Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.

140 Olúwa, gbà mi lọ́wọ́ ọkùnrin búburú u nì,
    yọ mí lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì;
Ẹni tí ń ro ìwà búburú ní inú wọn;
    nígbà gbogbo ni wọ́n ń rú ìjà sókè sí mi.
Wọ́n ti pọ́n ahọ́n wọn bí ejò,
    oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ ní abẹ́ ètè wọn.

Olúwa, pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú;
    yọ mí kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì
    ẹni tí ó ti pinnu rẹ̀ láti bi ìrìn mi ṣubú
Àwọn agbéraga ti dẹkùn sílẹ̀ fún mi àti okùn:
    wọ́n ti na àwọ̀n lẹ́bàá ọ̀nà;
    wọ́n ti kẹ́kùn sílẹ̀ fún mi.

Èmi wí fún Olúwa pé ìwọ ni Ọlọ́run mi;
    Olúwa, gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
Olúwa Olódùmarè, agbára ìgbàlà mi,
    ìwọ ni ó bo orí mi mọ́lẹ̀ ní ọjọ́ ìjà.
Olúwa, máa ṣe fi ìfẹ́ ènìyàn búburú fún un;
    Má ṣe kún ọgbọ́n búburú rẹ̀ lọ́wọ́;
    kí wọn kí ó máa ba à gbé ara wọn ga. Sela.

Bí ó ṣe ti orí àwọn tí ó yí mi káàkiri ni,
    jẹ́ kí ète ìka ara wọn kí ó bò wọ́n mọ́lẹ̀.
10 A ó da ẹ̀yin iná sí wọn lára:
    Òun yóò wọ́ wọn lọ sínú iná,
sínú ọ̀gbun omi jíjìn,
    kí wọn kí ó má ba à le dìde mọ́.
11 Má ṣe jẹ́ kí aláhọ́n búburú fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ayé;
    ibi ni yóò máa dọdẹ ọkùnrin ìkà nì láti bì í ṣubú.

12 Èmi mọ̀ pé, Olúwa yóò mú ọ̀nà olùpọ́njú dúró,
    yóò sì ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tálákà
13 Nítòótọ́ àwọn olódodo yóò
    máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ;
    àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yóò máa gbé iwájú rẹ.

Psalm 140[a]

For the director of music. A psalm of David.

Rescue me,(A) Lord, from evildoers;
    protect me from the violent,(B)
who devise evil plans(C) in their hearts
    and stir up war(D) every day.
They make their tongues as sharp as(E) a serpent’s;
    the poison of vipers(F) is on their lips.[b]

Keep me safe,(G) Lord, from the hands of the wicked;(H)
    protect me from the violent,
    who devise ways to trip my feet.
The arrogant have hidden a snare(I) for me;
    they have spread out the cords of their net(J)
    and have set traps(K) for me along my path.

I say to the Lord, “You are my God.”(L)
    Hear, Lord, my cry for mercy.(M)
Sovereign Lord,(N) my strong deliverer,
    you shield my head in the day of battle.
Do not grant the wicked(O) their desires, Lord;
    do not let their plans succeed.

Those who surround me proudly rear their heads;
    may the mischief of their lips engulf them.(P)
10 May burning coals fall on them;
    may they be thrown into the fire,(Q)
    into miry pits, never to rise.
11 May slanderers not be established in the land;
    may disaster hunt down the violent.(R)

12 I know that the Lord secures justice for the poor(S)
    and upholds the cause(T) of the needy.(U)
13 Surely the righteous will praise your name,(V)
    and the upright will live(W) in your presence.(X)

Footnotes

  1. Psalm 140:1 In Hebrew texts 140:1-13 is numbered 140:2-14.
  2. Psalm 140:3 The Hebrew has Selah (a word of uncertain meaning) here and at the end of verses 5 and 8.