Oniwaasu 11
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Àkàrà lórí omi
11 Fún àkàrà rẹ sórí omi,
nítorí lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ìwọ yóò rí i padà
2 Fi ìpín fún méje, àní fún mẹ́jọ pẹ̀lú,
nítorí ìwọ kò mọ ohun ìparun tí ó le è wá sórí ilẹ̀.
3 Bí àwọsánmọ̀ bá kún fún omi,
ayé ni wọ́n ń rọ òjò sí
Bí igi wó sí ìhà gúúsù tàbí sí ìhà àríwá
níbi tí ó wó sí náà, ni yóò dùbúlẹ̀ sí.
4 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wo afẹ́fẹ́ kò ní fúnrúgbìn;
ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wo àwọsánmọ̀ kò ní kórè.
5 Gẹ́gẹ́ bí ìwọ kò ti ṣe mọ ojú ọ̀nà afẹ́fẹ́
tàbí mọ bí ọmọ tí ń dàgbà nínú ikùn ìyáarẹ̀,
bẹ́ẹ̀ náà ni ìwọ kò le è ní òye iṣẹ́ Ọlọ́run
ẹlẹ́dàá ohun gbogbo.
6 Fún irúgbìn rẹ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù,
má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣọlẹ̀ ní àṣálẹ́,
nítorí ìwọ kò mọ èyí tí yóò ṣe rere
bóyá èyí tàbí ìyẹn
tàbí àwọn méjèèjì ni yóò ṣe dáradára bákan náà.
Rántí ẹlẹ́dàá rẹ ní ìgbà èwe rẹ
7 Ìmọ́lẹ̀ dùn;
Ó sì dára fún ojú láti rí oòrùn.
8 Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn jẹ̀gbádùn gbogbo iye ọdún
tí ó le è lò láyé
ṣùgbọ́n jẹ́ kí ó rántí ọjọ́ òkùnkùn
nítorí wọn ó pọ̀
Gbogbo ohun tí ó ń bọ̀ asán ni.
9 Jẹ́ kí inú rẹ dùn, ìwọ ọ̀dọ́mọdé ní ìgbà tí o wà ní èwe
kí o sì jẹ́ kí ọkàn rẹ fún ọ ní ayọ̀ ní ìgbà èwe rẹ.
Tẹ̀lé ọ̀nà ọkàn rẹ
àti ohunkóhun tí ojú rẹ rí
ṣùgbọ́n mọ̀ dájú pé nípa gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni
Ọlọ́run yóò mú ọ wá sí ìdájọ́.
10 Nítorí náà, mú ìjayà kúrò ní ọkàn rẹ
kí o sì lé ìbànújẹ́ ara rẹ kúrò
nítorí èwe àti kékeré kò ní ìtumọ̀.
Ecclesiastes 11
English Standard Version
Cast Your Bread upon the Waters
11 (A)Cast your bread upon the waters,
(B)for you will find it after many days.
2 (C)Give a portion to (D)seven, or even to eight,
(E)for you know not what disaster may happen on earth.
3 If the clouds are full of rain,
they empty themselves on the earth,
and if a tree falls to the south or to the north,
in the place where the tree falls, there it will lie.
4 He who observes the wind will not sow,
and he who regards the clouds will not reap.
5 As you do not know the way (F)the spirit comes to (G)the bones in the womb[a] of a woman with child, so you do not know the work of God who makes everything.
6 In the morning sow your seed, and at evening (H)withhold not your hand, for you do not know which will prosper, this or that, or whether both alike will be good.
7 Light is sweet, and it is pleasant for the eyes to (I)see the sun.
8 So if a person lives many years, let him rejoice in them all; but let him remember (J)that the days of darkness will be many. All that comes is (K)vanity.[b]
9 (L)Rejoice, O young man, in your youth, and let your heart cheer you in the days of your youth. (M)Walk in the ways of your heart and (N)the sight of your eyes. But know that for all these things (O)God will bring you into judgment.
10 Remove vexation from your heart, and (P)put away pain[c] from your body, for youth and the dawn of life are vanity.
Footnotes
- Ecclesiastes 11:5 Some Hebrew manuscripts, Targum; most Hebrew manuscripts As you do not know the way of the wind, or how the bones grow in the womb
- Ecclesiastes 11:8 The Hebrew term hebel can refer to a “vapor” or “mere breath”; also verse 10 (see note on 1:2)
- Ecclesiastes 11:10 Or evil
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
The ESV® Bible (The Holy Bible, English Standard Version®), © 2001 by Crossway, a publishing ministry of Good News Publishers. ESV Text Edition: 2025.
