Add parallel Print Page Options

Fèrè ìpè fàdákà

10 Olúwa sọ fún Mose pé: Ṣe fèrè fàdákà méjì pẹ̀lú fàdákà lílù, kí o máa lò ó láti máa fi pe ìjọ ènìyàn àti láti máa fi darí ìrìnàjò lọ sí ibùdó yín. Nígbà tí o bá fọn méjèèjì gbogbo ìjọ ènìyàn yóò pé síwájú rẹ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Bí ó bá jẹ́ ọ̀kan ni o fọn, nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Israẹli yóò péjọ síwájú rẹ. Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì, àwọn ẹ̀yà tó pa ibùdó sí ìhà ìlà-oòrùn ni yóò gbéra. Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì kejì, ibùdó tó wà ní ìhà gúúsù ni yóò gbéra. Ìpè ìdágìrì yìí ni yóò jẹ́ ààmì fún gbígbéra. Nígbà tí o bá fẹ́ pe ìjọ ènìyàn jọ, fun fèrè nìkan, má ṣe fun ti ìdágìrì pẹ̀lú rẹ̀.

“Àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni kí ó máa fun fèrè. Èyí yóò jẹ́ ìlànà láéláé fún yín àti fún ìran tó ń bọ̀. Nígbà tí ẹ bá lọ jagun pẹ̀lú àwọn ọ̀tá tó ń ni yín lára ní ilẹ̀ yín, ẹ fun ìpè ìdágìrì pẹ̀lú fèrè. A ó sì rántí yín níwájú Olúwa, Ọlọ́run yín yóò sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá yín. 10 Bẹ́ẹ̀ náà ni ní ọjọ́ ayọ̀ yín, ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn àti ní ìbẹ̀rẹ̀ oṣù yín, ni kí ẹ máa fun fèrè lórí ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà yín, wọn yóò sì jẹ́ ìrántí fún yín níwájú Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”

Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Sinai

11 Ní ogúnjọ́ oṣù kejì, ní ọdún kejì ni ìkùùkuu kúrò lórí tabanaku ẹ̀rí. 12 Àwọn ọmọ Israẹli sì gbéra kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì rin ìrìnàjò wọn káàkiri títí tí ìkùùkuu fi dúró sí aginjù Parani. 13 Wọ́n gbéra nígbà àkọ́kọ́ yìí nípa àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.

14 Àwọn ìpín ti ibùdó Juda ló kọ́kọ́ gbéra tẹ̀lé wọn lábẹ́ ogun wọn Nahiṣoni ọmọ Amminadabu ni ọ̀gágun wọn. 15 Netaneli ọmọ Ṣuari ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Isakari; 16 Eliabu ọmọ Heloni ni ọ̀gágun ni ìpín ti ẹ̀yà Sebuluni. 17 Nígbà náà ni wọ́n sọ tabanaku kalẹ̀ àwọn ọmọ Gerṣoni àti Merari tó gbé àgọ́ sì gbéra.

18 Àwọn ìpín ti ibùdó ti Reubeni ló gbéra tẹ̀lé wọn, lábẹ́ ọ̀págun wọn. Elisuri ọmọ Ṣedeuri ni ọ̀gágun wọn. 19 Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Simeoni. 20 Eliasafu ọmọ Deueli ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Gadi. 21 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Kohati tí ń ru ohun mímọ́ náà gbéra. Àwọn ti àkọ́kọ́ yóò sì ti gbé tabanaku dúró kí wọn tó dé.

22 Àwọn ìpín tó wà ní ibùdó Efraimu ló tún kàn lábẹ́ ọ̀págun wọn. Eliṣama ọmọ Ammihudu ni ọ̀gágun wọn. 23 Gamalieli ọmọ Pedasuri ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Manase. 24 Abidani ọmọ Gideoni ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Benjamini.

25 Lákòótan, àwọn ọmọ-ogun tó ń mójútó ẹ̀yìn ló tún kàn, àwọn ni ìpín ti ibùdó Dani lábẹ́ ọ̀págun wọn. Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai ni ọ̀gágun wọn. 26 Pagieli ọmọ Okanri ni ìpín ti ẹ̀yà Aṣeri, 27 Ahira ọmọ Enani ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Naftali; 28 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli ṣe tò jáde gẹ́gẹ́ bí ogun nígbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn.

29 Mose sì sọ fún Hobabu ọmọ Reueli ará Midiani tí í ṣe àna rẹ̀ pé, “A ń gbéra láti lọ sí ibi tí Olúwa sọ pé, ‘Èmi ó fi fún un yín.’ Bá wa lọ, àwa ó ṣe ọ́ dáradára nítorí pé Olúwa ti ṣèlérí ohun rere fún Israẹli.”

30 Ó sì dáhùn pé, “Rárá, èmi kò ní bá yín lọ, mò ń padà lọ sí ilẹ̀ mi àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi.”

31 Mose sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ma fi wá sílẹ̀, ìwọ mọ ibi tí a lè pa ibùdó sí nínú aginjù, ìwọ yóò sì jẹ́ ojú fún wa. 32 Bí o bá bá wa lọ, a ó sì pín fún ọ nínú ohun rere yówù tí Olúwa bá fún wa.”

