Johanu 13
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Jesu wẹ ẹsẹ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀
13 (A)Ǹjẹ́ kí àjọ ìrékọjá tó dé, nígbà tí Jesu mọ̀ pé, wákàtí rẹ̀ dé tan, tí òun ó ti ayé yìí kúrò lọ sọ́dọ̀ Baba, fífẹ́ tí ó fẹ́ àwọn tirẹ̀ tí ó wà ní ayé, ó fẹ́ wọn títí dé òpin.
2 (B)Bí wọ́n sì ti ń jẹ oúnjẹ alẹ́, tí èṣù ti fi í sí ọkàn Judasi Iskariotu ọmọ Simoni láti fi í hàn; 3 Tí Jesu sì ti mọ̀ pé Baba ti fi ohun gbogbo lé òun lọ́wọ́, àti pé lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni òun ti wá, òun sì ń lọ sọ́dọ̀ Ọlọ́run; 4 Ó dìde ní ìdí oúnjẹ alẹ́, ó sì fi agbádá rẹ̀ lélẹ̀ ní apá kan; nígbà tí ó sì mú aṣọ ìnura, ó di ara rẹ̀ ní àmùrè. 5 (C)Lẹ́yìn náà, ó bu omi sínú àwokòtò kan, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í máa wẹ ẹsẹ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó sì ń fi aṣọ ìnura tí ó fi di àmùrè nù wọ́n.
6 Nígbà náà ni ó dé ọ̀dọ̀ Simoni Peteru, òun sì wí fún un pé, “Olúwa, ìwọ yóò ha wẹ ẹsẹ̀ mi?”
7 Jesu dá a lóhùn, ó sì wí fún un pé, “Ohun tí èmi ń ṣe ni ìwọ kò mọ̀ nísinsin yìí; ṣùgbọ́n yóò yé ọ ní ìkẹyìn.”
8 (D)Peteru wí fún un pé, “Ìwọ kì yóò wẹ̀ ẹsẹ̀ mi láé.”
Jesu sì dalóhùn pé, “Bí èmi kò bá wẹ̀ ọ́, ìwọ kò ní ìpín ní ọ̀dọ̀ mi.”
9 Simoni Peteru wí fún ún pé, “Olúwa, kì í ṣe ẹsẹ̀ mi nìkan, ṣùgbọ́n àti ọwọ́ àti orí mi pẹ̀lú.”
10 Jesu wí fún un pé, “Ẹni tí a wẹ̀ kò tún fẹ́ ju kí a ṣan ẹsẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó mọ́ níbi gbogbo: ẹ̀yin sì mọ́, ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo yín.” 11 (E)Nítorí tí ó mọ ẹni tí yóò fi òun hàn; nítorí náà ni ó ṣe wí pé, kì í ṣe gbogbo yín ni ó mọ́.
12 Nítorí náà lẹ́yìn tí ó wẹ ẹsẹ̀ wọn tán, tí ó sì ti mú agbádá rẹ̀, tí ó tún jókòó, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin mọ ohun tí mo ṣe sí yín bí? 13 Ẹ̀yin ń pè mí ní ‘Olùkọ́’ àti ‘Olúwa,’ ẹ̀yin wí rere; bẹ́ẹ̀ ni mo jẹ́. 14 Ǹjẹ́ bí èmi tí í ṣe Olúwa àti olùkọ́ yín bá wẹ ẹsẹ̀ yín, ó tọ́ kí ẹ̀yin pẹ̀lú sì máa wẹ ẹsẹ̀ ara yín. 15 (F)Nítorí mo fi àpẹẹrẹ fún yín, kí ẹ̀yin lè máa ṣe gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí yín. 16 (G)Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ọmọ ọ̀dọ̀ kò tóbi ju ọ̀gá rẹ̀ lọ, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí a rán kò tóbi ju ẹni tí ó rán an lọ. 17 (H)Bí ẹ̀yin bá mọ nǹkan wọ̀nyí, alábùkún fún ni yín, bí ẹ̀yin bá ń ṣe wọ́n!
Jesu sọtẹ́lẹ̀ pé ẹnìkan yóò fi òun hàn
18 (I)“Kì í ṣe ti gbogbo yín ni mo ń sọ: èmi mọ àwọn tí mo yàn: ṣùgbọ́n kí Ìwé mímọ́ bá à lè ṣẹ, ‘ẹni tí ń bá mi jẹun pọ̀ sì gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sí mi.’
19 (J)“Láti ìsinsin yìí lọ ni mo wí fún un yín kí ó tó dé, pé nígbà tí ó bá dé, kí ẹ̀yin lè gbàgbọ́ pé èmi ni. 20 (K)Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún un yín, Ẹni tí ó bá gba ẹnikẹ́ni tí mo rán, ó gbà mí; ẹni tí ó bá sì gbà mí, ó gba ẹni tí ó rán mi.”
