Add parallel Print Page Options

Ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ohun àdídùn

23 Nígbà tí ìwọ bá jókòó láti bá ìjòyè jẹun,
    kíyèsi ohun tí ó wà níwájú rẹ gidigidi.
Ìwọ a sì fi ọ̀bẹ lé ara rẹ ní ọ̀fun,
    bí ìwọ bá jẹ́ òkúndùn ènìyàn.
Má ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀:
    nítorí pé oúnjẹ ẹ̀tàn ni.

Má ṣe ṣe làálàá láti lọ́rọ̀:
    ṣíwọ́ kúrò nínú ọgbọ́n ara rẹ.
Ìwọ ó ha fi ojú rẹ lépa ohun tí kò sí?
    Nítorí tí ọ̀rọ̀ hu ìyẹ́ apá fún ara rẹ̀,
    ó sì ń fò bí idì ní ojú ọ̀run.

Má ṣe jẹ oúnjẹ ẹni tí ó háwọ́,
    bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀.
Nítorí pé bí ẹni tí ń ṣírò ní ọkàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó rí:
    “Máa jẹ, kí o sì máa mu,” ni ó ń wí fún ọ;
    ṣùgbọ́n ọkàn rẹ̀ kò pẹ̀lú rẹ.
Òkèlè tí ìwọ jẹ ni ìwọ ó pọ̀ jáde,
    ìwọ a sì sọ ọ̀rọ̀ dídùn rẹ̀ nù.

Má ṣe sọ̀rọ̀ ní etí aṣiwèrè;
    nítorí tí yóò gan ọgbọ́n ọ̀rọ̀ rẹ.

10 Má ṣe ṣí ààlà àtijọ́ kúrò;
    má sì ṣe bọ́ sínú oko aláìní baba.
11 Nítorí pé Olùràpadà wọn lágbára;
    yóò gba ìjà wọn jà sí ọ.

12 Fi àyà sí ẹ̀kọ́,
    àti etí rẹ sí ọ̀rọ̀-ìmọ̀.

13 Má ṣe fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kúrò lára ọmọdé,
    nítorí pé bí ìwọ bá fi pàṣán nà án, òun kì yóò kú.
14 Bí ìwọ fi pàṣán nà án,
    ìwọ ó sì gbà ọkàn rẹ̀ là kúrò ní ọ̀run àpáàdì.

Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n fún ọmọ rere

15 Ọmọ mi, bí ọkàn rẹ bá gbọ́n,
    ọkàn mi yóò yọ̀, àní èmi pẹ̀lú.
16 Inú mi yóò sì dùn nígbà tí ètè rẹ̀ bá ń sọ̀rọ̀ títọ́.

17 Má ṣe jẹ́ kí àyà rẹ ó ṣe ìlara sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,
    ṣùgbọ́n kí ìwọ ó wà ní ìbẹ̀rù Olúwa,
    ní ọjọ́ gbogbo.
18 Nítorí pé ìgbẹ̀yìn ń bẹ nítòótọ́;
    ìrètí rẹ̀ kì yóò sì gé kúrò.

19 Gbọ́, ìwọ ọmọ mi, kí o sì gbọ́n,
    kí o sì máa tọ́ àyà rẹ sí ọ̀nà títọ́.
20 Má ṣe wà nínú àwọn ọ̀mùtí;
    àti àwọn wọ̀bìà alájẹkì ọ̀jẹun;
21 Nítorí pé ọ̀mùtí àti ọ̀jẹun ni yóò di tálákà;
    ìmúni-tòògbé ní sì ń fi àkísà wọ ọkùnrin láṣọ.

22 Fetí sí ti baba rẹ tí ó bí ọ,
    má sì ṣe gan ìyá rẹ, nígbà tí o bá gbó
23 Ra òtítọ́, kí o má sì ṣe tà á;
    ra ọgbọ́n pẹ̀lú àti ẹ̀kọ́ àti òye.
24 Baba olódodo ni yóò yọ̀ gidigidi:
    ẹni tí ó sì bí ọmọ ọlọ́gbọ́n,
    yóò ní ayọ̀ nínú rẹ̀.
25 Jẹ́ kí baba rẹ àti ìyá rẹ ó yọ̀,
    sì jẹ́ kí inú ẹni tí ó bí ọ dùn.

26 Ọmọ mi, fi àyà rẹ fún mi,
    kí o sì jẹ́ kí ojú rẹ ní inú dídùn sí ọ̀nà mi.
27 Nítorí pé panṣágà obìnrin ọ̀gbun jíjìn ni;
    àti àjèjì obìnrin kànga híhá ni.
28 Òun á sì ba ní bùba bí olè,
    a sì sọ àwọn olùrékọjá di púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn.

