Add parallel Print Page Options

Ìbẹ̀wò àwọn amòye

(A)Lẹ́yìn ìgbà tí a bí Jesu ní Bẹtilẹhẹmu ti Judea, ni àkókò ọba Herodu, àwọn amòye ti ìlà-oòrùn wá sí Jerusalẹmu. (B)Wọ́n si béèrè pé, “Níbo ni ẹni náà tí a bí tí í ṣe ọba àwọn Júù wà? Àwa ti rí ìràwọ̀ rẹ̀ ní ìlà-oòrùn, a sì wá láti foríbalẹ̀ fún un.”

Nígbà tí ọba Herodu sì gbọ́ èyí, ìdààmú bá a àti gbogbo àwọn ara Jerusalẹmu pẹ̀lú rẹ̀ Nígbà tí ó sì pe àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin jọ, ó bi wọ́n léèrè níbi ti a ó gbé bí Kristi? (C)Wọ́n sì wí pé, “Ní Bẹtilẹhẹmu ti Judea, èyí ni ohun tí wòlíì ti kọ ìwé rẹ̀ pé:

(D)“ ‘Ṣùgbọ́n ìwọ Bẹtilẹhẹmu, ní ilẹ̀ Judea,
    ìwọ kò kéré jù láàrín àwọn ọmọ-aládé Juda;
nítorí láti inú rẹ ni Baálẹ̀ kan yóò ti jáde,
    Ẹni ti yóò ṣe ìtọ́jú Israẹli, àwọn ènìyàn mi.’ ”

Nígbà náà ni Herodu ọba pe àwọn amòye náà sí ìkọ̀kọ̀, ó sì wádìí ni ọwọ́ wọn, àkókò náà gan an tí wọ́n kọ́kọ́ rí ìràwọ̀. Ó sì rán wọn lọ sí Bẹtilẹhẹmu, ó sì wí pé, “Ẹ lọ ṣe ìwádìí fínní fínní ní ti ọmọ náà tí a bí. Lẹ́yìn tí ẹ bá sì rí i, ẹ padà wá sọ fún mi, kí èmi náà le lọ foríbalẹ̀ fún un.”

Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ọba, wọ́n mú ọ̀nà wọn pọ̀n, sì wò ó, ìràwọ̀ tí wọ́n ti rí láti ìhà ìlà-oòrùn wá, ó ṣáájú wọn, títí tí ó fi dúró lókè ibi tí ọmọ náà gbé wà. 10 Nígbà tí wọ́n sì rí ìràwọ̀ náà, ayọ̀ kún ọkàn wọn. 11 (E)Bí wọ́n tí wọ inú ilé náà, wọn rí ọmọ ọwọ́ náà pẹ̀lú Maria ìyá rẹ̀, wọ́n wólẹ̀, wọ́n foríbalẹ̀ fún un. Nígbà náà ni wọ́n tú ìṣúra wọn, wọ́n sì ta Jesu lọ́rẹ: wúrà, tùràrí àti òjìá. 12 (F)Nítorí pé Ọlọ́run ti kìlọ̀ fún wọn ní ojú àlá pé kí wọ́n má ṣe padà tọ Herodu lọ mọ́, wọ́n gba ọ̀nà mìíràn lọ sí ìlú wọn.

A gbé Jesu sálọ sì Ejibiti

13 Nígbà tí wọn ti lọ, angẹli Olúwa fi ara hàn Josẹfu ní ojú àlá pé, “Dìde, gbé ọmọ ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀, kí ó sì sálọ sí Ejibiti. Dúró níbẹ̀ títí tí èmi yóò fi sọ fún ọ, nítorí Herodu yóò wá ọ̀nà láti pa ọmọ ọwọ́ náà.”

14 Nígbà náà ni ó sì dìde, ó mú ọmọ ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀ ní òru, ó sì lọ sí Ejibiti, 15 (G)ó sì wà níbẹ̀ títí tí Herodu fi kú. Èyí jẹ́ ìmúṣẹ àsọtẹ́lẹ̀ ohun tí Olúwa sọ láti ẹnu wòlíì pé: “Mo pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.”