21 (L)Nígbà tí Jesu ti wí nǹkan wọ̀nyí tán, ọkàn rẹ̀ dàrú nínú rẹ̀, ó sì jẹ́rìí, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún un yín pé, ọ̀kan nínú yín yóò dà mí.”
22 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń wò ara wọn lójú, wọ́n ń ṣiyèméjì ti ẹni tí ó wí. 23 (M)Ǹjẹ́ ẹnìkan rọ̀gbọ̀kú sí àyà Jesu, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ẹni tí Jesu fẹ́ràn. 24 Nítorí náà ni Simoni Peteru ṣàpẹẹrẹ sí i, ó sì wí fún un pé, “Wí fún wa ti ẹni tí o ń sọ.”
25 Ẹni tí ó ń rọ̀gún ní àyà Jesu wí fún un pé, “Olúwa, ta ni í ṣe?”
26 (N)Nítorí náà Jesu dáhùn pé, “Òun náà ni, ẹni tí mo bá fi àkàrà fún nígbà tí mo bá fi run àwo.” Nígbà tí ó sì fi run ún tan, ó fi fún Judasi Iskariotu ọmọ Simoni. 27 Ní kété tí Judasi gba àkàrà náà ni Satani wọ inú rẹ̀ lọ.
Nítorí náà Jesu wí fún un pé, “Ohun tí ìwọ ń ṣe nì, yára ṣe é kánkán.” 28 Kò sì sí ẹnìkan níbi tábìlì tí ó mọ ìdí tí ó ṣe sọ èyí fún un. 29 (O)Nítorí àwọn mìíràn nínú wọn rò pé, nítorí Judasi ni ó ni àpò, ni Jesu fi wí fún un pé, ra nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a kò le ṣe aláìní fún àjọ náà; tàbí kí ó lè fi nǹkan fún àwọn tálákà. 30 (P)Nígbà tí ó sì ti gbà òkèlè náà tan, ó jáde lójúkan náà àkókò náà si jẹ òru.
Jesu sọtẹ́lẹ̀ pé Peteru yóò sẹ́ òun
31 (Q)Nítorí náà nígbà tí ó jáde lọ tan, Jesu wí pé, “Nísinsin yìí ni a yin Ọmọ ènìyàn lógo, a sì yin Ọlọ́run lógo nínú rẹ̀. 32 Bí a bá yin Ọlọ́run lógo nínú rẹ̀, Ọlọ́run yóò sì yìn ín lógo nínú òun tìkára rẹ̀, yóò sì yìn ín lógo nísinsin yìí.
33 (R)“Ẹ̀yin ọmọ mi, nígbà díẹ̀ sí i ni èmi wà pẹ̀lú yín. Ẹ̀yin yóò wá mi: àti gẹ́gẹ́ bí mo ti wí fún àwọn Júù pé, Níbi tí èmi gbé ń lọ, ẹ̀yin kì yóò le wà; bẹ́ẹ̀ ni mo sì wí fún yín nísinsin yìí.
34 (S)“Òfin tuntun kan ni mo fi fún yín, kí ẹ̀yin kí ó fẹ́ ọmọnìkejì yín; gẹ́gẹ́ bí èmi ti fẹ́ràn yín, kí ẹ̀yin kí ó sì fẹ́ràn ọmọnìkejì yín. 35 Nípa èyí ni gbogbo ènìyàn yóò fi mọ̀ pé, ọmọ-ẹ̀yìn mi ni ẹ̀yin ń ṣe, nígbà tí ẹ̀yin bá ní ìfẹ́ sí ọmọ ẹnìkejì yín.”
36 (T)Simoni Peteru wí fún un pé, “Olúwa, níbo ni ìwọ ń lọ?”
Jesu dá a lóhùn pé, “Níbi tí èmi ń lọ, ìwọ kì yóò lè tẹ̀lé mí nísinsin yìí; ṣùgbọ́n ìwọ yóò tọ̀ mí lẹ́yìn ní ìkẹyìn.”
37 (U)Peteru wí fún un pé, “Olúwa èéṣe tí èmi kò fi le tọ̀ ọ́ lẹ́hìn nísinsin yìí? Èmi ó fi ẹ̀mí mi lélẹ̀ nítorí rẹ.”
38 Jesu dalóhùn wí pé, “Ìwọ ó ha fi ẹ̀mí rẹ lélẹ̀ nítorí mi? Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, àkùkọ kì yóò kọ, kí ìwọ kí ó tó ṣẹ́ mi nígbà mẹ́ta!
John 13
EasyEnglish Bible
Jesus washes his disciples' feet
13 It was nearly time for the Passover Festival. Jesus knew that he would soon leave this world and to go to the Father. He had always loved those who were his own people in the world. He continued to love them to the end.
