Add parallel Print Page Options

Ọlọ́run pe Israẹli níjà

Ẹ fi etí sí ohun tí Olúwa wí:

“Dìde dúró, bẹ ẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ rẹ níwájú òkè ńlá;
    sì jẹ́ kí àwọn òkè kéékèèkéé gbọ́ ohun tí ó fẹ́ wí.

“Gbọ́, ìwọ òkè ńlá, ẹ̀sùn Olúwa;
    gbọ́, ìwọ ìpìlẹ̀ ilé ayérayé.
Nítorí Olúwa ń bá àwọn ènìyàn rẹ̀ wíjọ́;
    òun yóò sì bá Israẹli rojọ́.

“Ẹ̀yin ènìyàn mi, kí ni mo ṣe fún yín?
    Àti nínú kí ni mo ti dá yin lágara? Dá mi lóhùn.
Nítorí èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá,
    mo sì rà yín padà láti ilẹ̀ ẹrú wá.
Mo rán Mose láti darí yín,
    bákan náà mo rán Aaroni àti Miriamu síwájú rẹ̀.
Ìwọ ènìyàn mi,
    rántí ohun tí Balaki ọba Moabu gbèrò
    àti ohun tí Balaamu ọmọ Beori dáhùn.
Rántí ìrìnàjò rẹ̀ láti Ṣittimu dé Gilgali,
    kí ìwọ ba le mọ òdodo Olúwa.”

Kí ni èmi yóò ha mú wá síwájú Olúwa
    tí èmi ó fi tẹ ara mi ba níwájú Ọlọ́run gíga?
Kí èmi ha wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun,
    pẹ̀lú ọmọ màlúù ọlọ́dún kan?
Ǹjẹ́ Olúwa yóò ní inú dídùn sí ẹgbẹgbàarùn-ún àgbò,
    tàbí sí ẹgbẹgbàarùn-ún ìṣàn òróró?
Èmi yóò ha fi àkọ́bí mi sílẹ̀ fún ìré-òfin-kọjá mi,
    èso inú ara mi fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkàn mi?
Ó ti fihàn ọ́, ìwọ ènìyàn, ohun tí ó dára,
    àti ohun tí Olúwa ń béèrè lọ́wọ́ rẹ?
Bí kò ṣe láti ṣe òtítọ́, kí o sì fẹ́ràn àánú,
    àti kí o rìn ní ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.

Ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli àti ìjìyà wọn

Gbọ́! Ohùn Olúwa kígbe sí ìlú ńlá náà,
    láti jẹ ọlọ́gbọ́n ni láti bẹ̀rù orúkọ rẹ.
    “Ẹ kíyèsi ọ̀pá rẹ̀ gbọ́ ọ̀pá àti Ẹni náà tí ó yàn án
10 Ǹjẹ́ ìṣúra ìwà búburú ha wà
    ní ilé ènìyàn búburú síbẹ̀,
    àti òṣùwọ̀n àìkún tí ó jẹ́ ohun ìbínú?
11 Ǹjẹ́ èmi ha lè kà wọ́n sí mímọ́
    pẹ̀lú òṣùwọ̀n búburú,
    pẹ̀lú àpò òṣùwọ̀n ẹ̀tàn?
12 Àwọn ọlọ́rọ̀ inú rẹ̀ kún fún ìwà ipá;
    àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ ti ọ̀rọ̀ èké
    àti ahọ́n wọn ń sọ ẹ̀tàn?
13 Nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ ṣàìsàn ní lílù ọ́,
    láti sọ ọ́ dahoro nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.
14 Ìwọ yóò jẹun ṣùgbọ́n kì yóò yó;
    ìyàn yóò wà láàrín rẹ;
Ìwọ yóò kó pamọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò lò láìléwu,
    nítorí ohun tí ìwọ kò pamọ́ ni èmi yóò fi fún idà.
15 Ìwọ yóò gbìn ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò kórè
    ìwọ yóò tẹ olifi,
ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò fi òróró rẹ̀ kún ara rẹ;
    ìwọ yóò tẹ èso àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò mu wáìnì.
16 Nítorí tí ìwọ ti pa òfin Omri mọ́,
    àti gbogbo iṣẹ́ ilé Ahabu,
    tí ó sì ti tẹ̀lé ìmọ̀ràn wọn,
nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ fún ìparun
    àti àwọn ènìyàn rẹ fún ìfiṣe ẹlẹ́yà;
    ìwọ yóò sì ru ẹ̀gàn àwọn ènìyàn mi.”

The Lord’s Case Against Israel

Listen to what the Lord says:

“Stand up, plead my case before the mountains;(A)
    let the hills hear what you have to say.

“Hear,(B) you mountains, the Lord’s accusation;(C)
    listen, you everlasting foundations of the earth.
For the Lord has a case(D) against his people;
    he is lodging a charge(E) against Israel.

“My people, what have I done to you?
    How have I burdened(F) you?(G) Answer me.
I brought you up out of Egypt(H)
    and redeemed you from the land of slavery.(I)
I sent Moses(J) to lead you,
    also Aaron(K) and Miriam.(L)
My people, remember
    what Balak(M) king of Moab plotted
    and what Balaam son of Beor answered.
Remember your journey from Shittim(N) to Gilgal,(O)
    that you may know the righteous acts(P) of the Lord.”

With what shall I come before(Q) the Lord
    and bow down before the exalted God?
Shall I come before him with burnt offerings,
    with calves a year old?(R)
Will the Lord be pleased with thousands of rams,(S)
    with ten thousand rivers of olive oil?(T)
Shall I offer my firstborn(U) for my transgression,
    the fruit of my body for the sin of my soul?(V)
He has shown you, O mortal, what is good.
    And what does the Lord require of you?
To act justly(W) and to love mercy
    and to walk humbly[a](X) with your God.(Y)

Israel’s Guilt and Punishment

Listen! The Lord is calling to the city—
    and to fear your name is wisdom—
    “Heed the rod(Z) and the One who appointed it.[b]
10 Am I still to forget your ill-gotten treasures, you wicked house,
    and the short ephah,[c] which is accursed?(AA)
11 Shall I acquit someone with dishonest scales,(AB)
    with a bag of false weights?(AC)
12 Your rich people are violent;(AD)
    your inhabitants are liars(AE)
    and their tongues speak deceitfully.(AF)
13 Therefore, I have begun to destroy(AG) you,
    to ruin[d] you because of your sins.
14 You will eat but not be satisfied;(AH)
    your stomach will still be empty.[e]
You will store up but save nothing,(AI)
    because what you save[f] I will give to the sword.
15 You will plant but not harvest;(AJ)
    you will press olives but not use the oil,
    you will crush grapes but not drink the wine.(AK)
16 You have observed the statutes of Omri(AL)
    and all the practices of Ahab’s(AM) house;
    you have followed their traditions.(AN)
Therefore I will give you over to ruin(AO)
    and your people to derision;
    you will bear the scorn(AP) of the nations.[g]

Footnotes

  1. Micah 6:8 Or prudently
  2. Micah 6:9 The meaning of the Hebrew for this line is uncertain.
  3. Micah 6:10 An ephah was a dry measure.
  4. Micah 6:13 Or Therefore, I will make you ill and destroy you; / I will ruin
  5. Micah 6:14 The meaning of the Hebrew for this word is uncertain.
  6. Micah 6:14 Or You will press toward birth but not give birth, / and what you bring to birth
  7. Micah 6:16 Septuagint; Hebrew scorn due my people