Jobu 28
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n àti òye Jobu
28 Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ,
àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
2 Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin,
bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
3 Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn,
ó sì ṣe àwárí ìṣúra
láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
4 Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè,
àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀,
wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
5 Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá,
àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná
6 Òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta Safire,
o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
7 Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀,
àti ojú gúnnugún kò rí i rí;
8 Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí,
bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
9 Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta,
ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
10 Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta,
ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
11 Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya,
ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.
12 Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí,
níbo sì ni òye ń gbe?
13 Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀,
bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
14 Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”;
omi Òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”
15 A kò le è fi wúrà rà á,
bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òṣùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
16 A kò le è fi wúrà ofiri,
tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta Safire díye lé e.
17 Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;
bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.
18 A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi;
iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.
19 Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;
bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
20 Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá?
Tàbí níbo ni òye ń gbé?
21 A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo,
ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
22 Ibi ìparun àti ikú wí pé,
àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
23 Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀,
òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.
24 Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé,
ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
25 Láti dà òṣùwọ̀n fún afẹ́fẹ́,
ó sì fi òṣùwọ̀n wọ́n omi.
26 Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò,
tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
27 Nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde;
ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
28 Àti fún ènìyàn ni ó wí pé,
“Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n,
àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”
Jobu 28
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n àti òye Jobu
28 Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ,
àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
2 Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin,
bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
3 Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn,
ó sì ṣe àwárí ìṣúra
láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
4 Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè,
àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀,
wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
5 Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá,
àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná
6 Òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta Safire,
o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
7 Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀,
àti ojú gúnnugún kò rí i rí;
8 Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí,
bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
9 Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta,
ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
10 Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta,
ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
11 Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya,
ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.
12 Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí,
níbo sì ni òye ń gbe?
13 Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀,
bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
14 Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”;
omi Òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”
15 A kò le è fi wúrà rà á,
bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òṣùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
16 A kò le è fi wúrà ofiri,
tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta Safire díye lé e.
17 Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;
bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.
18 A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi;
iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.
19 Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;
bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
20 Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá?
Tàbí níbo ni òye ń gbé?
21 A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo,
ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
22 Ibi ìparun àti ikú wí pé,
àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
23 Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀,
òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.
24 Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé,
ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
25 Láti dà òṣùwọ̀n fún afẹ́fẹ́,
ó sì fi òṣùwọ̀n wọ́n omi.
26 Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò,
tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
27 Nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde;
ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
28 Àti fún ènìyàn ni ó wí pé,
“Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n,
àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.