2 Jesus and his disciples were eating supper. The Devil had already put an idea into the mind of Judas Iscariot, Simon's son. The idea was to sell Jesus to his enemies. 3 Jesus knew that the Father had given him power over everything. He knew that he had come from God. And he knew that he would soon return to God. 4 So, during the meal, he stood up. He took off the coat that he wore over his other clothes. He tied a piece of cloth round himself. 5 Then he poured water into a bowl and he began to wash the disciples' feet. Jesus made their feet dry with the cloth that was round him.
6 Jesus came to Simon Peter. Peter asked him, ‘Lord, will you really wash my feet?’ 7 Jesus answered him, ‘You do not understand now what I am doing. But you will understand in the future.’ 8 Peter said, ‘No! You will never wash my feet!’ Jesus answered, ‘If I do not wash you, you do not belong with me.’ 9 Simon Peter replied, ‘So Lord, do not wash my feet only! Wash my hands and my head too!’ 10 Jesus said, ‘A person who has washed his whole body is completely clean. He needs only to wash his feet. And all of you are clean, except one of you.’ 11 Jesus knew already who would sell him to his enemies. That is why he said, ‘Not every one of you is clean.’
12 When he had finished washing the disciples' feet, Jesus put on his coat. He returned to his place at the meal. He asked them, ‘I want you to understand what I have just done for you. 13 You call me Teacher and Lord, and you are right. That is what I am. 14 I am your Teacher and your Lord, but I have washed your feet. So you also should wash each other's feet. 15 I have given you an example. You should do the same for others as I have done for you. 16 I tell you this: No servant is more important than his master is. No messenger is more important than the person who sent him with a message. 17 Now you understand these things. So you should do them, and God will bless you.’
18 Jesus then said, ‘I am not talking about all of you. I know the people that I have chosen. The Bible says, “Someone who ate food with me has turned against me.”[a] 19 I am telling you this now, before it happens. So then, when it does happen, you will believe me. You will believe that “I am who I am”.[b] 20 I tell you this: Anyone who accepts someone that I send to them is also accepting me. Anyone who accepts me is also accepting my Father God who sent me.’
Jesus tells the disciples what will happen to him
21 After Jesus had said this, he felt very upset. He said to the disciples very seriously, ‘I tell you this: One of you will help my enemies to take hold of me.’ 22 The disciples looked at each other. They did not know which of them Jesus was speaking about. 23 The disciple that Jesus loved was sitting very near to Jesus. 24 Simon Peter looked towards that disciple and said to him, ‘Ask Jesus who he is speaking about.’ 25 So that disciple moved even nearer to Jesus and he asked, ‘Who is it, Lord?’ 26 Jesus answered, ‘I will put a piece of bread in the dish of food. Then I will give the bread to him. That is the man.’ So he put a piece of bread in the dish. Then he gave it to Judas, the son of Simon Iscariot.
27 When Judas had taken the bread, Satan came into him. Then Jesus said to Judas, ‘Do quickly what you want to do.’ 28 None of the other disciples who were sitting at the meal understood this. They did not know why Jesus said this to Judas. 29 Judas kept the bag of money on behalf of the group of disciples. So some of them thought that Jesus had asked Judas to buy some things. Maybe he should buy what they needed for the festival. Or maybe he should go and give some money to the poor people.
30 Judas took the bread and he ate it. Then he went out immediately. By now it was night.
Jesus' new rule
31 When Judas had left, Jesus said, ‘Now people will see how great the Son of Man is. Because of him, they will also see how great God is. 32 The Son will show how great God is. Then God will take the Son to himself and he will show how great the Son is. He will do that very soon.
33 My children, I will be with you for only a short time now. You will look for me. But I tell you now what I told the Jews. You cannot go where I am now going. 34 I give a new rule to you. Love each other. You must love each other as I have loved you. 35 In this way, everyone will know that you are my disciples. They will know it, if you really love each other.’
36 Simon Peter asked him, ‘Lord, where will you go?’ Jesus replied, ‘You cannot follow now where I will go. But some time after this, you will follow.’ 37 Peter said, ‘Lord, why can I not go with you now? I would even die for you.’ 38 Jesus answered, ‘You say that you would die for me. But I tell you this: Soon you will say that you do not know me. Before the cockerel sings early tomorrow morning, you will say that three times.’
Footnotes
- 13:18 See Psalms 41:9.
- 13:19 The Jews used ‘I am’ as the name of God. When Jesus said, ‘I am,’ they would have recognized this name. He was saying that he is God.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
EasyEnglish Bible Copyright © MissionAssist 2019 - Charitable Incorporated Organisation 1162807. Used by permission. All rights reserved.