Add parallel Print Page Options

Èrò ènìyàn àti ti Ọlọ́run

Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé
    tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn!
Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde
    nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.
Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n,
    àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n.
Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára
    àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.

Nítorí náà, Olúwa wí pé:

“Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí,
    nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là.
Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́,
    nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.
Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín;
    wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé:
‘Ní kíkó a ti kó wọn tán;
    Olúwa ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi;
Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi!
    Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’ ”

Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ Olúwa,
    tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.

Àwọn wòlíì èké

“Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn Wòlíì wọn wí.
    “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí;
    kí ìtìjú má ṣe le bá wa”
Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu:
    “Ǹjẹ́ ẹ̀mí Olúwa ha ń bínú bí?
    Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?”

“Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere
    fún ẹni tí ń rìn déédé bí?
Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde
    bí ọ̀tá sí mi.
Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀
    kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu,
    bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.
Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi
    kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn,
ẹ̀yin sì ti gba ògo mi,
    kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.
10 Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ!
    Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín,
nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́
    yóò pa yín run,
    àní ìparun kíkorò.
11 Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé,
    ‘Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,’
    òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!

Ìlérí ìgbàlà

12 “Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu;
    Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ.
Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran,
    gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn,
    ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
13 Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn;
    wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ.
Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn,
    Olúwa ni yóò sì ṣe olórí wọn.”

Human Plans and God’s Plans

Woe to those who plan iniquity,
    to those who plot evil(A) on their beds!(B)
At morning’s light they carry it out
    because it is in their power to do it.
They covet fields(C) and seize them,(D)
    and houses, and take them.
They defraud(E) people of their homes,
    they rob them of their inheritance.(F)

Therefore, the Lord says:

“I am planning disaster(G) against this people,
    from which you cannot save yourselves.
You will no longer walk proudly,(H)
    for it will be a time of calamity.
In that day people will ridicule you;
    they will taunt you with this mournful song:
‘We are utterly ruined;(I)
    my people’s possession is divided up.(J)
He takes it from me!
    He assigns our fields to traitors.’”

Therefore you will have no one in the assembly of the Lord
    to divide the land(K) by lot.(L)

False Prophets

“Do not prophesy,” their prophets say.
    “Do not prophesy about these things;
    disgrace(M) will not overtake us.(N)
You descendants of Jacob, should it be said,
    “Does the Lord become[a] impatient?
    Does he do such things?”

“Do not my words do good(O)
    to the one whose ways are upright?(P)
Lately my people have risen up
    like an enemy.
You strip off the rich robe
    from those who pass by without a care,
    like men returning from battle.
You drive the women of my people
    from their pleasant homes.(Q)
You take away my blessing
    from their children forever.
10 Get up, go away!
    For this is not your resting place,(R)
because it is defiled,(S)
    it is ruined, beyond all remedy.
11 If a liar and deceiver(T) comes and says,
    ‘I will prophesy for you plenty of wine and beer,’(U)
    that would be just the prophet for this people!(V)

Deliverance Promised

12 “I will surely gather all of you, Jacob;
    I will surely bring together the remnant(W) of Israel.
I will bring them together like sheep in a pen,
    like a flock in its pasture;
    the place will throng with people.(X)
13 The One who breaks open the way will go up before(Y) them;
    they will break through the gate(Z) and go out.
Their King will pass through before them,
    the Lord at their head.”

Footnotes

  1. Micah 2:7 Or Is the Spirit of the Lord