself blameless;
26 with the purified you show yourself pure;
    and with (AS)the crooked you make yourself seem tortuous.
27 For you save (AT)a humble people,
    but (AU)the haughty eyes you bring down.
28 For it is you who light my (AV)lamp;
    the Lord my God lightens my darkness.
29 For by you I can run against a troop,
    and by my God I can (AW)leap over (AX)a wall.
30 This God—his way is (AY)perfect;[d]
    the word of the Lord (AZ)proves true;
    he is (BA)a shield for all those who (BB)take refuge in him.

31 For (BC)who is God, but the Lord?
    And who is (BD)a rock, except our God?—
32 the God who (BE)equipped me with strength
    and made my way (BF)blameless.
33 He made my feet like the feet of a (BG)deer
    and set me secure on (BH)the heights.
34 He (BI)trains my hands for war,
    so that my arms can bend a bow of bronze.
35 You have given me the shield of your salvation,
    and your right hand (BJ)supported me,
    and your (BK)gentleness made me great.
36 You (BL)gave a wide place for my steps under me,
    and my feet did not slip.
37 I pursued my enemies and overtook them,
    and did not turn back till they were consumed.
38 I thrust them through, so that they were not able to rise;
    they fell under my feet.
39 For you equipped me with strength for the battle;
    you made those who rise against me sink under me.
40 You made my enemies (BM)turn their backs to me,[e]
    and those who hated me I destroyed.
41 (BN)They cried for help, but there was none to save;
    they cried to the Lord, but he did not answer them.
42 I beat them fine as (BO)dust before the wind;
    I cast them out like (BP)the mire of the streets.

43 You delivered me from (BQ)strife with the people;
    you made me (BR)the head of the nations;
    (BS)people whom I had not known served me.
44 As soon as they heard of me they obeyed me;
    (BT)foreigners (BU)came cringing to me.
45 (BV)Foreigners lost heart
    and (BW)came trembling out of their fortresses.

46 The Lord lives, and blessed be my rock,
    and exalted be the God of my salvation—
47 the God who gave me vengeance
    and (BX)subdued peoples under me,
48 who rescued me from my enemies;
    yes, you (BY)exalted me above those who rose against me;
    you delivered me from (BZ)the man of violence.

49 (CA)For this I will praise you, O Lord, among the nations,
    and (CB)sing to your name.
50 Great (CC)salvation he brings to his king,
    and shows steadfast love to his (CD)anointed,
    to (CE)David and his offspring forever.

Footnotes

  1. Psalm 18:4 Or terrified me
  2. Psalm 18:8 Or in his wrath
  3. Psalm 18:22 Or just decrees
  4. Psalm 18:30 Or blameless
  5. Psalm 18:40 Or You gave me my enemies' necks