Add parallel Print Page Options

Òróró òun àkàrà tí a tẹ́ síwájú Olúwa

24 (A)Olúwa sọ fún Mose pé “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli láti mú òróró tí ó mọ́ tí a fún láti ara olifi wá láti fi tan iná, kí fìtílà lè máa jò láì kú. Lẹ́yìn aṣọ ìkélé ti ibi àpótí ẹ̀rí tí ó wà ní inú àgọ́ ìpàdé, ni kí Aaroni ti tan iná náà níwájú Olúwa, láti ìrọ̀lẹ́ di àárọ̀ lójoojúmọ́. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀. Àwọn Àtùpà tí wọ́n wà lórí ojúlówó ọ̀pá fìtílà tí a fi wúrà ṣe níwájú Olúwa ni kí ó máa jó lójoojúmọ́.

(B)“Mú ìyẹ̀fun dáradára, kí o sì ṣe ìṣù àkàrà méjìlá, kí o lo ìdá méjì nínú mẹ́wàá òṣùwọ̀n efa (èyí jẹ́ lítà mẹ́rin ààbọ̀) fún ìṣù kọ̀ọ̀kan. Tò wọ́n sí ọ̀nà ìlà méjì, mẹ́fàmẹ́fà ní ìlà kọ̀ọ̀kan lórí tábìlì tí a fi ojúlówó wúrà bọ̀. Èyí tí ó wà níwájú Olúwa. Ẹ fi ojúlówó tùràrí sí ọnà kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ìpín ìrántí láti dípò àkàrà, àti láti jẹ ẹbọ sísun sí Olúwa. Àkàrà yìí ni kí ẹ gbé wá síwájú Olúwa nígbàkúgbà, lọ́ṣọ̀ọ̀ṣẹ̀, nítorí tí àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí májẹ̀mú ayérayé. Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ló ni í. Wọ́n gbọdọ̀ jẹ ẹ́ ní ibi mímọ́ torí pé ó jẹ́ ipa tí ó mọ́ jùlọ ti ìpín wọn ojoojúmọ́ nínú ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.”

Ìṣọ̀rọ̀-òdì àti ìjìyà rẹ̀

10 Ọmọkùnrin kan wà tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọ Israẹli baba rẹ̀ sì jẹ́ ará Ejibiti. Ó jáde lọ láàrín àwọn ọmọ Israẹli, ìjà sì ṣẹlẹ̀ nínú àgọ́ láàrín òun àti ọmọ Israẹli kan. 11 Ọmọkùnrin arábìnrin Israẹli náà sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa pẹ̀lú èpè: Wọ́n sì mú un tọ Mose wá. (Orúkọ ìyá rẹ̀ ní Ṣelomiti, ọmọbìnrin Debiri, ti ẹ̀yà Dani). 12 Wọ́n fi í sínú túbú kí Olúwa to sọ ohun tí wọn yóò ṣe fún wọn.

13 Olúwa sì sọ fún Mose pé: 14 “Mú asọ̀rọ̀-òdì náà jáde wá sẹ́yìn àgọ́, kí gbogbo àwọn tí ó gbọ́ pé ó ṣépè gbé ọwọ́ wọn lórí ọkùnrin náà láti fihàn pé ó jẹ̀bi. Lẹ́yìn náà ni kí gbogbo àpéjọpọ̀, sọ ọ́ ní òkúta pa. 15 Sọ fún àwọn ará Israẹli pé: ‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣépè lé Ọlọ́run rẹ̀, yóò jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. 16 Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa ni kí ẹ pa, kí gbogbo àpéjọpọ̀ sọ ọ́ ní òkúta pa, yálà àlejò ni tàbí ọmọ bíbí Israẹli, bí ó bá ti sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa, pípa ni kí ẹ pa á.

17 “ ‘Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ènìyàn pípa ni kí ẹ pa á. 18 Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ẹran ọ̀sìn ẹlòmíràn, kí ó dá a padà—ẹ̀mí dípò ẹ̀mí. 19 (C)Bí ẹnìkan bá pa ẹnìkejì rẹ̀ lára: ohunkóhun tí ó ṣe ni kí ẹ ṣe sí i. 20 Ẹ̀yà fún ẹ̀yà, ojú fún ojú, eyín fún eyín; bí òun ti ṣe àbùkù sí ara ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni kí a ṣe sí i. 21 Ẹni tí ó bá sì lu ẹran pa, kí ó sán an padà; ẹni tí ó bá sì lu ènìyàn pa, a ó pa á. 22 (D)Òfin kan náà ló wà fún àlejò àti fún ọmọ Israẹli. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’ ”

23 Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì mú asọ̀rọ̀-òdì náà lọ sí ẹ̀yìn àgọ́: wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa. Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose.

Olive Oil and Bread Set Before the Lord(A)

24 The Lord said to Moses, “Command the Israelites to bring you clear oil of pressed olives for the light so that the lamps may be kept burning continually. Outside the curtain that shields the ark of the covenant law in the tent of meeting, Aaron is to tend the lamps before the Lord from evening till morning, continually. This is to be a lasting ordinance(B) for the generations to come. The lamps on the pure gold lampstand(C) before the Lord must be tended continually.

“Take the finest flour and bake twelve loaves of bread,(D) using two-tenths of an ephah[a](E) for each loaf. Arrange them in two stacks, six in each stack, on the table of pure gold(F) before the Lord. By each stack put some pure incense(G) as a memorial[b] portion(H) to represent the bread and to be a food offering presented to the Lord. This bread is to be set out before the Lord regularly,(I) Sabbath after Sabbath,(J) on behalf of the Israelites, as a lasting covenant. It belongs to Aaron and his sons,(K) who are to eat it in the sanctuary area,(L) because it is a most holy(M) part of their perpetual share of the food offerings presented to the Lord.”

A Blasphemer Put to Death

10 Now the son of an Israelite mother and an Egyptian father went out among the Israelites, and a fight broke out in the camp between him and an Israelite. 11 The son of the Israelite woman blasphemed the Name(N) with a curse;(O) so they brought him to Moses.(P) (His mother’s name was Shelomith, the daughter of Dibri the Danite.)(Q) 12 They put him in custody until the will of the Lord should be made clear to them.(R)

13 Then the Lord said to Moses: 14 “Take the blasphemer outside the camp. All those who heard him are to lay their hands on his head, and the entire assembly is to stone him.(S) 15 Say to the Israelites: ‘Anyone who curses their God(T) will be held responsible;(U) 16 anyone who blasphemes(V) the name of the Lord is to be put to death.(W) The entire assembly must stone them. Whether foreigner or native-born, when they blaspheme the Name they are to be put to death.

17 “‘Anyone who takes the life of a human being is to be put to death.(X) 18 Anyone who takes the life of someone’s animal must make restitution(Y)—life for life. 19 Anyone who injures their neighbor is to be injured in the same manner: 20 fracture for fracture, eye for eye, tooth for tooth.(Z) The one who has inflicted the injury must suffer the same injury. 21 Whoever kills an animal must make restitution,(AA) but whoever kills a human being is to be put to death.(AB) 22 You are to have the same law for the foreigner(AC) and the native-born.(AD) I am the Lord your God.’”

23 Then Moses spoke to the Israelites, and they took the blasphemer outside the camp and stoned him.(AE) The Israelites did as the Lord commanded Moses.

Footnotes

  1. Leviticus 24:5 That is, probably about 7 pounds or about 3.2 kilograms
  2. Leviticus 24:7 Or representative