Numeri 3
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Àwọn ẹ̀yà Lefi
3 Ìwọ̀nyí ni ìdílé Aaroni àti Mose ní ìgbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní òkè Sinai.
2 (A)Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni nìwọ̀nyí, Nadabu ni àkọ́bí, Abihu, Eleasari àti Itamari. 3 Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni ni ìwọ̀nyí, àwọn àlùfáà tí a fi òróró yàn, àwọn tí a fi joyè àlùfáà láti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà. 4 Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu ti kú níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n rú iná àjèjì níwájú Olúwa nínú ijù Sinai, àwọn méjèèjì kò sì ní ọmọ. Báyìí Eleasari àti Itamari ló ṣiṣẹ́ àlùfáà nígbà ayé Aaroni baba wọn.
5 (B)(C) Olúwa sọ fún Mose pé, 6 “Kó ẹ̀yà Lefi wá, kí o sì fà wọ́n fún Aaroni àlùfáà láti máa ràn án lọ́wọ́. 7 Wọn yóò máa ṣiṣẹ́ fún un àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn ní àgọ́ ìpàdé bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú àgọ́. 8 Wọn yóò máa tọ́jú gbogbo ohun èlò inú àgọ́ ìpàdé, wọn yóò sì máa ṣe ojúṣe àwọn ọmọ Israẹli nípa ṣíṣe iṣẹ́ nínú àgọ́. 9 Fi ẹ̀yà Lefi jì Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn nìkan ni a fi fún Aaroni nínú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli. 10 Kí o sì yan Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ láti máa ṣiṣẹ́ àlùfáà; àlejò tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ pípa ni kí ẹ pa á.”
11 (D)Olúwa tún sọ fún Mose pé, 12 “Báyìí èmi fúnra mi ti mú ẹ̀yà Lefi láàrín àwọn ọmọ Israẹli dípò gbogbo àkọ́bí ọkùnrin àwọn ọmọbìnrin Israẹli. Ti èmi ni àwọn ọmọ Lefi, 13 nítorí pé ti èmi ni gbogbo àkọ́bí. Ní ọjọ́ tí mo pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti ya gbogbo àkọ́bí sọ́tọ̀ ní Israẹli yálà ti ènìyàn tàbí ti ẹranko. Gbogbo wọn gbọdọ̀ jẹ́ ti èmi. Èmi ni Olúwa.”
Kíka àwọn ọmọ Lefi
14 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose ní aginjù Sinai pé, 15 (E)“Ka àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn kí o ka gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ oṣù kan sókè” 16 Mose sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.
17 (F)Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi:
Gerṣoni, Kohati àti Merari.
18 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni:
Libni àti Ṣimei.
19 Àwọn ìdílé Kohati ni:
Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.
20 Àwọn ìdílé Merari ni:
Mahili àti Muṣi.
Wọ̀nyí ni ìdílé Lefi gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
21 Ti Gerṣoni ni ìdílé Libni àti Ṣimei; àwọn ni ìdílé Gerṣoni.
22 Iye àwọn ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, jẹ́ ẹgbàata ó-lé-ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ (7,500).
23 Àwọn ìdílé Gerṣoni yóò pa ibùdó sí ìhà ìwọ̀-oòrùn lẹ́yìn àgọ́.
24 Olórí àwọn ìdílé Gerṣoni ni Eliasafu ọmọ Láélì.
25 Iṣẹ́ àwọn ìdílé Gerṣoni nínú àgọ́ ìpàdé ni pé àwọn yóò máa tọ́jú àgọ́, ìbòrí àgọ́, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, 26 aṣọ títa ti àgbàlá, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, àwọn okùn rẹ̀ àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.
27 Ti Kohati ní ìdílé Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli, wọ̀nyí ni ìran Kohati.
28 Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbàá-mẹ́rin ó-lé-ẹgbẹ̀ta (8,600),
tí yóò máa ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́.
29 Àwọn ìdílé Kohati yóò pa ibùdó wọn sí ìhà gúúsù ní ẹ̀gbẹ́ àgọ́.
30 Olórí àwọn ìdílé Kohati ni Elisafani ọmọ Usieli.
31 Àwọn ni yóò máa tọ́jú àpótí ẹ̀rí, tábìlì, ọ̀pá fìtílà, àwọn pẹpẹ, gbogbo ohun èlò ibi mímọ́ tí à ń lò fún iṣẹ́ ìsìn, aṣọ títa àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.