33 Wọ́n sì gbéra láti orí òkè Olúwa ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Àpótí ẹ̀rí Olúwa ń lọ níwájú wọn fún gbogbo ọjọ́ mẹ́ta yìí láti wá ibi ìsinmi fún wọn. 34 Ìkùùkuu Olúwa wà lórí wọn lọ́sàn nígbà tí wọ́n gbéra kúrò ní ibùdó.

35 (A)Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá gbéra Mose yóò sì wí pé,

“Dìde, Olúwa!
    Kí a tú àwọn ọ̀tá rẹ ká,
    kí àwọn tí ó kórìíra rẹ sì sálọ níwájú rẹ.”

36 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá sinmi yóò wí pé;

“Padà, Olúwa,
    Sọ́dọ̀ àwọn àìmoye ẹgbẹẹgbẹ̀rún Israẹli.”

The Silver Trumpets

10 The Lord spoke to Moses, saying, “Make two silver trumpets. Of hammered work you shall make them, and you shall use them for (A)summoning the congregation and for breaking camp. And when (B)both are blown, all the congregation shall gather themselves to you at the entrance of the tent of meeting. But if they blow only one, then (C)the chiefs, the heads of the tribes of Israel, shall gather themselves to you. When you blow an alarm, (D)the camps that are on the east side shall set out. And when you blow an alarm the second time, (E)the camps that are on the south side shall set out. An alarm is to be blown whenever they are to set out. But when the assembly is to be gathered together, (F)you shall blow a long blast, but you shall not (G)sound an alarm. (H)And the sons of Aaron, the priests, shall blow the trumpets. The trumpets shall be to you for a perpetual statute throughout your generations. And (I)when you go to war in your land against the adversary who (J)oppresses you, then you shall (K)sound an alarm with the trumpets, that you may be (L)remembered before the Lord your God, and you shall be saved from your enemies. 10 (M)On the day of your gladness also, and at your appointed feasts and (N)at the beginnings of your months, you shall blow the trumpets over your burnt offerings and over the sacrifices of your peace offerings. They shall be (O)a reminder of you before your God: I am the Lord your God.”

Israel Leaves Sinai

11 In the second year, in the second month, on the twentieth day of the month, (P)the cloud lifted from over the tabernacle of the testimony, 12 and the people of Israel (Q)set out by stages from the (R)wilderness of Sinai. And the cloud settled down in the (S)wilderness of Paran. 13 They set out for the first time (T)at the command of the Lord by Moses. 14 The standard of the camp of the people of Judah set out (U)first by their companies, and over their company was (V)Nahshon the son of Amminadab. 15 And over the company of the tribe of the people of Issachar was Nethanel the son of Zuar. 16 And over the company of the tribe of the people of Zebulun was Eliab the son of Helon.

17 And when (W)the tabernacle was taken down, the sons of Gershon and the sons of Merari, (X)who carried the tabernacle, set out. 18 And (Y)the standard of the camp of Reuben set out by their companies, and over their company was (Z)Elizur the son of Shedeur. 19 And over the company of the tribe of the people of Simeon was (AA)Shelumiel the son of Zurishaddai. 20 And over the company of the tribe of the people of Gad was (AB)Eliasaph the son of (AC)Deuel.

21 Then the Kohathites set out, (AD)carrying the holy things, and (AE)the tabernacle was set up before their arrival. 22 And (AF)the standard of the camp of the people of Ephraim set out by their companies, and over their company was (AG)Elishama the son of Ammihud. 23 And over the company of the tribe of the people of Manasseh was (AH)Gamaliel the son of Pedahzur. 24 And over the company of the tribe of the people of Benjamin was (AI)Abidan the son of Gideoni.

25 Then (AJ)the standard of the camp of the people of Dan, acting as the (AK)rear guard of all the camps, set out by their companies, and over their company was (AL)Ahiezer the son of Ammishaddai. 26 And over the company of the tribe of the people of Asher was (AM)Pagiel the son of Ochran. 27 And over the company of the tribe of the people of Naphtali was (AN)Ahira the son of Enan. 28 (AO)This was the order of march of the people of Israel by their companies, when they set out.

29 And Moses said to Hobab the son of (AP)Reuel the Midianite, Moses' father-in-law, “We are setting out for the place of which the Lord said, (AQ)‘I will give it to you.’ Come with us, and we will do good to you, for (AR)the Lord has promised good to Israel.” 30 But he said to him, “I will not go. I will depart to my own land and to my kindred.” 31 And he said, “Please do not leave us, for you know where we should camp in the wilderness, and you will serve (AS)as eyes for us. 32 And if you do go with us, (AT)whatever good the Lord will do to us, the same will we do to you.”

33 So they set out from (AU)the mount of the Lord three days' journey. And the ark of the covenant of the Lord went before them three days' journey, to seek out (AV)a resting place for them. 34 (AW)And the cloud of the Lord was over them by day, whenever they set out from the camp.

35 And whenever the ark set out, Moses said, (AX)“Arise, O Lord, and let your enemies be scattered, and let those who hate you flee before you.” 36 And when it rested, he said, “Return, O Lord, to the ten thousand thousands of Israel.”