Add parallel Print Page Options

Ọjọ́ ètùtù ìwẹ̀nùmọ́ ẹ̀ṣẹ̀

16 Olúwa sọ fún Mose lẹ́yìn ikú àwọn ọmọ Aaroni méjèèjì tí wọ́n kú nígbà tí wọ́n súnmọ́ Olúwa. (A)Olúwa sì sọ fún Mose pé “Kìlọ̀ fún Aaroni arákùnrin rẹ pé kí ó má ṣe máa wá nígbà gbogbo sí ibi mímọ́ jùlọ tí ó wà lẹ́yìn aṣọ títa ní ibi tí àpótí ẹ̀rí àti ìtẹ́ àánú wà, kí ó má ba à kú” nítorí pé Èmi ó farahàn nínú ìkùùkuu lórí ìtẹ́ àánú.

(B)Báyìí ni Aaroni yóò ṣe máa wá sí ibi mímọ́ pẹ̀lú ọ̀dọ́ akọ màlúù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti àgbò fún ẹbọ sísun. Òun yóò sì wọ aṣọ funfun mímọ́ pẹ̀lú àwọ̀tẹ́lẹ̀ funfun, yóò sì fi àmùrè funfun mímọ́ dì í: yóò sì dé fìlà funfun: àwọn aṣọ mímọ́ nìwọ̀nyí: Òun yóò sì fi omi wẹ̀, kí ó tó wọ̀ wọ́n. Òun yóò sì mú ọmọ ewúrẹ́ méjì láti ọ̀dọ̀ gbogbo àgbájọpọ̀ àwọn ọmọ Israẹli láti fi ṣe ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ wọ́n: àti àgbò kan fún ẹbọ sísun.

Aaroni yóò sì fi akọ màlúù rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ èyí tí ṣe ti ara rẹ̀ òun yóò sì ṣe ètùtù fún ara rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀. Lẹ́yìn náà yóò sì mú ewúrẹ́ méjì náà wá sí iwájú Olúwa ní ibi ìlẹ̀kùn àgọ́ ìpàdé. Aaroni yóò sì dìbò ní ti àwọn ewúrẹ́ méjèèjì náà, ìbò àkọ́kọ́ fún ti Olúwa, àti èkejì fún ewúrẹ́ ìpààrọ̀. Aaroni yóò sì mú ewúrẹ́ tí ìbò Ọlọ́run mú, yóò sì fi rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. 10 Ṣùgbọ́n ewúrẹ́ tí ìbò bá mú gẹ́gẹ́ bí ewúrẹ́ ìpààrọ̀ ni a ó mú wá láààyè síwájú Olúwa láti fi ṣe ètùtù sí i àti láti jẹ́ kí ó lọ lọ́fẹ̀ẹ́, sí aginjù.

Ètùtù fún olórí àlùfáà

11 Aaroni yóò sì mú akọ màlúù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ wá láti ṣe ètùtù fún ara rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀. Yóò sì pa akọ màlúù náà fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tirẹ̀. 12 Yóò sì mú àwo tùràrí tí ó kún fún èédú tí a ti sun pẹ̀lú iná láti orí pẹpẹ wá síwájú Olúwa: àti ẹ̀kúnwọ́ méjì tùràrí tí a gún kúnná yóò sì mú un wá sí ẹ̀yìn aṣọ títa. 13 Yóò sì fi tùràrí náà lé orí iná níwájú Olúwa: kí èéfín tùràrí náà ba à le bo ìtẹ́ àánú tí ó wà ní orí àpótí ẹ̀rí kí o má ba à kú. 14 Yóò sì mú nínú ẹ̀jẹ̀ ọmọ màlúù náà yóò sì fi ìka rẹ̀ wọ́n ọn, ní iwájú ìtẹ́ àánú, yóò sì fi ìka rẹ̀ wọ́n ọn nígbà méje níwájú ìtẹ́ àánú.

Ètùtù fún àwọn ènìyàn

15 (C)Nígbà yìí ni yóò pa ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó wà fún àwọn ènìyàn yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wá sí ẹ̀yìn aṣọ títa, bí ó ti ṣe ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù náà ni yóò ṣe ti ewúrẹ́ yìí, yóò sì wọ́n ọn sórí ìtẹ́ ètùtù àti síwájú ìtẹ́ ètùtù. 16 Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún ibi mímọ́ jùlọ nítorí àìmọ́ àwọn ará Israẹli àti nítorí gbogbo ìrékọjá wọn àti ìṣọ̀tẹ̀ wọn nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn gbogbo, bákan náà ni yóò sì ṣe fún àgọ́ ìpàdé, èyí tí ó wà láàrín wọn nínú àìmọ́ wọn. 17 Kí ó má ṣe sí ẹyọ ènìyàn kan nínú àgọ́ ìpàdé nígbà tí òun bá wọ ibi mímọ́ lọ láti ṣe ètùtù: títí di ìgbà tí yóò fi jáde lẹ́yìn tí ó ba ṣe ètùtù fúnrarẹ̀ fún ìdílé rẹ̀ àti fún gbogbo àgbájọpọ̀ Israẹli.