16 Nígbà tí Herodu rí í pé àwọn amòye náà ti tan òun jẹ, ó bínú gidigidi, ó sì pàṣẹ kí a pa gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí ó wà ní Bẹtilẹhẹmu àti ní ẹkùn rẹ̀ láti àwọn ọmọ ọdún méjì sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àkókò tí ó ti fi ẹ̀sọ̀ ẹ̀sọ̀ béèrè lọ́wọ́ àwọn amòye náà. 17 Nígbà náà ni èyí tí a ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu wòlíì Jeremiah wá ṣẹ pé:

18 (H)“A gbọ́ ohùn kan ní Rama,
    ohùn réré ẹkún àti ọ̀fọ̀ ńlá,
Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀.
    Ó kọ̀ láti gbìpẹ̀
nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”

Ìpadà sí Nasareti

19 (I)Lẹ́yìn ikú Herodu, angẹli Olúwa fi ara hàn Josẹfu lójú àlá ní Ejibiti 20 Ó sì wí fún un pé, “Dìde gbé ọmọ ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀ padà sí ilẹ̀ Israẹli, nítorí àwọn tí ń wá ẹ̀mí ọmọ ọwọ́ náà láti pa ti kú.”

21 Nítorí náà, o sì dìde, ó gbé ọmọ ọwọ́ náà àti ìyá rẹ̀ ó sì wá sí ilẹ̀ Israẹli. 22 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó gbọ́ pé Akelausi ni ó ń jẹ ọba ní Judea ní ipò Herodu baba rẹ̀, ó bẹ̀rù láti lọ sí ì bẹ̀. Nítorí tí Ọlọ́run ti kìlọ̀ fún un ní ojú àlá, ó yí padà, ó sì gba ẹkùn Galili lọ, 23 (J)ó sì lọ í gbé ní ìlú tí a pè ní Nasareti. Nígbà náà ni èyí tí a sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì wá sí ìmúṣẹ: “A ó pè é ní ará Nasareti.”

Wise Men Visit Jesus

Now after[a] Jesus was born in Bethlehem of Judea in the days of Herod the king, behold, wise men from the east came to Jerusalem, saying, “Where is the one who has been born king of the Jews? For we have seen his star at its rising[b] and have come to worship him.” And when[c] King Herod heard it,[d] he was troubled, and all Jerusalem with him, and after[e] calling together all the chief priests and scribes of the people, he inquired from them where the Christ was to be born. So they said to him, “In Bethlehem of Judea, for thus it is written by the prophet,

‘And you, Bethlehem, land of Judah,
    are by no means least among the rulers of Judah,
for from you will go out a ruler
    who will shepherd my people Israel.’”[f]

Then Herod secretly summoned the wise men and[g] determined precisely from them the time when[h] the star appeared. And he sent them to Bethlehem and[i] said, “Go, inquire carefully concerning the child, and when you have found him, report to me so that I also may come and[j] worship him.” After[k] they listened to the king, they went out, and behold, the star which they had seen at its rising[l] led them until it came and[m] stood above the place where the child was. 10 Now when they[n] saw the star, they rejoiced with very great joy. 11 And when they[o] came into the house, they saw the child with Mary his mother, and they fell down and[p] worshiped him. And opening their treasure boxes, they offered him gifts of gold and frankincense and myrrh. 12 And being warned in a dream not to return to Herod, they went back to their own country by another route.

Joseph, Mary, and Jesus Escape to Egypt

13 Now after they had gone away, behold, an angel of the Lord appeared in a dream to Joseph, saying, “Get up, take the child and his mother and flee to Egypt, and stay there until I tell you. For Herod is about to seek the child to destroy him.” 14 So he got up and[q] took the child and his mother during the night and went away to Egypt. 15 And he was there until the death of Herod, in order that what was said by the Lord through the prophet would be fulfilled, saying,

“Out of Egypt I called my son.”

