Add parallel Print Page Options

10 Àwọn tí ó fi èdìdì dì í ni:

Nehemiah baálẹ̀, ọmọ Hakaliah.

Sedekiah Seraiah, Asariah, Jeremiah,

Paṣuri, Amariah, Malkiah,

Hattusi, Ṣebaniah, Malluki,

Harimu, Meremoti, Ọbadiah,

Daniẹli, Ginetoni, Baruku,

Meṣullamu, Abijah, Mijamini,

Maasiah, Bilgai àti Ṣemaiah.

Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà.

Àwọn ọmọ Lefi:

Jeṣua ọmọ Asaniah, Binnui ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Henadadi, Kadmieli,

10 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn: Ṣebaniah,

Hodiah, Kelita, Pelaiah, Hanani,

11 Mika, Rehobu, Haṣabiah,

12 Sakkuri, Ṣerebiah, Ṣebaniah,

13 Hodiah, Bani àti Beninu.

14 Àwọn olórí àwọn ènìyàn:

Paroṣi, Pahati-Moabu, Elamu, Sattu, Bani,

15 Bunni, Asgadi, Bebai.

16 Adonijah, Bigfai, Adini,

17 Ateri, Hesekiah, Assuri,

18 Hodiah, Haṣumu, Besai,

19 Harifu, Anatoti, Nebai,

20 Magpiaṣi, Meṣullamu, Hesiri

21 Meṣesabeli, Sadoku, Jaddua

22 Pelatiah, Hanani, Anaiah,

23 Hosea, Hananiah, Haṣubu,

24 Halloheṣi, Pileha, Ṣobeki,

25 Rehumu, Haṣabna, Maaseiah,

26 Ahijah, Hanani, Anani,

27 Malluki, Harimu, àti Baanah.

28 “Àwọn ènìyàn tókù—àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn aṣọ́nà, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn àjèjì nítorí òfin Ọlọ́run, papọ̀ pẹ̀lú ìyàwó wọn, gbogbo ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, tí òye yé 29 gbogbo wọn fi ara mọ́ àwọn arákùnrin wọn, àwọn ọlọ́lá, wọ́n sì fi ègún àti ìbúra dé ara wọn láti máa tẹ̀lé òfin Ọlọ́run tí a fi fún wọn ní ipasẹ̀ Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti láti pa gbogbo àṣẹ, ìlànà àti òfin Olúwa, wa mọ́ dáradára.

30 “A ti ṣe ìlérí pé, a kò ní fi àwọn ọmọbìnrin wa fún àwọn tí wọ́n wà ní àyíká wa bí ìyàwó, tàbí fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin wa.

31 “Nígbà tí àwọn ènìyàn àdúgbò bá mú ọjà tàbí oúnjẹ wá ní ọjọ́ ìsinmi láti tà, àwa kò ní rà á ní ọwọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi tàbí ní ọjọ́ mímọ́ kankan. Ní gbogbo ọdún keje àwa kò ní ro ilẹ̀ náà, a ó sì pa gbogbo àwọn gbèsè rẹ́.

32 “Àwa gbà ojúṣe láti máa pa àṣẹ mọ́ pé a ó máa san ìdámẹ́ta ṣékélì ní ọdọọdún fún iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa: 33 Nítorí oúnjẹ tí ó wà lórí tábìlì; nítorí ọrẹ ohun jíjẹ àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo; nítorí ọrẹ ọjọ́ ìsinmi, ti àyajọ́ oṣù tuntun àti àjọ̀dún tí a yàn; nítorí ọrẹ mímọ́; nítorí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún Israẹli; àti fún gbogbo iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa.

34 “Àwa, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ènìyàn náà ti dìbò láti pinnu ìgbà tí olúkúlùkù àwọn ìdílé yóò mú ọrẹ igi wá láti sun lọ́ríi pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa sí ilé Ọlọ́run wa, ní àkókò tí a yàn ní ọdọọdún. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin.

35 “Àwa tún gbà ojúṣe láti mú àkọ́so àwọn èso wa wá àti gbogbo èso igi wá ní ilé Olúwa.

36 “Gẹ́gẹ́ bí a sì ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin, àwa yóò mú àkọ́bí àwọn ọmọkùnrin wa, ti ohun ọ̀sìn wa, ti àwọn abo màlúù àti ti àwọn àgùntàn wa, wá sí ilé Ọlọ́run wa, fún àwọn àlùfáà tí ń ṣiṣẹ́ níbẹ̀.

