Add parallel Print Page Options

Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.

Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn,
    fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,
Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín,
    (A)Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.

Ìdájọ́ tí o lòdì sí Samaria àti Jerusalẹmu

Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀;
    yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀,
    àwọn Àfonífojì yóò sì pínyà,
bí idà níwájú iná,
    bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí,
    àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli.
Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu?
    Ǹjẹ́ Samaria ha kọ?
Kí ni àwọn ibi gíga Juda?
    Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?

“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá,
    bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà.
Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì.
    Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́
    gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun:
    Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run.
Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà,
    gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”

Ẹkún òun ọfọ̀

Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún,
    èmi yóò sì pohùnréré ẹkún:
èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò
    Èmi yóò ké bí akátá,
    èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán;
    ó sì ti wá sí Juda.
Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi,
    àní sí Jerusalẹmu.
10 Ẹ má ṣe sọ ní Gati
    ẹ má ṣe sọkún rárá.
Ní ilẹ̀ Beti-Ofra
    mo yí ara mi nínú eruku.
11 Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú,
    ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri.
Àwọn tí ó ń gbé ni Ṣaanani
    kì yóò sì jáde wá.
Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀;
    A ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
12 Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre,
    Ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
13 Ìwọ olùgbé Lakiṣi,
    dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára.
Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀
    sí àwọn ọmọbìnrin Sioni,
    nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
14 Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀
    fún Moreṣeti Gati.
Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
15 Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa.
    Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli
    yóò sì wá sí Adullamu.
16 Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀
    nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára,
sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún,
    nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.

The word of the Lord that came to Micah of Moresheth(A) during the reigns of Jotham,(B) Ahaz(C) and Hezekiah,(D) kings of Judah(E)—the vision(F) he saw concerning Samaria and Jerusalem.

Hear,(G) you peoples, all of you,(H)
    listen, earth(I) and all who live in it,
that the Sovereign Lord may bear witness(J) against you,
    the Lord from his holy temple.(K)

Judgment Against Samaria and Jerusalem

Look! The Lord is coming from his dwelling(L) place;
    he comes down(M) and treads on the heights of the earth.(N)
The mountains melt(O) beneath him(P)
    and the valleys split apart,(Q)
like wax before the fire,
    like water rushing down a slope.
All this is because of Jacob’s transgression,
    because of the sins of the people of Israel.
What is Jacob’s transgression?
    Is it not Samaria?(R)
What is Judah’s high place?
    Is it not Jerusalem?

“Therefore I will make Samaria a heap of rubble,
    a place for planting vineyards.(S)
I will pour her stones(T) into the valley
    and lay bare her foundations.(U)
All her idols(V) will be broken to pieces;(W)
    all her temple gifts will be burned with fire;
    I will destroy all her images.(X)
Since she gathered her gifts from the wages of prostitutes,(Y)
    as the wages of prostitutes they will again be used.”

Weeping and Mourning

Because of this I will weep(Z) and wail;
    I will go about barefoot(AA) and naked.
I will howl like a jackal
    and moan like an owl.
For Samaria’s plague(AB) is incurable;(AC)
    it has spread to Judah.(AD)
It has reached the very gate(AE) of my people,
    even to Jerusalem itself.
10 Tell it not in Gath[a];
    weep not at all.
In Beth Ophrah[b]
    roll in the dust.
11 Pass by naked(AF) and in shame,
    you who live in Shaphir.[c]
Those who live in Zaanan[d]
    will not come out.
Beth Ezel is in mourning;
    it no longer protects you.
12 Those who live in Maroth[e] writhe in pain,
    waiting for relief,(AG)
because disaster(AH) has come from the Lord,
    even to the gate of Jerusalem.
13 You who live in Lachish,(AI)
    harness fast horses to the chariot.
You are where the sin of Daughter Zion(AJ) began,
    for the transgressions of Israel were found in you.
14 Therefore you will give parting gifts(AK)
    to Moresheth(AL) Gath.
The town of Akzib[f](AM) will prove deceptive(AN)
    to the kings of Israel.
15 I will bring a conqueror against you
    who live in Mareshah.[g](AO)
The nobles of Israel
    will flee to Adullam.(AP)
16 Shave(AQ) your head in mourning
    for the children in whom you delight;
make yourself as bald as the vulture,
    for they will go from you into exile.(AR)

Footnotes

  1. Micah 1:10 Gath sounds like the Hebrew for tell.
  2. Micah 1:10 Beth Ophrah means house of dust.
  3. Micah 1:11 Shaphir means pleasant.
  4. Micah 1:11 Zaanan sounds like the Hebrew for come out.
  5. Micah 1:12 Maroth sounds like the Hebrew for bitter.
  6. Micah 1:14 Akzib means deception.
  7. Micah 1:15 Mareshah sounds like the Hebrew for conqueror.