18 Lẹ́yìn náà òun yóò lọ sí ibi pẹpẹ tí ó wà níwájú Olúwa: yóò sì ṣe ètùtù fún pẹpẹ náà. Yóò sì mú nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù àti nínú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ náà, yóò sì fi sí orí ọ̀kọ̀ọ̀kan ìwo pẹpẹ náà yíká. 19 Lẹ́yìn náà, òun yóò wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà sórí rẹ̀ pẹ̀lú ìka rẹ̀ nígbà méje láti wẹ̀ ẹ́ mọ́ àti láti sọ ọ́ dí mímọ́ kúrò nínú àìmọ́ àwọn ọmọ Israẹli.

20 Lẹ́yìn ti Aaroni ti parí ṣíṣe ètùtù ti ibi mímọ́ jùlọ, ti àgọ́ ìpàdé àti ti pẹpẹ: òun yóò sì mú ààyè ewúrẹ́ wá. 21 Aaroni yóò sì gbé ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì lé orí ààyè ewúrẹ́ náà, yóò sì jẹ́wọ́ gbogbo ìwà búburú àti ìṣọ̀tẹ̀ àwọn ara Israẹli lé e lórí: gbogbo ìrékọjá wọn àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn ni yóò sì gbé ka orí ewúrẹ́ náà. Yóò sì rán an lọ sí ijù láti ọwọ́ ẹni tí a yàn fún iṣẹ́ náà. 22 Ewúrẹ́ náà yóò sì ru gbogbo àìṣedéédéé wọn lọ sí ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé. Òun yóò sì jọ̀wọ́ ewúrẹ́ náà lọ́wọ́ lọ sínú ijù.

23 (D)Aaroni yóò sì padà wá sí ibi àgọ́ ìpàdé, yóò sì bọ́ aṣọ ọ̀gbọ̀ wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀, tí ó wọ̀ nígbà tí ó lọ sí ibi mímọ́ jùlọ, yóò sì fi wọ́n sílẹ̀ níbẹ̀ 24 Yóò sì fi omi wẹ ara rẹ̀ ní ibi mímọ́ kan: yóò sì wọ aṣọ rẹ̀ yóò sì wá ṣí iwájú: yóò sì rú ẹbọ sísun ti ara rẹ̀ àti ẹbọ sísun ti àwọn ènìyàn láti ṣe ètùtù fún ara rẹ̀ àti fún àwọn ènìyàn: 25 Òun yóò sì sun ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà lórí pẹpẹ.

26 Ẹni tí ó tú ewúrẹ́ ìpààrọ̀ náà sílẹ̀ yóò sì fọ aṣọ rẹ̀: yóò sì wẹ ara rẹ̀ nínú omi: lẹ́yìn èyí ó lè wá sí ibùdó. 27 (E)Ọ̀dọ́ akọ màlúù àti ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tí a ti mú ẹ̀jẹ̀ wọn wá sí ibi mímọ́ jùlọ ni kí a gbe jáde kúrò ní ibùdó. Awọ wọn ni a ó fi iná sun bákan náà. 28 Ẹni tí ó sun wọ́n yóò sì fọ aṣọ rẹ̀: yóò sì wẹ ara rẹ̀: lẹ́yìn èyí ni ó tó le wọ ibùdó.

29 (F)Èyí ni yóò jẹ́ ìlànà títí láé fún un yín: pé ní ọjọ́ kẹwàá oṣù keje ni ẹ gbọdọ̀ ṣẹ́ ara yín: kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ kankan, yálà onílé tàbí àlejò tí ó ń gbé pẹ̀lú yín. 30 Torí pé ní ọjọ́ yìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún yín láti sọ yín di mímọ́: kí ẹ̀yin bá à le mọ́ níwájú Olúwa yín kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín gbogbo. 31 Ọjọ́ yìí yóò jẹ́ ọjọ́ ìsinmi pátápátá fún un yín: ẹ̀yin yóò sì ṣẹ́ ara yín: Èyí yóò sì jẹ́ ìlànà títí láé. 32 Àlùfáà náà tí a ti fi òróró yàn tí a sì ti sọ di mímọ́ láti máa ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ilé ìsìn ní ipò baba rẹ̀: òun ni kí ó ṣe ètùtù: yóò sì wọ aṣọ funfun gbòò àní aṣọ mímọ́ náà: òun yóò sì ṣe ètùtù. 33 Yóò sì ṣe ètùtù fún àgọ́ ìpàdé àti fún pẹpẹ: yóò sì ṣe ètùtù fún àlùfáà àti fún gbogbo àgbájọpọ̀ àwọn ènìyàn náà.

34 “Èyí ni yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún yín: láti máa ṣe ètùtù fún àwọn ará Israẹli fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wọn lẹ́ẹ̀kan lọ́dún.”

Ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

The Day of Atonement(A)

16 The Lord spoke to Moses after the death of the two sons of Aaron who died when they approached the Lord.(B) The Lord said to Moses: “Tell your brother Aaron that he is not to come whenever he chooses(C) into the Most Holy Place(D) behind the curtain(E) in front of the atonement cover(F) on the ark, or else he will die. For I will appear(G) in the cloud(H) over the atonement cover.