Herod Has Innocent Children Murdered

16 Then Herod, when he[r] saw that he had been deceived by the wise men, became very angry, and he sent soldiers[s] and[t] executed all the children in Bethlehem and in all the region around it from the age of two years old and under, according to the time which he had determined precisely from the wise men. 17 Then what was spoken by the prophet Jeremiah was fulfilled, saying,

18 “A voice was heard in Ramah,
    weeping and great mourning,
Rachel weeping for her children,
    and she did not want to be comforted,
because they exist no longer[u].”[v]

Joseph, Mary, and Jesus Return to Nazareth

19 Now after[w] Herod had died, behold, an angel of the Lord appeared in a dream to Joseph in Egypt, 20 saying, “Get up, take the child and his mother and go to the land of Israel, for those who were seeking the life of the child are dead.” 21 So he got up and[x] took the child and his mother and entered[y] the land of Israel. 22 But when he[z] heard that Archelaus was reigning over Judea in place of his father Herod, he was afraid to go there, and being warned in a dream, he took refuge in the regions of Galilee. 23 And he came and[aa] lived in a town called Nazareth, in order that what was said by the prophets would be fulfilled:[ab] “He will be called a Nazarene.”

Footnotes

  1. Matthew 2:1 Here “after” is supplied as a component of the temporal genitive absolute participle (“was born”)
  2. Matthew 2:2 Or, “when it rose”; traditionally rendered “in the east” by many English versions
  3. Matthew 2:3 Here “when” is supplied as a component of the participle (“heard”) which is understood as temporal
  4. Matthew 2:3 *Here the direct object is supplied from context in the English translation
  5. Matthew 2:4 Here “after” is supplied as a component of the participle (“calling together”) which is understood as temporal
  6. Matthew 2:6 A quotation from Mic 5:2
  7. Matthew 2:7 Here “and” is supplied because the previous participle (“summoned”) has been translated as a finite verb
  8. Matthew 2:7 Here “when” is supplied as a component of the temporal genitive absolute participle (“appeared”)
  9. Matthew 2:8 Here “and” is supplied because the previous participle (“sent”) has been translated as a finite verb
  10. Matthew 2:8 Here “and” is supplied because the previous participle (“may come”) has been translated as a finite verb
  11. Matthew 2:9 Here “after” is supplied as a component of the participle (“listened to”) which is understood as temporal
  12. Matthew 2:9 Or, “when it rose”; traditionally rendered “in the east” by many English versions
  13. Matthew 2:9 Here “and” is supplied because the previous participle (“came”) has been translated as a finite verb
  14. Matthew 2:10 Here “when” is supplied as a component of the participle (“saw”) which is understood as temporal
  15. Matthew 2:11 Here “when” is supplied as a component of the participle (“came”) which is understood as temporal
  16. Matthew 2:11 Here “and” is supplied because the previous participle (“fell down”) has been translated as a finite verb
  17. Matthew 2:14 Here “and” is supplied because the previous participle (“got up”) has been translated as a finite verb
  18. Matthew 2:16 Here “when” is supplied as a component of the participle (“saw”) which is understood as temporal
  19. Matthew 2:16 Here the direct object is supplied from context in the English translation
  20. Matthew 2:16 Here “and” is supplied because the previous participle (“sent”) has been translated as a finite verb
  21. Matthew 2:18 Literally “they are not”
  22. Matthew 2:18 A quotation from Jer 31:15
  23. Matthew 2:19 Here “after” is supplied as a component of the temporal genitive absolute participle (“had died”)
  24. Matthew 2:21 Here “and” is supplied because the previous participle (“got up”) has been translated as a finite verb
  25. Matthew 2:21 Literally “entered into”
  26. Matthew 2:22 Here “when” is supplied as a component of the participle (“heard”) which is understood as temporal
  27. Matthew 2:23 Here “and” is supplied because the previous participle (“came”) has been translated as a finite verb
  28. Matthew 2:23 Literally “that”; the conjunction could be understood (1) to introduce a direct quotation, serving a function similar to modern English quotation marks, and thus not translated; or (2) to introduce an indirect quotation, in which case it could be translated “that he would be called a Nazarene”