Add parallel Print Page Options

Bíbá àwọn olórí àti àwọn wòlíì wí

Nígbà náà, ni mo wí pé,

“Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu,
    ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli.
Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.
    Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi;
Ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn
    àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;
Àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi,
    wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn.
    Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́;
Wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò,
    bí ẹran inú agbada?”

Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí Olúwa,
    Ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn.
Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn,
    nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.

Báyìí ni Olúwa wí:

“Ní ti àwọn Wòlíì
    tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà,
tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ,
    wọn yóò kéde àlàáfíà;
Ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu,
    wọn yóò múra ogun sí i.
Nítorí náà òru yóò wá sórí yín,
    tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan,
òkùnkùn yóò sì kùn fún yín,
    tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀
Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì
    ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.
Ojú yóò sì ti àwọn Wòlíì
    àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú.
Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn,
    nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
Ṣùgbọ́n ní tèmi,
    èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa,
    láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un,
    àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.

Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu,
    àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli,
tí ó kórìíra òdodo
    tí ó sì yí òtítọ́ padà;
10 Tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀,
    àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.
11 Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀,
    àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà
    àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó.
Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, wọ́n sì wí pé,
    “Nítòótọ́, Olúwa wà pẹ̀lú wa!
    Ibi kan kì yóò bá wa.”
12 Nítorí náà, nítorí tiyín,
    ni a ó ṣe ro Sioni bí oko,
Jerusalẹmu yóò sì di ebè
    àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.

Leaders and Prophets Rebuked

Then I said,

“Listen, you leaders(A) of Jacob,
    you rulers of Israel.
Should you not embrace justice,
    you who hate good and love evil;
who tear the skin from my people
    and the flesh from their bones;(B)
who eat my people’s flesh,(C)
    strip off their skin
    and break their bones in pieces;(D)
who chop(E) them up like meat for the pan,
    like flesh for the pot?(F)

Then they will cry out to the Lord,
    but he will not answer them.(G)
At that time he will hide his face(H) from them
    because of the evil they have done.(I)

This is what the Lord says:

“As for the prophets
    who lead my people astray,(J)
they proclaim ‘peace’(K)
    if they have something to eat,
but prepare to wage war against anyone
    who refuses to feed them.
Therefore night will come over you, without visions,
    and darkness, without divination.(L)
The sun will set for the prophets,(M)
    and the day will go dark for them.(N)
The seers will be ashamed(O)
    and the diviners disgraced.(P)
They will all cover(Q) their faces(R)
    because there is no answer from God.(S)
But as for me, I am filled with power,
    with the Spirit of the Lord,
    and with justice and might,
to declare to Jacob his transgression,
    to Israel his sin.(T)

Hear this, you leaders of Jacob,
    you rulers of Israel,
who despise justice
    and distort all that is right;(U)
10 who build(V) Zion with bloodshed,(W)
    and Jerusalem with wickedness.(X)
11 Her leaders judge for a bribe,(Y)
    her priests teach for a price,(Z)
    and her prophets tell fortunes for money.(AA)
Yet they look(AB) for the Lord’s support and say,
    “Is not the Lord among us?
    No disaster will come upon us.”(AC)
12 Therefore because of you,
    Zion will be plowed like a field,
Jerusalem will become a heap of rubble,(AD)
    the temple(AE) hill a mound overgrown with thickets.(AF)