Add parallel Print Page Options

Ìbéèrè Jobu

24 “Ṣe bí ìgbà kò pamọ́ lọ́dọ̀ Olódùmarè fún ìdájọ́?
    Èéṣe tí ojúlùmọ̀ rẹ̀ kò fi rí ọjọ́ rẹ̀?
Wọ́n a sún ààmì ààlà ilẹ̀,
    wọ́n á fi agbára kó agbo ẹran lọ, wọ́n a sì bọ́ wọn.
Wọ́n á sì da kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ aláìní baba
    lọ, wọ́n a sì gba ọ̀dá màlúù opó ní ohun ògo.
Wọ́n á bi aláìní kúrò lójú ọ̀nà,
    àwọn tálákà ayé a fi agbára sápamọ́.
Kíyèsi i, bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó nínú ijù ni àwọn tálákà jáde lọ sí iṣẹ́ wọn,
    wọ́n a tètè dìde láti wá ohun ọdẹ;
    ijù pèsè oúnjẹ fún wọn àti fún àwọn ọmọ wọn.
Olúkúlùkù a sì sá ọkà oúnjẹ ẹran rẹ̀ nínú oko,
    wọn a sì ká ọgbà àjàrà ènìyàn búburú.
Ní ìhòhò ni wọn máa sùn láìní aṣọ,
    tí wọn kò ní ìbora nínú òtútù.
Ọ̀wààrà òjò òkè ńlá sì pa wọ́n,
    wọ́n sì lẹ̀ mọ́ àpáta nítorí tí kò sí ààbò.
Wọ́n já ọmọ aláìní baba kúrò ní ẹnu ọmú,
    wọ́n sì gbà ọmọ tálákà nítorí gbèsè.
10 Wọ́n rìn kiri ní ìhòhò láìní aṣọ;
    àwọn tí ebi ń pa rẹrù ìdì ọkà,
11 Àwọn ẹni tí ń fún òróró nínú àgbàlá wọn,
    tí wọ́n sì ń tẹ ìfúntí àjàrà, síbẹ̀ òǹgbẹ sì ń gbẹ wọn.
12 Àwọn ènìyàn ń kérora láti ìlú wá,
    ọkàn àwọn ẹni tí ó gbọgbẹ́ kígbe sókè fún ìrànlọ́wọ́
    síbẹ̀ Ọlọ́run kò kíyèsi àṣìṣe náà.

13 “Àwọn ni ó wà nínú àwọn tí ó ṣọ̀tẹ̀ sí ìmọ́lẹ̀;
    Wọn kò mọ̀ ipa ọ̀nà rẹ̀,
    bẹ́ẹ̀ ni wọn kò dúró nípa ọ̀nà rẹ̀.
14 Apànìyàn a dìde ní àfẹ̀mọ́júmọ́,
    a sì pa tálákà àti aláìní,
    àti ní òru a di olè.
15 Ojú alágbèrè pẹ̀lú dúró kí ilẹ̀ ṣú díẹ̀;
    ‘Ó ní, ojú ẹnìkan kì yóò rí mi,’
    ó sì fi ìbòjú bojú rẹ̀.
16 Ní òkùnkùn wọn á rúnlẹ̀ wọlé,
    tí wọ́n ti fi ojú sọ fún ara wọn ní ọ̀sán,
    wọn kò mọ̀ ìmọ́lẹ̀.
17 Nítorí pé bí òru dúdú ní òwúrọ̀ fún gbogbo wọn;
    nítorí tí wọn sì mọ̀ ìbẹ̀rù òkùnkùn.

18 “Ó yára lọ bí ẹni lójú omi;
    ìpín wọn ní ilé ayé ni a ó parun;
    òun kò rìn lọ mọ́ ní ọ̀nà ọgbà àjàrà.
19 Gẹ́gẹ́ bi ọ̀dá àti òru ní í mú omi òjò-dídì yọ́,
    bẹ́ẹ̀ ní isà òkú í run àwọn tó dẹ́ṣẹ̀.
20 Inú ìbímọ yóò gbàgbé rẹ̀, kòkòrò
    ní yóò máa fi adùn jẹun lára rẹ̀,
a kì yóò rántí ènìyàn búburú
    mọ́; Bẹ́ẹ̀ ní a ó sì ṣẹ ìwà búburú bí ẹní ṣẹ́ igi;
21 Ẹni tí o hù ìwà búburú sí àgàn tí
    kò ṣe rere sí opó.
22 Ọlọ́run fi ipá agbára rẹ̀ fa alágbára,
    bí wọ́n tilẹ̀ fìdímúlẹ̀, kò sí ìrètí ìyè fún wọn.
23 Ọlọ́run sì fi àìléwu fún un,
    àti nínú èyí ni a ó sì tì i lẹ́yìn,
    ojú rẹ̀ sì wà ní ipa ọ̀nà wọn.
24 A gbé wọn lékè nígbà díẹ̀, wọ́n kọjá lọ;
    a sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀; A sì mú wọn kúrò ní ọ̀nà bí àwọn ẹlòmíràn,
    a sì ké wọn kúrò bí orí síírí ọkà bàbà.

