Add parallel Print Page Options

Ìṣubú Ninefe

Àwọn apanirun ti dìde sí ọ, ìwọ Ninefe
    pa ilé ìṣọ́ mọ́,
    ṣọ́ ọ̀nà náà
    di àmùrè, ẹ̀gbẹ́ rẹ kí ó le,
    múra gírí.

Olúwa yóò mú ọláńlá Jakọbu padà sípò
    gẹ́gẹ́ bí ọláńlá Israẹli
bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn apanirun ti pa ibẹ̀ run,
    tí wọ́n sì ba ẹ̀ka àjàrà wọn jẹ́.

Asà àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì di pupa;
    àwọn ológun wọn sì wọ aṣọ òdòdó.
Idẹ tí ó wà lórí kẹ̀kẹ́ ogun ń kọ mọ̀nàmọ́ná
    ní ọjọ́ tí a bá pèsè wọn sílẹ̀ tán;
    igi firi ni a ó sì mì tìtì.
Àwọn kẹ̀kẹ́ ogun yóò ya bo àwọn pópónà,
    wọn yóò sì máa sáré síwá àti sẹ́yìn ní àárín ìgboro.
Wọn sì dàbí ètùfù iná;
    tí ó sì kọ bí i mọ̀nàmọ́ná.

Ninefe yóò ṣe àṣàrò àwọn ọlọ́lá rẹ̀;
    síbẹ̀ wọ́n ń kọsẹ̀ ní ojú ọ̀nà wọn;
wọn sáré lọ sí ibi odi rẹ̀,
    a ó sì pèsè ààbò rẹ̀.
A ó ṣí ìlẹ̀kùn àwọn odò wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀,
    a ó sì mú ààfin náà di wíwó palẹ̀.
A pa á láṣẹ pé ìlú náà, èyí tí a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀
    ni a ó sì kó ní ìgbèkùn lọ.
A ó sì mú un gòkè wá
    àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ yóò kérora bí ti ẹyẹ àdàbà,
    wọn a sì máa lu àyà wọn.
Ninefe dàbí adágún omi,
    tí omi rẹ̀ sì ń gbẹ́ ẹ lọ.
“Dúró! Dúró!” ni wọ́n ó máa kígbe,
    ṣùgbọ́n ẹnìkankan kì yóò wo ẹ̀yìn.
“Ẹ kó ìkógun fàdákà!
    Ẹ kó ìkógun wúrà!
Ìṣúra wọn ti kò lópin náà,
    àti ọrọ̀ kúrò nínú gbogbo ohun èlò ti a fẹ́!”
10 Òun ti ṣòfò, ó si di asán, ó sì di ahoro:
    ọkàn pami, eékún ń lu ara wọn,
    ìrora púpọ̀ sì wà nínú gbogbo ẹgbẹ́
    àti ojú gbogbo wọ́n sì rẹ̀wẹ̀sì.

11 Níbo ni ihò àwọn kìnnìún wà
    àti ibi ìjẹun àwọn ọmọ kìnnìún,
níbi tí kìnnìún, àní abo kìnnìún tí ń rìn,
    àti ọmọ kìnnìún, láìsí ohun ìbẹ̀rù
12 Kìnnìún tipa ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀,
    ó sì fún un ẹran ọdẹ ní ọrùn pa fún àwọn abo kìnnìún rẹ̀,
Ó sì fi ohun pípa kún ibùgbé rẹ̀
    àti ihò rẹ̀ fún ohun ọdẹ.

13 “Kíyèsi i èmi dojúkọ ọ́,”
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
“Èmi yóò sì fi kẹ̀kẹ́ rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jóná nínú èéfín,
    idà yóò sì jẹ ọmọ kìnnìún rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì run.
    Èmi yóò sì ké ohun ọdẹ rẹ kúrò lórí ilẹ̀ ayé
Ohùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ
    ni a kì yóò sì tún gbọ́ mọ́.”

Nineveh to Fall

[a]An attacker(A) advances against you, Nineveh.
    Guard the fortress,
    watch the road,
    brace yourselves,
    marshal all your strength!

The Lord will restore(B) the splendor(C) of Jacob
    like the splendor of Israel,
though destroyers have laid them waste
    and have ruined their vines.

The shields of the soldiers are red;
    the warriors are clad in scarlet.(D)
The metal on the chariots flashes
    on the day they are made ready;
    the spears of juniper are brandished.[b]
The chariots(E) storm through the streets,
    rushing back and forth through the squares.
They look like flaming torches;
    they dart about like lightning.

Nineveh summons her picked troops,
    yet they stumble(F) on their way.
They dash to the city wall;
    the protective shield is put in place.
The river gates(G) are thrown open
    and the palace collapses.
It is decreed[c] that Nineveh
    be exiled and carried away.
Her female slaves moan(H) like doves
    and beat on their breasts.(I)
Nineveh is like a pool
    whose water is draining away.
“Stop! Stop!” they cry,
    but no one turns back.
Plunder the silver!
    Plunder the gold!
The supply is endless,
    the wealth from all its treasures!
10 She is pillaged, plundered, stripped!
    Hearts melt,(J) knees give way,
    bodies tremble, every face grows pale.(K)

11 Where now is the lions’ den,(L)
    the place where they fed their young,
where the lion and lioness went,
    and the cubs, with nothing to fear?
12 The lion killed(M) enough for his cubs
    and strangled the prey for his mate,
filling his lairs(N) with the kill
    and his dens with the prey.(O)

13 “I am against(P) you,”
    declares the Lord Almighty.
“I will burn up your chariots in smoke,(Q)
    and the sword(R) will devour your young lions.
    I will leave you no prey on the earth.
The voices of your messengers
    will no longer be heard.”(S)

Footnotes

  1. Nahum 2:1 In Hebrew texts 2:1-13 is numbered 2:2-14.
  2. Nahum 2:3 Hebrew; Septuagint and Syriac ready; / the horsemen rush to and fro.
  3. Nahum 2:7 The meaning of the Hebrew for this word is uncertain.