Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Tí ohùn orin “àgbọ̀nrín òwúrọ̀.” Saamu ti Dafidi.

22 (A)Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀?
    Èéṣe tí o fi jìnnà láti gbà mí là,
    àní sí igbe ìkérora mi?
Ọlọ́run mi, ní ọ̀sán gangan ni mo kígbe, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi ní ohùn:
    àti ní òru èmi kò dákẹ́.

Ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹni mímọ́ ni ìwọ;
    ẹni tí ó tẹ ìyìn Israẹli dó;
Àwọn baba ńlá wa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ;
    wọ́n ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ìwọ sì gbà wọ́n.
Ìwọ ni wọ́n sun ẹkún sí, wọ́n sì ní ìgbàlà;
    ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, a kò sì dójútì wọ́n.

Ṣùgbọ́n kòkòrò ní mo jẹ́, kì í sì í ṣe ènìyàn;
    mo di ẹlẹ́gàn àwọn ènìyàn, ẹlẹ́yà àwọn ènìyàn
Gbogbo àwọn tí ó rí mí fi mí ṣe ẹlẹ́yà;
    wọ́n yọ ètè ẹ̀gàn wọn sí mi, wọ́n sì ń mi orí wọn pé.
“Ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé Olúwa;
    jẹ́ kí Olúwa gbà á là.
Jẹ́ kí ó gbà á là,
    nítorí pé, ó ní ayọ̀ nínú rẹ̀.”

Síbẹ̀ ìwọ ni ó ti mú mi wá láti inú;
    ìwọ ni ó mú mi wà láìléwu, nígbà tí mo rọ̀ mọ́ ọmú ìyá mi.
10 Ìwọ ni a fi mí lé lọ́wọ́ láti inú ìyá mi wá,
    nígbà tí ìyá mí sì ti bí mi, ìwọ ni Ọlọ́run mi.

11 Má ṣe jìnnà sí mi,
    nítorí pé ìyọnu súnmọ́ tòsí
    kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò ṣe ìrànlọ́wọ́.

12 Ọ̀pọ̀ akọ màlúù yí mi ká;
    àwọn màlúù alágbára Baṣani rọ̀gbà yí mi ká.
13 Wọ́n ya ẹnu wọn sì mi bí i kìnnìún tí ń dọdẹ kiri,
    tí ń ké ramúramù.
14 A dà mí jáde gẹ́gẹ́ bí omi,
    gbogbo egungun mi ti yẹ̀ kúrò ní oríkèé rẹ̀.
Ọkàn mi sì dàbí i ìda;
    tí ó yọ́ láàrín inú mi.
15 Agbára mí ti gbẹ bí àpáàdì,
    ahọ́n mí sì tilẹ̀ mọ́ párí ẹ̀rẹ̀kẹ́ ẹ mi;
    ìwọ ti tẹ́ mi sínú eruku ikú.

16 Àwọn ajá yí mi ká;
    ìjọ àwọn ènìyàn ibi ti ká mi mọ́,
    Wọ́n gún mi lọ́wọ́, wọ́n sì gún mi lẹ́sẹ̀
17 Mo lè ka gbogbo àwọn egungun mi;
    àwọn tìkára wọn ń wò, wọ́n dójú lé mi.
18 Wọ́n pín aṣọ mi láàrín ara wọn
    àní lórí aṣọ mi ni wọ́n ṣẹ́ gègé.

19 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, má ṣe jìnnà sí mi;
    Háà! Olùrànlọ́wọ́ ọ̀ mi, yára wá fún àtìlẹ́yìn mi!
20 Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ idà,
    àní ẹ̀mí mi lọ́wọ́ agbára àwọn ajá.
21 Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ kìnnìún;
    Kí o sì gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ìwo àgbáǹréré.

22 Èmi yóò kéde orúkọ rẹ láàrín arákùnrin àti arábìnrin mi;
    nínú ìjọ ni èmi yóò máa yìn ọ́.
23 Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ yìn ín!
    Gbogbo ẹ̀yin ìran Jakọbu, ẹ fi ògo fún un!
    Ẹ dìde fún un tẹ̀rù tẹ̀rù, ẹ̀yin irú-ọmọ Israẹli!
24 Nítorí pé òun kò ṣátá, bẹ́ẹ̀ ni kò sì kórìíra
    ìpọ́njú àwọn tí a ni lára;
kò sì fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún mi
    ṣùgbọ́n ó gbọ́ nígbà tí mo ké pè é.

25 Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìyìn mi yóò ti wá nínú àjọ ńlá;
    ẹ̀jẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò san níwájú àwọn tí o bẹ̀rù rẹ̀
26 tálákà yóò jẹ yóò sì yó;
    àwọn tí n wá Olúwa yóò yin
    jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ̀ wà láààyè títí ayérayé!

27 Gbogbo òpin ayé ni yóò rántí
    wọn yóò sì yípadà sí Olúwa,
àti gbogbo ìdílé orílẹ̀-èdè
    ni wọn yóò jọ́sìn níwájú rẹ̀,
28 Nítorí ìjọba ni ti Olúwa.
    Òun ni ó ń pàṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè.