29 Ta ni ó ni òsì? Ta ni ó ni ìbànújẹ́?
    Ta ni ó ni ìjà? Ta ni ó ni asọ̀? Ta ni ó ni ọgbẹ́ láìnídìí?
30 Àwọn tí ó dúró pẹ́ níbi ọtí wáìnì;
    àwọn tí ń lọ láti dán ọtí wáìnì àdàlú wò.
31 Ìwọ má ṣe wò ọtí wáìnì nígbà tí ó pọ́n,
    nígbà tí ó bá ń fi àwọ̀ rẹ̀ hàn nínú ago,
    tí a gbé e mì, tí ó ń dùn.
32 Níkẹyìn òun á bu ni ṣán bí ejò,
    a sì bunijẹ bí i paramọ́lẹ̀.
33 Ojú rẹ yóò wò àwọn àjèjì obìnrin,
    àyà rẹ yóò sì sọ̀rọ̀ àyídáyidà.
34 Nítòótọ́, ìwọ ó dàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ ní àárín Òkun,
    tàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ lókè-ọkọ̀.
35 Ìwọ ó sì wí pé, “Wọ́n lù mí; kò dùn mí;
    wọ́n lù mí, èmi kò sì mọ̀:
nígbà wo ni èmi ó jí?
    Èmi ó tún máa wá òmíràn láti mu.”

23 When you sit to eat with a ruler,
    consider diligently what is before you;
put a knife to your throat
    if you are a man given to appetite.
Don’t be desirous of his dainties,
    since they are deceitful food.
Don’t weary yourself to be rich.
    In your wisdom, show restraint.
Why do you set your eyes on that which is not?
    For it certainly sprouts wings like an eagle and flies in the sky.
Don’t eat the food of him who has a stingy eye,
    and don’t crave his delicacies,
    for as he thinks about the cost, so he is.
    “Eat and drink!” he says to you,
    but his heart is not with you.
You will vomit up the morsel which you have eaten
    and waste your pleasant words.

Don’t speak in the ears of a fool,
    for he will despise the wisdom of your words.

10 Don’t move the ancient boundary stone.
    Don’t encroach on the fields of the fatherless,
11 for their Defender is strong.
    He will plead their case against you.

12 Apply your heart to instruction,
    and your ears to the words of knowledge.
13 Don’t withhold correction from a child.
    If you punish him with the rod, he will not die.
14 Punish him with the rod,
    and save his soul from Sheol.[a]

15 My son, if your heart is wise,
    then my heart will be glad, even mine.
16 Yes, my heart will rejoice
    when your lips speak what is right.
17 Don’t let your heart envy sinners,
    but rather fear Yahweh all day long.
18 Indeed surely there is a future hope,
    and your hope will not be cut off.
19 Listen, my son, and be wise,
    and keep your heart on the right path!
20 Don’t be among ones drinking too much wine,
    or those who gorge themselves on meat;
21 for the drunkard and the glutton shall become poor;
    and drowsiness clothes them in rags.
22 Listen to your father who gave you life,
    and don’t despise your mother when she is old.
23 Buy the truth, and don’t sell it.
    Get wisdom, discipline, and understanding.
24 The father of the righteous has great joy.
    Whoever fathers a wise child delights in him.
25 Let your father and your mother be glad!
    Let her who bore you rejoice!
26 My son, give me your heart;
    and let your eyes keep in my ways.
27 For a prostitute is a deep pit;
    and a wayward wife is a narrow well.
28 Yes, she lies in wait like a robber,
    and increases the unfaithful among men.

29 Who has woe?
    Who has sorrow?
    Who has strife?
    Who has complaints?
    Who has needless bruises?
    Who has bloodshot eyes?
30 Those who stay long at the wine;
    those who go to seek out mixed wine.
31 Don’t look at the wine when it is red,
    when it sparkles in the cup,
    when it goes down smoothly.
32 In the end, it bites like a snake,
    and poisons like a viper.
33 Your eyes will see strange things,
    and your mind will imagine confusing things.
34 Yes, you will be as he who lies down in the middle of the sea,
    or as he who lies on top of the rigging:
35 “They hit me, and I was not hurt!
    They beat me, and I don’t feel it!
    When will I wake up? I can do it again.
    I will look for more.”

Footnotes

  1. 23:14 Sheol is the place of the dead.