32 Eleasari ọmọ Aaroni àlùfáà ni alákòóso gbogbo àwọn olórí ìdílé Lefi. Òun ni wọ́n yàn lórí gbogbo àwọn tí yóò máa tọ́jú ibi mímọ́.
33 Ti Merari ni ìran Mahili àti Muṣi, àwọn ni ìran Merari.
34 Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, èyí tí wọ́n kà jẹ́ igba mọ́kànlélọ́gbọ̀n (6,200).
35 Olórí àwọn ìdílé ìran Merari ni Ṣurieli ọmọ Abihaili.
Wọn yóò pa ibùdó wọn sí ìhà àríwá àgọ́.
36 Àwọn ìran Merari ni a yàn fún títọ́jú àwọn férémù àgọ́, ọ̀pá ìdábùú rẹ̀, òpó rẹ̀, ihò òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn; 37 Iṣẹ́ wọn tún ni títọ́jú àwọn òpó tó yí àgbàlá ká, ihò òpó rẹ̀, èèkàn àti okùn wọn.
38 Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn ọmọ yóò pa àgọ́ ní ìdojúkọ ìwọ̀-oòrùn níwájú àgọ́ ìpàdé.
Iṣẹ́ wọn ni láti máa mójútó iṣẹ́ ìsìn ibi mímọ́ àti láti máa ṣiṣẹ́ ìsìn fún àwọn ọmọ Israẹli.
Àlejò tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ yàtọ̀ sí àwọn tí a yàn, pípa ni kí ẹ pa á.
39 Àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Lefi tí a kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose àti Aaroni gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, pẹ̀lú gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbàá-mọ́kànlá (22,000).
40 Olúwa sọ fún Mose pé, “Ka gbogbo àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli láti ọmọ oṣù kan ó lé kí o sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn. 41 Kí o sì gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì gba gbogbo ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi fún mi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Èmi ni Olúwa.”
42 Mose sì ka gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un. 43 Àpapọ̀ iye àwọn àkọ́bí ọkùnrin láti ọmọ oṣù kan ó lé, ní àkọsílẹ̀ orúkọ wọn jẹ́ ẹgbàá-mọ́kànlá ó lé ọ̀rìnlúgba ó-dínméje (22,273).
44 Olúwa tún sọ fún Mose pé, 45 (G)Gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli àti ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi dípò ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Tèmi ni àwọn ọmọ Lefi. Èmi ni Olúwa. 46 Nísinsin yìí, láti lè ra ọ̀rìnlúgba dín méje (273) àkọ́bí àwọn Israẹli tó ju iye àwọn ọmọ Lefi lọ, 47 ìwọ yóò gba ṣékélì márùn-ún (5) lórí ẹni kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, èyí tí í ṣe ogún gera. 48 Owó tí a fi ra àwọn àkọ́bí ọmọ Israẹli tó lé yìí, ni kí o kó fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀.
49 Nígbà náà ni Mose gba owó ìràpadà àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi ti ra àwọn yòókù padà. 50 Mose sì gba egbèje ṣékélì ó dín márùn-dínlógójì (1,365) gẹ́gẹ́ bí iye ṣékélì ibi mímọ́ lọ́wọ́ àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli. 51 Mose sì kó owó ìràpadà yìí fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.
Numeri 3
Nouă Traducere În Limba Română
Responsabilităţile leviţilor
3 Aceştia sunt urmaşii lui Aaron şi ai lui Moise, de pe vremea când Domnul a vorbit cu Moise pe muntele Sinai. 2 Acestea sunt numele fiilor lui Aaron: Nadab, întâiul născut, Abihu, Elazar şi Itamar; 3 acestea sunt numele fiilor lui Aaron, preoţii care au primit ungerea, pe care el i-a învestit în slujba preoţiei. 4 Nadab şi Abihu au murit înaintea Domnului în pustia Sinai, atunci când au adus foc străin înaintea Domnului; ei n-au avut copii. Elazar şi Itamar au slujit ca preoţi în prezenţa tatălui lor Aaron.