25 “Ǹjẹ́, bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ nísinsin yìí, ta ni yóò mú mi ní èké,
    tí yóò sì sọ ọ̀rọ̀ mi di aláìníláárí?”

24 “·I wish the Almighty would set a time for judging [L Why are times not kept by the Almighty/Shaddai?].
    ·Those who know God do [L Why do those who know God …?] not see such a day.
·Wicked people [L They] ·take other people’s land [L move boundaries; C move boundary markers];
    they steal flocks and ·take them to new pastures [L pasture them].
They chase away the orphan’s donkey
    and take the widow’s ox ·when she has no money [L as a pledge; Deut. 24:6, 10–13, 17].
They push needy people off the path;
    all the poor of the land hide from them.
The poor become like wild donkeys in the ·desert [wilderness]
    who go about their ·job of finding food [L work].
    ·The desert gives them [L In the desert they forage for] food for their children.
They ·gather hay and straw in the fields [L reap in fields not their own]
    and ·pick up leftover grapes [L glean] from the vineyard of the wicked.
They spend the night naked, because they have no clothes,
    nothing to cover themselves in the cold.
They are soaked from mountain ·rains [storms]
    and ·stay near [hug; embrace] the ·large rocks [cliffs] because they have no shelter.
The ·fatherless child [orphan] is grabbed from its mother’s breast;
    they take a poor mother’s baby ·to pay for what she owes [L as a pledge; 24:3].
10 So the poor ·go [wander] around naked without any clothes;
    they carry bundles of grain but still go hungry;
11 they crush olives to get oil
    and grapes to get wine, but they still go thirsty.
12 Dying people groan in the city,
    and the ·injured [or living dead] cry out for help,
    but God ·accuses no one of doing wrong [or does not hear/react to their prayers].

13 “Those who ·fight [rebel] against the light
    do not ·know [recognize] God’s ways
    or stay in his paths.
14 ·When the day is over [or At the light], the murderers get up
    to ·kill [slay] the poor and needy.
    At night they go about like thieves [Ex. 22:2].
15 ·Those who are guilty of adultery [L The eyes of the adulterer] watch for the ·night [dusk],
    thinking, ‘No ·one [L eye] will see us,’
    and they keep their faces covered [Prov. 7:6–9].
16 In the dark, evil people break into houses [v. 14].
    In the daytime they ·shut [seal] themselves up in their own houses,
    because they ·want nothing to do with [L do not know] the light.
17 Darkness is like morning to all these evil people
    who ·make friends with [L recognize] the terrors of darkness.

18 “·They [The wicked] are ·like foam floating [or like scum; L quick] on the water.
    Their ·part of the land [lot; portion] is cursed;
    no one ·uses the road that goes by [L turns toward] their vineyards. [C This seems to contradict Job’s contention that the wicked escape judgment. Perhaps these are his opponents’ views, or his wish.]
19 As ·heat and dryness [the desert and heat] ·quickly melt the snow [L steal away the snow waters],
    so ·the grave [L Sheol] quickly takes away the sinners.
20 ·Their mothers [L The womb] forget them,
    and worms ·will eat their bodies [L think they are sweet].
They will not be remembered,
    so wickedness is broken in pieces like a ·stick [L tree; C perhaps by wind or lightening; Ps. 29:5–6; Ezek. 17:24].
21 These evil people ·abuse women who cannot have children [or associate with barren women]
    ·and show no kindness to widows [or which is not favorable to their widow].
22 But God drags away the strong by his power.
    Even though they ·seem strong [L rise up], they ·do not know how long they will live [L can have no confidence in life].
23 God may ·let these evil people feel safe [give them security they can lean on],
    but ·he is watching [L his eyes are on] their ways.
24 For a little while they are ·important [exalted], and then ·they die [L are no more];
    they ·are laid low [or give in] and ·buried [L are gathered/drawn in] like everyone else;
    they ·are cut off [or wither] like the heads of grain.
25 If this is not true, who can prove I am ·wrong [L a liar]?
    Who can show that my words are worth nothing?”