Numeri 24
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
24 Nísinsin yìí nígbà tí Balaamu rí i wí pé ó tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn láti bùkún àwọn Israẹli, kò lo ọ̀nà ìṣoṣó gẹ́gẹ́ bí ti ìgbà ìṣáájú, ṣùgbọ́n ó yí ojú rẹ̀ sí apá aginjù. 2 Nígbà tí Balaamu wo ìta ó sì rí Israẹli tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀ 3 ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀:
“Ó wí pé Balaamu ọmọ Beori,
òwe ẹni tí ojú rẹ̀ mọ́lẹ̀,
4 Òwe ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run,
ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè,
ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì là:
5 “Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jakọbu,
àti ibùgbé rẹ, ìwọ Israẹli!
6 “Gẹ́gẹ́ bí Àfonífojì tí ó tàn jáde,
gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá,
gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí Olúwa gbìn,
gẹ́gẹ́ bí igi kedari tí ó wà lẹ́bàá odò.
7 Omi yóò sàn láti inú garawa:
èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
“Ọba wọn yóò ga ju Agagi lọ;
ìjọba wọn yóò di gbígbéga.
8 “Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá;
wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti àgbáǹréré.
Wọ́n jẹ orílẹ̀-èdè tí ń ṣe ọ̀tá rẹ̀ run,
wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí túútúú;
wọ́n ó sì fi ọfà wọn ta wọ́n ní àtapòyọ.
9 (A)Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún,
bí abo kìnnìún: ta ni ó gbọdọ̀ jí wọn?
“Ìbùkún ni fún ẹni tí ó bùkún fún ọ,
kí ìfibú jẹ́ ti ẹni tí ó fi ọ́ bú!”
10 Nígbà náà ni ìbínú Balaki sì dé sí Balaamu. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀tá mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí. 11 Nísinsin yìí sálọ sí ibùjókòó rẹ! Èmi ti rò láti sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n Olúwa tí fà ọ́ sẹ́yìn láti gba èrè yìí.”
12 Balaamu dá Balaki lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé, 13 ‘Kódà bí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin Olúwa: ohun tí Olúwa bá wí ni èmi ó sọ’? 14 Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”
Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ẹ̀kẹrin Balaamu
15 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe:
“Òwe Balaamu ọmọ Beori,
òwe ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
16 Ẹni tó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń wí,
tí ó sì mọ ìmọ̀ Ọ̀gá-ògo,
tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè,
ẹni tí ó dọ̀bálẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì ṣí:
17 “Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí,
Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́.
Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jakọbu;
yóò yọ jáde láti Israẹli.
Yóò tẹ̀ fọ́ orí Moabu,
yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Seti.
18 Wọn yóò borí Edomu;
yóò ṣẹ́gun Seiri ọ̀tá rẹ̀,
ṣùgbọ́n Israẹli yóò dàgbà nínú agbára.
19 Olórí yóò jáde láti Jakọbu
yóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”
Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ìkẹyìn Balaamu
20 Nígbà náà ni Balaamu rí Amaleki ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe:
“Amaleki ni àkọ́kọ́ nínú àwọn orílẹ̀-èdè,
ṣùgbọ́n yóò dahoro níkẹyìn.”
21 Nígbà náà ní ó rí ará Keni ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe:
“Ibùgbé rẹ ní ààbò,
ìtẹ́ rẹ ni a tò sínú àpáta;
22 síbẹ̀ ẹ̀yin ará Keni ni yóò di píparun
nígbà tí Asiria bá mú yín ní ìgbèkùn.”
23 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀:
“Háà, ta ni ó lè yè nígbà tí Ọlọ́run bá ṣe èyí?
24 Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdókọ̀ Kittimu;
wọn yóò ṣẹ́gun Asiria àti Eberi,
ṣùgbọ́n àwọn náà yóò di píparun.”
25 Nígbà náà ni Balaamu dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Balaki sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.