5 Domnul i-a zis lui Moise: 6 „Adu-i pe cei din seminţia lui Levi şi pune-i înaintea preotului Aaron ca să-i slujească. 7 Ei să-l ajute în lucrurile pe care le are de făcut pentru el şi pentru întreaga adunare înaintea Cortului Întâlnirii, slujind la Tabernacul; 8 atunci când slujesc la Tabernacul, ei trebuie să aibă grijă de toate lucrurile din Cortul Întâlnirii şi să ajute la ceea ce li s-a poruncit israeliţilor să facă. 9 Să-i încredinţezi pe leviţi lui Aaron şi urmaşilor săi; ei sunt aceia dintre israeliţi care trebuie să-i fie încredinţaţi lui[a] cu totul. 10 Să-i pui pe Aaron şi pe urmaşii lui să-şi păzească preoţia, iar străinul[b] care se va apropia să fie omorât.“
Leviţii şi întâii născuţi ai lui Israel
11 Domnul i-a mai zis lui Moise: 12 „Iată că i-am luat pe leviţi din mijlocul israeliţilor, în locul tuturor întâilor născuţi care li se nasc israeliţilor. Leviţii vor fi ai Mei, 13 pentru că toţi întâii născuţi sunt ai Mei; când i-am lovit cu moartea pe toţi întâii născuţi din ţara Egiptului, Mi i-am pus deoparte pe toţi întâii născuţi din Israel, atât dintre oameni, cât şi dintre animale; ei vor fi ai Mei. Eu sunt Domnul.“
14 Domnul i-a vorbit lui Moise în pustia Sinai şi i-a zis: 15 „Numără-i pe leviţi după familiile şi clanurile lor. Să numeri fiecare bărbat de la vârsta de o lună în sus.“ 16 Moise i-a numărat după Cuvântul Domnului, aşa cum i s-a poruncit.
17 Acestea sunt numele fiilor lui Levi: Gherşon, Chehat şi Merari. 18 Acestea sunt numele fiilor lui Gherşon, potrivit clanurilor lor: Libni şi Şimei. 19 Fiii lui Chehat, potrivit clanurilor lor: Amram, Iţhar, Hebron şi Uziel. 20 Iar fiii lui Merari, potrivit clanurilor lor: Mahli şi Muşi. Acestea sunt clanurile leviţilor, potrivit familiilor lor.
21 Din Gherşon provin clanul lui Libni şi clanul lui Şimei; acestea alcătuiesc clanurile gherşoniţilor. 22 Cei ieşiţi la numărătoare, după ce au fost număraţi toţi bărbaţii de la vârsta de o lună în sus, erau în număr de şapte mii cinci sute. 23 Clanurile gherşoniţilor îşi făceau tabăra în spatele Tabernaculului, în partea de apus. 24 Căpetenia familiilor gherşoniţilor era Eliasaf, fiul lui Lael. 25 Responsabilitatea fiilor lui Gherşon în Cortul Întâlnirii era să aibă grijă de Tabernacul, de cort cu acoperitoarea lui, de draperia de la intrarea în Cortul Întâlnirii, 26 de draperiile curţii, de draperia de la intrarea în curtea dimprejurul Tabernaculului şi a altarului şi de funii.
27 Din Chehat provin clanul amramiţilor, clanul iţhariţilor, clanul hebroniţilor şi clanul uzieliţilor; acestea alcătuiesc clanurile chehatiţilor. 28 După ce au fost număraţi toţi bărbaţii de la vârsta de o lună în sus, s-au găsit opt mii şase sute[c] de bărbaţi care aveau grijă de lucrurile Lăcaşului. 29 Clanurile chehatiţilor îşi făceau tabăra în partea de sud a Tabernaculului. 30 Căpetenia familiilor din clanurile chehatiţilor era Eliţafan, fiul lui Uziel. 31 Responsabilitatea lor era să aibă grijă de chivot, masă, sfeşnic, altare, de uneltele Lăcaşului cu care preoţii îşi făceau slujba şi de draperie[d]. 32 Căpetenia conducătorilor leviţilor era Elazar, fiul preotului Aaron; el îi supraveghea pe cei care aveau grijă de Lăcaş.
