Add parallel Print Page Options

Ìbọ̀rìṣà Mika

17 Nígbà náà ni ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika láti agbègbè òkè Efraimu sọ fún ìyá rẹ̀ pé, “Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà èyí tí wọ́n jí mọ́ ọ lọ́wọ́, àti nípa èyí tí mo gbọ́ tí ìwọ ń ṣẹ́ èpè. Kíyèsi fàdákà náà wà ní ọ̀dọ̀ mi, èmi ni mo kó o.”

Nígbà náà ni ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Kí Olúwa bùkún ọ ọmọ mi!”

Nígbà tí ó da ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Èmi ti fi òtítọ́ inú ya sílífà náà sọ́tọ̀ sí Olúwa fún ọmọ mi láti fi dá ère dídá àti ère gbígbẹ́. Èmi yóò dá a padà fún ọ.”

Nítorí náà òun dá sílífà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì mú igba (200) ṣékélì fàdákà, ó sì fún alágbẹ̀dẹ fàdákà ẹni tí ó fi wọ́n rọ ère fínfín àti ère dídà. Wọ́n sì kó wọn sí ilé Mika.

Ọkùnrin náà, Mika sì ní ojúbọ kan. Òun sì ra ẹ̀wù efodu kan, ó sì ṣe àwọn ère kan, ó sì fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin ṣe àlùfáà rẹ̀. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba; olúkúlùkù ṣe bí ó ti rò pé ó tọ́ ní ojú ara rẹ́.

Ọ̀dọ́mọkùnrin kan sì ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda wá, tí í ṣe ìdílé Juda, ẹni tí í ṣe ẹ̀yà Lefi, òun sì ṣe àtìpó níbẹ̀, Ọkùnrin náà sì ti ìlú Bẹtilẹhẹmu ti Juda lọ, láti ṣe àtìpó ní ibikíbi tí ó bá rí. Ní ojú ọ̀nà àjò rẹ̀, ó dé ilẹ̀ Mika nínú àwọn ilẹ̀ òkè Efraimu.

Mika bi í pé, “Níbo ni ó ti ń bọ̀?”

Ó dáhùn pé, “Ọmọ Lefi ni mí láti Bẹtilẹhẹmu Juda, mo sì ń wá ibi tí èmi yóò máa gbé.”

10 Mika sì sọ fún un wí pé, “Dúró lọ́dọ̀ mi kí ìwọ sì jẹ́ baba mi àti àlùfáà fún mi, èmi ó sì máa fún ọ ní ṣékélì mẹ́wàá fàdákà ní ọdọọdún, pẹ̀lú aṣọ àti oúnjẹ rẹ̀.” 11 Ọmọ Lefi náà sì gbà láti máa bá a gbé, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀. 12 Nígbà náà ni Mika ya ará Lefi náà sí mímọ́, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì di àlùfáà rẹ̀, ó sì ń gbé ilé rẹ̀. 13 Mika sì wí pé, “Báyìí, èmi mọ̀ pé Olúwa yóò ṣe mi ní oore nítorí pé mo ní ọmọ Lefi ní àlùfáà mi.”

Micah’s Idols

17 Now a man named Micah(A) from the hill country of Ephraim said to his mother, “The eleven hundred shekels[a] of silver that were taken from you and about which I heard you utter a curse—I have that silver with me; I took it.”

Then his mother said, “The Lord bless you,(B) my son!”

When he returned the eleven hundred shekels of silver to his mother, she said, “I solemnly consecrate my silver to the Lord for my son to make an image overlaid with silver.(C) I will give it back to you.”

So after he returned the silver to his mother, she took two hundred shekels[b] of silver and gave them to a silversmith, who used them to make the idol.(D) And it was put in Micah’s house.

Now this man Micah had a shrine,(E) and he made an ephod(F) and some household gods(G) and installed(H) one of his sons as his priest.(I) In those days Israel had no king;(J) everyone did as they saw fit.(K)

A young Levite(L) from Bethlehem in Judah,(M) who had been living within the clan of Judah, left that town in search of some other place to stay. On his way[c] he came to Micah’s house in the hill country of Ephraim.

Micah asked him, “Where are you from?”

“I’m a Levite from Bethlehem in Judah,(N)” he said, “and I’m looking for a place to stay.”

10 Then Micah said to him, “Live with me and be my father(O) and priest,(P) and I’ll give you ten shekels[d] of silver a year, your clothes and your food.” 11 So the Levite agreed to live with him, and the young man became like one of his sons to him. 12 Then Micah installed(Q) the Levite, and the young man became his priest(R) and lived in his house. 13 And Micah said, “Now I know that the Lord will be good to me, since this Levite has become my priest.”(S)

Footnotes

  1. Judges 17:2 That is, about 28 pounds or about 13 kilograms
  2. Judges 17:4 That is, about 5 pounds or about 2.3 kilograms
  3. Judges 17:8 Or To carry on his profession
  4. Judges 17:10 That is, about 4 ounces or about 115 grams