Add parallel Print Page Options

Àkókò àti ìgbà wà fún ohun gbogbo

Àsìkò wà fún ohun gbogbo,
    àti ìgbà fún gbogbo nǹkan ní abẹ́ ọ̀run.

Ìgbà láti bí àti ìgbà kíkú,
    ìgbà láti gbìn àti ìgbà láti fàtu.
Ìgbà láti pa àti ìgbà láti mú láradá
    ìgbà láti wó lulẹ̀ àti ìgbà láti kọ́.
Ìgbà láti sọkún àti ìgbà láti rín ẹ̀rín
    ìgbà láti ṣọ̀fọ̀ àti ìgbà láti jó
Ìgbà láti tú òkúta ká àti ìgbà láti ṣà wọ́n jọ
    ìgbà láti súnmọ́ àti ìgbà láti fàsẹ́yìn
Ìgbà láti wá kiri àti ìgbà láti ṣàì wá kiri
    ìgbà láti pamọ́ àti ìgbà láti jù nù,
Ìgbà láti ya àti ìgbà láti rán
    ìgbà láti dákẹ́ àti ìgbà láti sọ̀rọ̀
Ìgbà láti ní ìfẹ́ àti ìgbà láti kórìíra
ìgbà fún ogun àti ìgbà fún àlàáfíà.

Kí ni òṣìṣẹ́ jẹ ní èrè nínú wàhálà rẹ̀? 10 Mo ti rí àjàgà tí Ọlọ́run gbé lé ọmọ ènìyàn. 11 Ó ti ṣe ohun gbogbo dáradára ní àsìkò tirẹ̀, ó sì ti fi èrò nípa ayérayé sí ọkàn ọmọ ènìyàn, síbẹ̀, wọn kò le ṣe àwárí ìdí ohun tí Ọlọ́run ti ṣe láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin. 12 Mo mọ̀ wí pé kò sí ohun tí ó dára fún ènìyàn ju pé kí inú wọn dùn kí wọn sì ṣe rere níwọ̀n ìgbà tí wọ́n sì wà láààyè. 13 Wí pé: kí olúkúlùkù le è jẹ, kí wọn sì mu, kí wọn sì rí ìtẹ́lọ́rùn nínú gbogbo iṣẹ́ wọn ẹ̀bùn Ọlọ́run ni èyí jẹ́. 14 Mo mọ̀ wí pé ohun gbogbo tí Ọlọ́run ṣe ni yóò wà títí láé, kò sí ohun tí a lè fi kún un tàbí kí a yọ kúrò nínú rẹ̀. Ọlọ́run ṣe èyí kí ènìyàn le è ní ìbẹ̀rù rẹ̀ ni.

15 Ohun tí ó wà ti wà tẹ́lẹ̀,
    ohun tí ó ń bọ̀ wá ti wà tẹ́lẹ̀,
    Ọlọ́run yóò sì mú kí àwọn ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sẹ́yìn tún ṣẹlẹ̀.

16 Mo sì tún rí ohun mìíràn ní

abẹ́ ọ̀run dípò ìdájọ́,
    òdodo ni ó wà níbẹ̀ dípò ètò òtítọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ni o wà níbẹ̀.

17 Mo wí nínú ọkàn mi,

“Ọlọ́run yóò ṣe ìdájọ́
    olódodo àti ènìyàn búburú,
nítorí pé àsìkò yóò wà fún gbogbo iṣẹ́,
    àti àsìkò ṣe ìdájọ́ gbogbo ìṣe.”

18 Mo tún rò pé “Ọlọ́run ń dán wa wò láti fihàn wá wí pé bí ẹranko ni ènìyàn rí. 19 Ó ní láti jẹ́ ohun ìrántí pé ìpín ènìyàn rí bí i tẹranko ìpín kan náà ń dúró dè wọ́n. Bí ọ̀kan ti ń kú náà ni èkejì yóò kú. Àwọn méjèèjì ni irú èémí kan náà, ènìyàn kò sàn ju ẹranko lọ, nítorí pé asán ni yíyè jẹ́ fún wọn. 20 Ibìkan náà ni gbogbo wọn ń lọ, wọ́n wá láti inú erùpẹ̀, inú erùpẹ̀ náà ni wọn yóò tún padà sí. 21 Ta ni ó mọ̀ bóyá ẹ̀mí ènìyàn ń lọ sí òkè tí ẹ̀mí ẹranko sì ń lọ sí ìsàlẹ̀ nínú ilẹ̀ ni?”

22 Nígbà náà, ni mo wá rí i wí pé, kò sí ohun tí ó sàn fún ènìyàn ju kí ó gbádùn iṣẹ́ rẹ̀, nítorí pé ìpín tirẹ̀ ni èyí. Tàbí ta ni ó le è mú kí ó rí ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀ kò sí!

A Time for Everything

There is a time(A) for everything,
    and a season for every activity under the heavens:

    a time to be born and a time to die,
    a time to plant and a time to uproot,(B)
    a time to kill(C) and a time to heal,
    a time to tear down and a time to build,
    a time to weep and a time to laugh,
    a time to mourn and a time to dance,
    a time to scatter stones and a time to gather them,
    a time to embrace and a time to refrain from embracing,
    a time to search and a time to give up,
    a time to keep and a time to throw away,
    a time to tear and a time to mend,
    a time to be silent(D) and a time to speak,
    a time to love and a time to hate,
    a time for war and a time for peace.

What do workers gain from their toil?(E) 10 I have seen the burden God has laid on the human race.(F) 11 He has made everything beautiful in its time.(G) He has also set eternity in the human heart; yet[a] no one can fathom(H) what God has done from beginning to end.(I) 12 I know that there is nothing better for people than to be happy and to do good while they live. 13 That each of them may eat and drink,(J) and find satisfaction(K) in all their toil—this is the gift of God.(L) 14 I know that everything God does will endure forever; nothing can be added to it and nothing taken from it. God does it so that people will fear him.(M)

15 Whatever is has already been,(N)
    and what will be has been before;(O)
    and God will call the past to account.[b]

16 And I saw something else under the sun:

In the place of judgment—wickedness was there,
    in the place of justice—wickedness was there.

17 I said to myself,

“God will bring into judgment(P)
    both the righteous and the wicked,
for there will be a time for every activity,
    a time to judge every deed.”(Q)

18 I also said to myself, “As for humans, God tests them so that they may see that they are like the animals.(R) 19 Surely the fate of human beings(S) is like that of the animals; the same fate awaits them both: As one dies, so dies the other. All have the same breath[c]; humans have no advantage over animals. Everything is meaningless. 20 All go to the same place; all come from dust, and to dust all return.(T) 21 Who knows if the human spirit rises upward(U) and if the spirit of the animal goes down into the earth?”

22 So I saw that there is nothing better for a person than to enjoy their work,(V) because that is their lot.(W) For who can bring them to see what will happen after them?

Footnotes

  1. Ecclesiastes 3:11 Or also placed ignorance in the human heart, so that
  2. Ecclesiastes 3:15 Or God calls back the past
  3. Ecclesiastes 3:19 Or spirit