Numbers 24
New King James Version
Balaam Foretells the Happiness of Israel
24 Now when Balaam saw that it pleased the Lord to bless Israel, he did not go as at (A)other times, to seek to use [a]sorcery, but he set his face toward the wilderness. 2 And Balaam raised his eyes, and saw Israel (B)encamped according to their tribes; and (C)the Spirit of God came upon him.
3 (D)Then he took up his oracle and said:
“The utterance of Balaam the son of Beor,
The utterance of the man whose eyes are opened,
4 The utterance of him who hears the words of God,
Who sees the vision of the Almighty,
Who (E)falls down, with eyes wide open:
5 “How lovely are your tents, O Jacob!
Your dwellings, O Israel!
6 Like valleys that stretch out,
Like gardens by the riverside,
(F)Like aloes (G)planted by the Lord,
Like cedars beside the waters.
7 He shall pour water from his buckets,
And his seed shall be (H)in many waters.
8 “God(K) brings him out of Egypt;
He has strength like a wild ox;
He shall (L)consume the nations, his enemies;
He shall (M)break their bones
And (N)pierce them with his arrows.
9 ‘He(O) bows down, he lies down as a lion;
And as a lion, who shall rouse him?’
(P)“Blessed is he who blesses you,
And cursed is he who curses you.”
10 Then Balak’s anger was aroused against Balaam, and he (Q)struck his hands together; and Balak said to Balaam, (R)“I called you to curse my enemies, and look, you have bountifully blessed them these three times! 11 Now therefore, flee to your place. (S)I said I would greatly honor you, but in fact, the Lord has kept you back from honor.”
12 So Balaam said to Balak, “Did I not also speak to your messengers whom you sent to me, saying, 13 ‘If Balak were to give me his house full of silver and gold, I could not go beyond the word of the Lord, to do good or bad of my own will. What the Lord says, that I must speak’? 14 And now, indeed, I am going to my people. Come, (T)I will advise you what this people will do to your people in the (U)latter days.”
Balaam’s Fourth Prophecy
15 So he took up his oracle and said:
“The utterance of Balaam the son of Beor,
And the utterance of the man whose eyes are opened;
16 The utterance of him who hears the words of God,
And has the knowledge of the Most High,
Who sees the vision of the Almighty,
Who falls down, with eyes wide open:
17 “I(V) see Him, but not now;
I behold Him, but not near;
(W)A Star shall come out of Jacob;
(X)A Scepter shall rise out of Israel,
And [b]batter the brow of Moab,
And destroy all the sons of [c]tumult.
18 “And (Y)Edom shall be a possession;
Seir also, his enemies, shall be a possession,
While Israel does [d]valiantly.
19 (Z)Out of Jacob One [e]shall have dominion,
And destroy the remains of the city.”
20 Then he looked on Amalek, and he took up his oracle and said:
“Amalek was first among the nations,
But shall be last until he perishes.”
21 Then he looked on the Kenites, and he took up his oracle and said:
“Firm is your dwelling place,
And your nest is set in the rock;
22 Nevertheless Kain shall be burned.
How long until Asshur carries you away captive?”
23 Then he took up his oracle and said:
“Alas! Who shall live when God does this?
24 But ships shall come from the coasts of (AA)Cyprus,[f]
And they shall afflict Asshur and afflict (AB)Eber,
And so shall [g]Amalek, until he perishes.”
25 So Balaam rose and departed and (AC)returned to his place; Balak also went his way.
Footnotes
- Numbers 24:1 enchantments
- Numbers 24:17 shatter the forehead
- Numbers 24:17 Heb. Sheth, Jer. 48:45
- Numbers 24:18 mightily
- Numbers 24:19 shall rule
- Numbers 24:24 Heb. Kittim
- Numbers 24:24 Lit. he or that one
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Scripture taken from the New King James Version®. Copyright © 1982 by Thomas Nelson. Used by permission. All rights reserved.