33 Din Merari provin clanul lui Mahli şi clanul lui Muşi; acestea alcătuiesc clanurile lui Merari. 34 Cei ieşiţi la numărătoare, după ce au fost număraţi toţi bărbaţii de la vârsta de o lună în sus, erau şase mii două sute de bărbaţi. 35 Căpetenia familiilor din clanurile lui Merari era Ţuriel, fiul lui Abihail. Ei îşi făceau tabăra în partea de nord a Tabernaculului. 36 Responsabilitatea dată fiilor lui Merari era să aibă grijă de scândurile Tabernaculului, de drugi, stâlpi, piedestale şi de toate uneltele ce ţin de ele; 37 de asemenea, ei aveau grijă de stâlpii care împrejmuiau curtea, de piedestalele acestora, de ţăruşi şi de funii.
38 Cei care-şi făceau tabăra înaintea Tabernaculului, în partea de răsărit – chiar înaintea Cortului Întâlnirii, spre răsărit – erau Moise, Aaron şi fiii lui Aaron. Ei aveau în grijă Lăcaşul cu tot ce trebuia făcut pentru israeliţi; oricine altcineva care se apropia era omorât.
39 Toţi leviţii pe care i-a numărat Moise şi Aaron după porunca Domnului, potrivit clanurilor lor, şi anume toţi bărbaţii de la vârsta de o lună în sus, au fost douăzeci şi două de mii.
40 Apoi Domnul i-a zis lui Moise: „Numără-i pe toţi întâii născuţi băieţi ai israeliţilor, de la vârsta de o lună în sus, şi fă o listă cu numele lor. 41 Pe leviţi să-i iei pentru Mine – Eu sunt Domnul – în locul tuturor întâilor născuţi ai israeliţilor, iar vitele leviţilor să le iei în locul tuturor întâilor născuţi ai vitelor israeliţilor.“ 42 Moise i-a numărat pe toţi întâii născuţi ai israeliţilor, aşa cum i-a poruncit Domnul.
43 Toţi întâii născuţi băieţi de la vârsta de o lună în sus, înscrişi după numele lor, au fost douăzeci şi două de mii două sute şaptezeci şi trei.
44 După aceea, Domnul i-a zis lui Moise: 45 „Ia-i pe leviţi în locul tuturor întâilor născuţi ai israeliţilor, iar turmele leviţilor în locul turmelor acestora. Leviţii vor fi ai Mei. Eu sunt Domnul. 46 Ca preţ de răscumpărare pentru cei două sute şaptezeci şi trei dintre întâii născuţi ai israeliţilor, care trec peste numărul leviţilor, 47 să iei cinci şecheli[e] pentru fiecare în parte, după şechelul Lăcaşului (un şechel este douăzeci de ghere). 48 Să dai argintul acesta, cu care sunt răscumpăraţi cei ce trec peste numărul leviţilor, lui Aaron şi fiilor săi.“
49 Moise a luat argintul pentru răscumpărare de la cei care erau peste numărul celor răscumpăraţi de leviţi; 50 a luat argintul de la întâii născuţi ai israeliţilor: o mie trei sute şaizeci şi cinci de şecheli[f], după şechelul Lăcaşului. 51 Moise a dat argintul pentru răscumpărare lui Aaron şi fiilor săi, după Cuvântul[g] Domnului, aşa cum Domnul i-a poruncit lui Moise.
Footnotes
- Numeri 3:9 Cele mai multe mss ale TM; unele mss ale TM, PentSam şi LXX (vezi şi Num. 8:16): să-Mi fie încredinţaţi Mie
- Numeri 3:10 Vezi nota de la 1:51; şi în v. 38
- Numeri 3:28 TM; unele mss ale LXX: opt mii trei sute; totalul leviţilor din v. 39 îndreptăţeşte varianta LXX
- Numeri 3:31 Draperia despărţitoare (vezi 4:5)
- Numeri 3:47 Sau: siclii, greutate de bază, comună la toate popoarele semite antice; existau mai multe tipuri de şechel: regal (2 Sam. 14:26; aproximativ 13 gr), obişnuit (aproximativ 12 gr) şi cel al Lăcaşului (aproximativ 10 gr); greutatea şechelului a variat în diferite vremuri şi în diferite zone; aproximativ 50 gr
- Numeri 3:50 Aproximativ 13,5 kg
- Numeri 3:51 Lit.: gura, glasul
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Nouă Traducere În Limba Română (Holy Bible, New Romanian Translation) Copyright © 2006 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.