37 “Síwájú sí i, àwa yóò mú àkọ́so oúnjẹ ilẹ̀ wa ti ọrẹ oúnjẹ, ti gbogbo èso àwọn igi àti ti wáìnì tuntun wa àti ti òróró wá sí yàrá ìkó-nǹkan-pamọ́-sí ilé Ọlọ́run wa àti fún àwọn àlùfáà. Àwa yóò sì mú ìdámẹ́wàá ohun ọ̀gbìn wá fún àwọn ọmọ Lefi, nítorí àwọn ọmọ Lefi ni ó ń gba ìdámẹ́wàá ní gbogbo àwọn ìlú tí a ti ń ṣiṣẹ́. 38 Àlùfáà tí o ti ìdílé Aaroni wá ni yóò wá pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nígbà tí wọ́n bá ń gba ìdámẹ́wàá, àwọn ọmọ Lefi yóò sì mú ìdámẹ́wàá ti ìdámẹ́wàá náà wá sí ilé Ọlọ́run, sí yàrá ìkó-nǹkan-pamọ́-sí inú ilé ìṣúra. 39 Àwọn ènìyàn Israẹli, àti àwọn ọmọ Lefi gbọdọ̀ mú ọrẹ oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró wá sí yàrá ìkó-nǹkan-pamọ́-sí níbi tí a pa ohun èlò ibi mímọ́ mọ́ sí àti ibi tí àwọn àlùfáà tí ń ṣe ìránṣẹ́ lọ́wọ́, àwọn aṣọ́nà àti àwọn akọrin máa ń dúró sí.

“Àwa kì yóò gbàgbé tàbí ṣe àìbìkítà nípa ilé Ọlọ́run wa.”

10 [a]Those who sealed it were:

Nehemiah the governor, the son of Hakaliah.

Zedekiah, Seraiah,(A) Azariah, Jeremiah,

Pashhur,(B) Amariah, Malkijah,

Hattush, Shebaniah, Malluk,

Harim,(C) Meremoth, Obadiah,

Daniel, Ginnethon, Baruch,

Meshullam, Abijah, Mijamin,

Maaziah, Bilgai and Shemaiah.

These were the priests.(D)

The Levites:(E)

Jeshua son of Azaniah, Binnui of the sons of Henadad, Kadmiel,

10 and their associates: Shebaniah,

Hodiah, Kelita, Pelaiah, Hanan,

11 Mika, Rehob, Hashabiah,

12 Zakkur, Sherebiah, Shebaniah,

13 Hodiah, Bani and Beninu.

14 The leaders of the people:

Parosh, Pahath-Moab, Elam, Zattu, Bani,

15 Bunni, Azgad, Bebai,

16 Adonijah, Bigvai, Adin,(F)

17 Ater, Hezekiah, Azzur,

18 Hodiah, Hashum, Bezai,

19 Hariph, Anathoth, Nebai,

20 Magpiash, Meshullam, Hezir,(G)

21 Meshezabel, Zadok, Jaddua,

22 Pelatiah, Hanan, Anaiah,

23 Hoshea, Hananiah,(H) Hasshub,

24 Hallohesh, Pilha, Shobek,

25 Rehum, Hashabnah, Maaseiah,

26 Ahiah, Hanan, Anan,

27 Malluk, Harim and Baanah.

28 “The rest of the people—priests, Levites, gatekeepers, musicians, temple servants(I) and all who separated themselves from the neighboring peoples(J) for the sake of the Law of God, together with their wives and all their sons and daughters who are able to understand— 29 all these now join their fellow Israelites the nobles, and bind themselves with a curse and an oath(K) to follow the Law of God given through Moses the servant of God and to obey carefully all the commands, regulations and decrees of the Lord our Lord.

30 “We promise not to give our daughters in marriage to the peoples around us or take their daughters for our sons.(L)

31 “When the neighboring peoples bring merchandise or grain to sell on the Sabbath,(M) we will not buy from them on the Sabbath or on any holy day. Every seventh year we will forgo working the land(N) and will cancel all debts.(O)

32 “We assume the responsibility for carrying out the commands to give a third of a shekel[b] each year for the service of the house of our God: 33 for the bread set out on the table;(P) for the regular grain offerings and burnt offerings; for the offerings on the Sabbaths, at the New Moon(Q) feasts and at the appointed festivals; for the holy offerings; for sin offerings[c] to make atonement for Israel; and for all the duties of the house of our God.(R)

34 “We—the priests, the Levites and the people—have cast lots(S) to determine when each of our families is to bring to the house of our God at set times each year a contribution of wood(T) to burn on the altar of the Lord our God, as it is written in the Law.

35 “We also assume responsibility for bringing to the house of the Lord each year the firstfruits(U) of our crops and of every fruit tree.(V)

36 “As it is also written in the Law, we will bring the firstborn(W) of our sons and of our cattle, of our herds and of our flocks to the house of our God, to the priests ministering there.(X)

37 “Moreover, we will bring to the storerooms of the house of our God, to the priests, the first of our ground meal, of our grain offerings, of the fruit of all our trees and of our new wine and olive oil.(Y) And we will bring a tithe(Z) of our crops to the Levites,(AA) for it is the Levites who collect the tithes in all the towns where we work.(AB) 38 A priest descended from Aaron is to accompany the Levites when they receive the tithes, and the Levites are to bring a tenth of the tithes(AC) up to the house of our God, to the storerooms of the treasury. 39 The people of Israel, including the Levites, are to bring their contributions of grain, new wine and olive oil to the storerooms, where the articles for the sanctuary and for the ministering priests, the gatekeepers and the musicians are also kept.

“We will not neglect the house of our God.”(AD)

Footnotes

  1. Nehemiah 10:1 In Hebrew texts 10:1-39 is numbered 10:2-40.
  2. Nehemiah 10:32 That is, about 1/8 ounce or about 4 grams
  3. Nehemiah 10:33 Or purification offerings