29 Bẹ́ẹ̀ náà ni gbogbo àwọn olówó ayé wọn yóò ṣe àsè, wọn yóò sì sìn;
    gbogbo àwọn tí ó wọ inú ilẹ̀ lọ yóò kúnlẹ̀ ní iwájú rẹ̀
    àti ẹni tí kò lè pa ọkàn ara rẹ̀ mọ́ ni ààyè.
30 Irú-ọmọ rẹ̀ yóò sìn ín;
    a ó sọ fún àwọn ìran tí ń bọ̀ nípa Olúwa,
31 Wọn yóò polongo òdodo rẹ̀
    sí àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí,
    wí pé, òun ni ó ṣe èyí.

Psalm 22[a]

For the director of music. To the tune of “The Doe of the Morning.” A psalm of David.

My God, my God, why have you forsaken me?(A)
    Why are you so far(B) from saving me,
    so far from my cries of anguish?(C)
My God, I cry out by day, but you do not answer,(D)
    by night,(E) but I find no rest.[b]

Yet you are enthroned as the Holy One;(F)
    you are the one Israel praises.[c](G)
In you our ancestors put their trust;
    they trusted and you delivered them.(H)
To you they cried out(I) and were saved;
    in you they trusted(J) and were not put to shame.(K)

But I am a worm(L) and not a man,
    scorned by everyone,(M) despised(N) by the people.
All who see me mock me;(O)
    they hurl insults,(P) shaking their heads.(Q)
“He trusts in the Lord,” they say,
    “let the Lord rescue him.(R)
Let him deliver him,(S)
    since he delights(T) in him.”

Yet you brought me out of the womb;(U)
    you made me trust(V) in you, even at my mother’s breast.
10 From birth(W) I was cast on you;
    from my mother’s womb you have been my God.

11 Do not be far from me,(X)
    for trouble is near(Y)
    and there is no one to help.(Z)

12 Many bulls(AA) surround me;(AB)
    strong bulls of Bashan(AC) encircle me.
13 Roaring lions(AD) that tear their prey(AE)
    open their mouths wide(AF) against me.
14 I am poured out like water,
    and all my bones are out of joint.(AG)
My heart has turned to wax;(AH)
    it has melted(AI) within me.
15 My mouth[d] is dried up like a potsherd,(AJ)
    and my tongue sticks to the roof of my mouth;(AK)
    you lay me in the dust(AL) of death.

16 Dogs(AM) surround me,
    a pack of villains encircles me;
    they pierce[e](AN) my hands and my feet.
17 All my bones are on display;
    people stare(AO) and gloat over me.(AP)
18 They divide my clothes among them
    and cast lots(AQ) for my garment.(AR)

19 But you, Lord, do not be far from me.(AS)
    You are my strength;(AT) come quickly(AU) to help me.(AV)
20 Deliver me from the sword,(AW)
    my precious life(AX) from the power of the dogs.(AY)
21 Rescue me from the mouth of the lions;(AZ)
    save me from the horns of the wild oxen.(BA)

22 I will declare your name to my people;
    in the assembly(BB) I will praise you.(BC)
23 You who fear the Lord, praise him!(BD)
    All you descendants of Jacob, honor him!(BE)
    Revere him,(BF) all you descendants of Israel!
24 For he has not despised(BG) or scorned
    the suffering of the afflicted one;(BH)
he has not hidden his face(BI) from him
    but has listened to his cry for help.(BJ)

25 From you comes the theme of my praise in the great assembly;(BK)
    before those who fear you[f] I will fulfill my vows.(BL)
26 The poor will eat(BM) and be satisfied;
    those who seek the Lord will praise him—(BN)
    may your hearts live forever!

27 All the ends of the earth(BO)
    will remember and turn to the Lord,
and all the families of the nations
    will bow down before him,(BP)
28 for dominion belongs to the Lord(BQ)
    and he rules over the nations.

29 All the rich(BR) of the earth will feast and worship;(BS)
    all who go down to the dust(BT) will kneel before him—
    those who cannot keep themselves alive.(BU)
30 Posterity(BV) will serve him;
    future generations(BW) will be told about the Lord.
31 They will proclaim his righteousness,(BX)
    declaring to a people yet unborn:(BY)
    He has done it!(BZ)

Footnotes

  1. Psalm 22:1 In Hebrew texts 22:1-31 is numbered 22:2-32.
  2. Psalm 22:2 Or night, and am not silent
  3. Psalm 22:3 Or Yet you are holy, / enthroned on the praises of Israel
  4. Psalm 22:15 Probable reading of the original Hebrew text; Masoretic Text strength
  5. Psalm 22:16 Dead Sea Scrolls and some manuscripts of the Masoretic Text, Septuagint and Syriac; most manuscripts of the Masoretic Text me, / like a lion
  6. Psalm 22:25 Hebrew him