Add parallel Print Page Options

Fèrè ìpè fàdákà

10 Olúwa sọ fún Mose pé: Ṣe fèrè fàdákà méjì pẹ̀lú fàdákà lílù, kí o máa lò ó láti máa fi pe ìjọ ènìyàn àti láti máa fi darí ìrìnàjò lọ sí ibùdó yín. Nígbà tí o bá fọn méjèèjì gbogbo ìjọ ènìyàn yóò pé síwájú rẹ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Bí ó bá jẹ́ ọ̀kan ni o fọn, nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Israẹli yóò péjọ síwájú rẹ. Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì, àwọn ẹ̀yà tó pa ibùdó sí ìhà ìlà-oòrùn ni yóò gbéra. Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì kejì, ibùdó tó wà ní ìhà gúúsù ni yóò gbéra. Ìpè ìdágìrì yìí ni yóò jẹ́ ààmì fún gbígbéra. Nígbà tí o bá fẹ́ pe ìjọ ènìyàn jọ, fun fèrè nìkan, má ṣe fun ti ìdágìrì pẹ̀lú rẹ̀.

“Àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni kí ó máa fun fèrè. Èyí yóò jẹ́ ìlànà láéláé fún yín àti fún ìran tó ń bọ̀. Nígbà tí ẹ bá lọ jagun pẹ̀lú àwọn ọ̀tá tó ń ni yín lára ní ilẹ̀ yín, ẹ fun ìpè ìdágìrì pẹ̀lú fèrè. A ó sì rántí yín níwájú Olúwa, Ọlọ́run yín yóò sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá yín. 10 Bẹ́ẹ̀ náà ni ní ọjọ́ ayọ̀ yín, ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn àti ní ìbẹ̀rẹ̀ oṣù yín, ni kí ẹ máa fun fèrè lórí ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà yín, wọn yóò sì jẹ́ ìrántí fún yín níwájú Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”

Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Sinai

11 Ní ogúnjọ́ oṣù kejì, ní ọdún kejì ni ìkùùkuu kúrò lórí tabanaku ẹ̀rí. 12 Àwọn ọmọ Israẹli sì gbéra kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì rin ìrìnàjò wọn káàkiri títí tí ìkùùkuu fi dúró sí aginjù Parani. 13 Wọ́n gbéra nígbà àkọ́kọ́ yìí nípa àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.

14 Àwọn ìpín ti ibùdó Juda ló kọ́kọ́ gbéra tẹ̀lé wọn lábẹ́ ogun wọn Nahiṣoni ọmọ Amminadabu ni ọ̀gágun wọn. 15 Netaneli ọmọ Ṣuari ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Isakari; 16 Eliabu ọmọ Heloni ni ọ̀gágun ni ìpín ti ẹ̀yà Sebuluni. 17 Nígbà náà ni wọ́n sọ tabanaku kalẹ̀ àwọn ọmọ Gerṣoni àti Merari tó gbé àgọ́ sì gbéra.

18 Àwọn ìpín ti ibùdó ti Reubeni ló gbéra tẹ̀lé wọn, lábẹ́ ọ̀págun wọn. Elisuri ọmọ Ṣedeuri ni ọ̀gágun wọn. 19 Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Simeoni. 20 Eliasafu ọmọ Deueli ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Gadi. 21 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Kohati tí ń ru ohun mímọ́ náà gbéra. Àwọn ti àkọ́kọ́ yóò sì ti gbé tabanaku dúró kí wọn tó dé.

22 Àwọn ìpín tó wà ní ibùdó Efraimu ló tún kàn lábẹ́ ọ̀págun wọn. Eliṣama ọmọ Ammihudu ni ọ̀gágun wọn. 23 Gamalieli ọmọ Pedasuri ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Manase. 24 Abidani ọmọ Gideoni ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Benjamini.

25 Lákòótan, àwọn ọmọ-ogun tó ń mójútó ẹ̀yìn ló tún kàn, àwọn ni ìpín ti ibùdó Dani lábẹ́ ọ̀págun wọn. Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai ni ọ̀gágun wọn. 26 Pagieli ọmọ Okanri ni ìpín ti ẹ̀yà Aṣeri, 27 Ahira ọmọ Enani ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Naftali; 28 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli ṣe tò jáde gẹ́gẹ́ bí ogun nígbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn.

29 Mose sì sọ fún Hobabu ọmọ Reueli ará Midiani tí í ṣe àna rẹ̀ pé, “A ń gbéra láti lọ sí ibi tí Olúwa sọ pé, ‘Èmi ó fi fún un yín.’ Bá wa lọ, àwa ó ṣe ọ́ dáradára nítorí pé Olúwa ti ṣèlérí ohun rere fún Israẹli.”

30 Ó sì dáhùn pé, “Rárá, èmi kò ní bá yín lọ, mò ń padà lọ sí ilẹ̀ mi àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi.”

