Jobu 5
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ìjìyà jẹ́ èso àìṣòdodo
5 “Ó jẹ́ pé nísinsin yìí bí ẹnìkan bá wà tí yóò dá wa lóhùn?
Tàbí ta ni nínú àwọn ènìyàn mímọ́ tí ìwọ ó yípadà sí?
2 Nítorí pé ìbínú pa aláìmòye,
ìrunú a sì pa òpè ènìyàn.
3 Èmi ti rí aláìmòye ti ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lulẹ̀,
ṣùgbọ́n lójúkan náà mo fi ibùjókòó rẹ̀ bú.
4 Àwọn ọmọ rẹ̀ kò jìnnà sí ewu,
a sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ lójú ibodè,
bẹ́ẹ̀ ni kò sí aláàbò kan.
5 Ìkórè oko ẹni tí àwọn tí ebi ń pa sọ̀ di jíjẹ,
tí wọ́n sì wọ inú ẹ̀gún lọ kó,
àwọn ìgárá ọlọ́ṣà sì gbé ohun ìní wọn mì.
6 Bí ìpọ́njú kò bá ti inú erùpẹ̀ jáde wá ni,
tí ìyọnu kò ti ilẹ̀ jáde wá.
7 Ṣùgbọ́n a bí ènìyàn sínú wàhálà,
gẹ́gẹ́ bí ìpẹ́pẹ́ iná ti máa ń ta sókè.
8 “Ṣùgbọ́n bí ó ṣe tèmi, ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní èmi yóò ti ṣìpẹ̀,
ní ọwọ́ Ọlọ́run ní èmi yóò máa fi ọ̀rọ̀ mi lé.
9 Ẹni tí ó ṣe ohun tí ó tóbi tí a kò lè ṣe àwárí,
ohun ìyanu láìní iye.
10 Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayé
tí ó sì ń rán omi sínú ilẹ̀kílẹ̀.
11 Láti gbé àwọn orílẹ̀-èdè lékè
kí á lè gbé àwọn ẹni ìbànújẹ́ ga sí ibi aláìléwu.
12 (A)Ó yí ìmọ̀ àwọn alárékérekè po,
bẹ́ẹ̀ ní ọwọ́ wọn kò lè mú ìdáwọ́lé wọn ṣẹ.
13 Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú àrékérekè ara wọn,
àti ìmọ̀ àwọn òǹrorò ní ó tì ṣubú ní ògèdèǹgbé.
14 Wọ́n sáré wọ inú òkùnkùn ní ọ̀sán;
wọ́n sì fọwọ́ tálẹ̀ ní ọ̀sán gangan bí ẹni pé ní òru ni.
15 Ṣùgbọ́n ó gba tálákà là ní ọwọ́ idà,
lọ́wọ́ ẹnu wọn àti lọ́wọ́ àwọn alágbára.
16 Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún tálákà,
àìṣòótọ́ sì pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
17 “Kíyèsi i, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí,
nítorí náà, má ṣe gan ìbáwí Olódùmarè.
18 Nítorí pé òun a máa pa ni lára, síbẹ̀ òun a sì tún dì í ní ìdì ìtura,
ó sá lọ́gbẹ́, a sì fi ọwọ́ rẹ̀ di ojú ọgbẹ̀ náà jiná.
19 Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà,
àní nínú méje, ibi kan kì yóò bá ọ
20 Nínú ìyanu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú
àti nínú ogun, yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.
21 A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́n,
bẹ́ẹ̀ ní ìwọ kì yóò bẹ̀rù ìparun tí ó bá dé.
22 Ìwọ yóò rẹ́rìn-ín nínú ìparun àti ìyàn,
bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò bẹ̀rù ẹranko ilẹ̀ ayé.
23 Nítorí pé ìwọ ti bá òkúta igbó mulẹ̀,
àwọn ẹranko igbó yóò wà pẹ̀lú rẹ ní àlàáfíà.
24 Ìwọ ó sì mọ̀ pé àlàáfíà ni ibùjókòó rẹ wà,
ìwọ yóò sì máa ṣe ìbẹ̀wò ibùjókòó rẹ, ìwọ kì yóò ṣìnà.
25 Ìwọ ó sì mọ̀ pẹ̀lú pé irú-ọmọ rẹ ó sì pọ̀
àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ yóò rí bí koríko igbó.
26 Ìwọ yóò wọ isà òkú rẹ ní ògbólógbòó ọjọ́,
bí síírí ọkà tí ó gbó tí á sì kó ní ìgbà ìkórè rẹ̀.
27 “Kíyèsi i, àwa ti wádìí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní ó rí!
Gbà á gbọ́, kí o sì mọ̀ pé fún ìre ara rẹ ni.”
Job 5
International Standard Version
Eliphaz: God Blesses those who Seek Him
5 “Cry out, won’t you!
Is there anyone who will answer you?
To whom will you turn among the holy ones?
2 For wrath will slay a fool;
zealous anger will kill the naïve.
3 “I myself saw a fool becoming established,
but I suddenly cursed where he lived.[a]
4 His children are far from deliverance;
they’ll be maltreated before they leave home,[b]
with no one to rescue them.
5 Then the hungry will devour his harvest,
snatching it even from the midst of thorns,
while the thirsty covet their wealth.
6 For wickedness doesn’t crop up from dust,
nor does trouble sprout out of the ground;
7 But mankind is born headed for trouble,
just as sparks soar skyward.”
God Can be Trusted in Adversity
8 “Now as for me, I would seek God if I were you;[c]
I would commit my case to God.
9 He is always doing great things that cannot be explained,
countless awesome deeds.
10 He sends rain on the surface of the earth,
and waters the surface of the open country.
11 He sets the lowly on high,
and lifts those who mourn to safety.[d]
12 He frustrates the plans of the crafty;
so that what they work for never succeeds.
13 He captures the wise in their own craftiness,
bringing a quick end to their cunning advice.
14 They meet with darkness in broad daylight;
at noonday they grope around as if it were night.
15 So he delivers from the sword of their mouth—
the poor from the power[e] of the mighty.
16 Therefore there is hope for those who are poor,
and iniquity shuts its mouth.
17 “Indeed, how blessed is the person whom God reproves!
So never disrespect the discipline of the Almighty,
18 because though he wounds, but then applies bandages;
though he strikes, his hands still heal.
19 “He will deliver you through six calamities;
and calamity won’t touch you throughout the seventh.
20 He will deliver you from death by famine;
in war from the power[f] of the sword.
21 You’ll be protected from the accusing[g] tongue;
you need not fear destruction when it heads your way.
22 You’ll laugh at destruction and famine;
and you need not fear the beasts of the earth.
23 For you’ll have a pact[h] with the stones in the field;
and the beasts of the field will be at peace with you.
24 You’ll know that your home[i] is secure;
when you search your possessions, and nothing will be missing.
25 You’ll know that you’ll have many children;
and that your offspring will be like the grass of the earth.
26 You’ll go to your grave at a ripe old age;
like a stack of grain that’s harvested at just the right time.
27 “Look! We have thought all this through,
and what we’ve said is true;[j]
So please listen and learn for your own good!”
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Copyright © 1995-2014 by ISV Foundation. ALL RIGHTS RESERVED INTERNATIONALLY. Used by permission of Davidson Press, LLC.