“This is how Aaron is to enter the Most Holy Place:(I) He must first bring a young bull(J) for a sin offering[a] and a ram for a burnt offering.(K) He is to put on the sacred linen tunic,(L) with linen undergarments next to his body; he is to tie the linen sash around him and put on the linen turban.(M) These are sacred garments;(N) so he must bathe himself with water(O) before he puts them on.(P) From the Israelite community(Q) he is to take two male goats(R) for a sin offering and a ram for a burnt offering.

“Aaron is to offer the bull for his own sin offering to make atonement for himself and his household.(S) Then he is to take the two goats and present them before the Lord at the entrance to the tent of meeting. He is to cast lots(T) for the two goats—one lot for the Lord and the other for the scapegoat.[b](U) Aaron shall bring the goat whose lot falls to the Lord and sacrifice it for a sin offering. 10 But the goat chosen by lot as the scapegoat shall be presented alive before the Lord to be used for making atonement(V) by sending it into the wilderness as a scapegoat.

11 “Aaron shall bring the bull for his own sin offering to make atonement for himself and his household,(W) and he is to slaughter the bull for his own sin offering. 12 He is to take a censer full of burning coals(X) from the altar before the Lord and two handfuls of finely ground fragrant incense(Y) and take them behind the curtain. 13 He is to put the incense on the fire before the Lord, and the smoke of the incense will conceal the atonement cover(Z) above the tablets of the covenant law, so that he will not die.(AA) 14 He is to take some of the bull’s blood(AB) and with his finger sprinkle it on the front of the atonement cover; then he shall sprinkle some of it with his finger seven times before the atonement cover.(AC)

15 “He shall then slaughter the goat for the sin offering for the people(AD) and take its blood behind the curtain(AE) and do with it as he did with the bull’s blood: He shall sprinkle(AF) it on the atonement cover and in front of it. 16 In this way he will make atonement(AG) for the Most Holy Place(AH) because of the uncleanness and rebellion of the Israelites, whatever their sins have been. He is to do the same for the tent of meeting,(AI) which is among them in the midst of their uncleanness. 17 No one is to be in the tent of meeting from the time Aaron goes in to make atonement in the Most Holy Place until he comes out, having made atonement for himself, his household and the whole community of Israel.

18 “Then he shall come out to the altar(AJ) that is before the Lord and make atonement for it. He shall take some of the bull’s blood and some of the goat’s blood and put it on all the horns of the altar.(AK) 19 He shall sprinkle some of the blood on it with his finger seven times to cleanse it and to consecrate it from the uncleanness of the Israelites.(AL)

20 “When Aaron has finished making atonement for the Most Holy Place, the tent of meeting and the altar, he shall bring forward the live goat.(AM) 21 He is to lay both hands on the head of the live goat(AN) and confess(AO) over it all the wickedness and rebellion of the Israelites—all their sins—and put them on the goat’s head. He shall send the goat away into the wilderness in the care of someone appointed for the task. 22 The goat will carry on itself all their sins(AP) to a remote place; and the man shall release it in the wilderness.

23 “Then Aaron is to go into the tent of meeting and take off the linen garments(AQ) he put on before he entered the Most Holy Place, and he is to leave them there.(AR) 24 He shall bathe himself with water in the sanctuary area(AS) and put on his regular garments.(AT) Then he shall come out and sacrifice the burnt offering for himself and the burnt offering for the people,(AU) to make atonement for himself and for the people.(AV) 25 He shall also burn the fat of the sin offering on the altar.

26 “The man who releases the goat as a scapegoat(AW) must wash his clothes(AX) and bathe himself with water;(AY) afterward he may come into the camp. 27 The bull and the goat for the sin offerings, whose blood was brought into the Most Holy Place to make atonement, must be taken outside the camp;(AZ) their hides, flesh and intestines are to be burned up. 28 The man who burns them must wash his clothes and bathe himself with water; afterward he may come into the camp.(BA)

29 “This is to be a lasting ordinance(BB) for you: On the tenth day of the seventh month(BC) you must deny yourselves[c](BD) and not do any work(BE)—whether native-born(BF) or a foreigner residing among you— 30 because on this day atonement will be made(BG) for you, to cleanse you. Then, before the Lord, you will be clean from all your sins.(BH) 31 It is a day of sabbath rest, and you must deny yourselves;(BI) it is a lasting ordinance.(BJ) 32 The priest who is anointed and ordained(BK) to succeed his father as high priest is to make atonement. He is to put on the sacred linen garments(BL) 33 and make atonement for the Most Holy Place, for the tent of meeting and the altar, and for the priests and all the members of the community.(BM)

34 “This is to be a lasting ordinance(BN) for you: Atonement is to be made once a year(BO) for all the sins of the Israelites.”

And it was done, as the Lord commanded Moses.

Footnotes

  1. Leviticus 16:3 Or purification offering; here and throughout this chapter
  2. Leviticus 16:8 The meaning of the Hebrew for this word is uncertain; also in verses 10 and 26.
  3. Leviticus 16:29 Or must fast; also in verse 31