Saamu 92
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Saamu. Orin. Fún ọjọ́ Ìsinmi
92 Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa
àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
2 Láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀
àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́
3 Lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá
àti lára ohun èlò orin haapu.
4 Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn
nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa;
èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
5 Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa?
Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
6 Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n,
aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
7 Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú
bá rú jáde bí i koríko
àti gbogbo àwọn olùṣe
búburú gbèrú,
wọn yóò run láéláé.
8 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
9 Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ,
Olúwa,
nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé;
gbogbo àwọn olùṣe búburú
ni a ó fọ́nká.
10 Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó;
òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
11 Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi;
ìparun sí àwọn ènìyàn búburú
tí ó dìde sí mi.
12 Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ,
wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni;
13 Tí a gbìn sí ilé Olúwa,
Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
14 Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó,
wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
15 Láti fihàn pé “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa;
òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú
kankan nínú rẹ̀.”
Psalm 92
New International Version
Psalm 92[a]
A psalm. A song. For the Sabbath day.
1 It is good to praise the Lord
and make music(A) to your name,(B) O Most High,(C)
2 proclaiming your love in the morning(D)
and your faithfulness at night,
3 to the music of the ten-stringed lyre(E)
and the melody of the harp.(F)
4 For you make me glad by your deeds, Lord;
I sing for joy(G) at what your hands have done.(H)
5 How great are your works,(I) Lord,
how profound your thoughts!(J)
6 Senseless people(K) do not know,
fools do not understand,
7 that though the wicked spring up like grass
and all evildoers flourish,
they will be destroyed forever.(L)
8 But you, Lord, are forever exalted.
9 For surely your enemies(M), Lord,
surely your enemies will perish;
all evildoers will be scattered.(N)
10 You have exalted my horn[b](O) like that of a wild ox;(P)
fine oils(Q) have been poured on me.
11 My eyes have seen the defeat of my adversaries;
my ears have heard the rout of my wicked foes.(R)
12 The righteous will flourish(S) like a palm tree,
they will grow like a cedar of Lebanon;(T)
13 planted in the house of the Lord,
they will flourish in the courts of our God.(U)
14 They will still bear fruit(V) in old age,
they will stay fresh and green,
15 proclaiming, “The Lord is upright;
he is my Rock, and there is no wickedness in him.(W)”
Footnotes
- Psalm 92:1 In Hebrew texts 92:1-15 is numbered 92:2-16.
- Psalm 92:10 Horn here symbolizes strength.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.