31 Mose sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ma fi wá sílẹ̀, ìwọ mọ ibi tí a lè pa ibùdó sí nínú aginjù, ìwọ yóò sì jẹ́ ojú fún wa. 32 Bí o bá bá wa lọ, a ó sì pín fún ọ nínú ohun rere yówù tí Olúwa bá fún wa.”

33 Wọ́n sì gbéra láti orí òkè Olúwa ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Àpótí ẹ̀rí Olúwa ń lọ níwájú wọn fún gbogbo ọjọ́ mẹ́ta yìí láti wá ibi ìsinmi fún wọn. 34 Ìkùùkuu Olúwa wà lórí wọn lọ́sàn nígbà tí wọ́n gbéra kúrò ní ibùdó.

35 (A)Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá gbéra Mose yóò sì wí pé,

“Dìde, Olúwa!
    Kí a tú àwọn ọ̀tá rẹ ká,
    kí àwọn tí ó kórìíra rẹ sì sálọ níwájú rẹ.”

36 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá sinmi yóò wí pé;

“Padà, Olúwa,
    Sọ́dọ̀ àwọn àìmoye ẹgbẹẹgbẹ̀rún Israẹli.”

10 Yahweh spoke to Moses, saying, “Make two trumpets of silver. You shall make them of beaten work. You shall use them for the calling of the congregation and for the journeying of the camps. When they blow them, all the congregation shall gather themselves to you at the door of the Tent of Meeting. If they blow just one, then the princes, the heads of the thousands of Israel, shall gather themselves to you. When you blow an alarm, the camps that lie on the east side shall go forward. When you blow an alarm the second time, the camps that lie on the south side shall go forward. They shall blow an alarm for their journeys. But when the assembly is to be gathered together, you shall blow, but you shall not sound an alarm.

“The sons of Aaron, the priests, shall blow the trumpets. This shall be to you for a statute forever throughout your generations. When you go to war in your land against the adversary who oppresses you, then you shall sound an alarm with the trumpets. Then you will be remembered before Yahweh your God, and you will be saved from your enemies.

10 “Also in the day of your gladness, and in your set feasts, and in the beginnings of your months, you shall blow the trumpets over your burnt offerings, and over the sacrifices of your peace offerings; and they shall be to you for a memorial before your God. I am Yahweh your God.”

11 In the second year, in the second month, on the twentieth day of the month, the cloud was taken up from over the tabernacle of the covenant. 12 The children of Israel went forward on their journeys out of the wilderness of Sinai; and the cloud stayed in the wilderness of Paran. 13 They first went forward according to the commandment of Yahweh by Moses.

14 First, the standard of the camp of the children of Judah went forward according to their armies. Nahshon the son of Amminadab was over his army. 15 Nethanel the son of Zuar was over the army of the tribe of the children of Issachar. 16 Eliab the son of Helon was over the army of the tribe of the children of Zebulun. 17 The tabernacle was taken down; and the sons of Gershon and the sons of Merari, who bore the tabernacle, went forward. 18 The standard of the camp of Reuben went forward according to their armies. Elizur the son of Shedeur was over his army. 19 Shelumiel the son of Zurishaddai was over the army of the tribe of the children of Simeon. 20 Eliasaph the son of Deuel was over the army of the tribe of the children of Gad.

21 The Kohathites set forward, bearing the sanctuary. The others set up the tabernacle before they arrived.

22 The standard of the camp of the children of Ephraim set forward according to their armies. Elishama the son of Ammihud was over his army. 23 Gamaliel the son of Pedahzur was over the army of the tribe of the children of Manasseh. 24 Abidan the son of Gideoni was over the army of the tribe of the children of Benjamin.

25 The standard of the camp of the children of Dan, which was the rear guard of all the camps, set forward according to their armies. Ahiezer the son of Ammishaddai was over his army. 26 Pagiel the son of Ochran was over the army of the tribe of the children of Asher. 27 Ahira the son of Enan was over the army of the tribe of the children of Naphtali. 28 Thus were the travels of the children of Israel according to their armies; and they went forward.

29 Moses said to Hobab, the son of Reuel the Midianite, Moses’ father-in-law, “We are journeying to the place of which Yahweh said, ‘I will give it to you.’ Come with us, and we will treat you well; for Yahweh has spoken good concerning Israel.”

30 He said to him, “I will not go; but I will depart to my own land, and to my relatives.”

31 Moses said, “Don’t leave us, please; because you know how we are to encamp in the wilderness, and you can be our eyes. 32 It shall be, if you go with us—yes, it shall be—that whatever good Yahweh does to us, we will do the same to you.”

33 They set forward from the Mount of Yahweh three days’ journey. The ark of Yahweh’s covenant went before them three days’ journey, to seek out a resting place for them. 34 The cloud of Yahweh was over them by day, when they set forward from the camp. 35 When the ark went forward, Moses said, “Rise up, Yahweh, and let your enemies be scattered! Let those who hate you flee before you!” 36 When it rested, he said, “Return, Yahweh, to the ten thousands of the thousands of Israel.”