Jobu 15
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Elifasi tako ọrọ̀ Jobu
15 Ìgbà náà ní Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé:
2 “Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán, kí
ó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn kún ara rẹ̀ nínú?
3 Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò ní
èrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?
4 Ṣùgbọ́n ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì,
ìwọ sì dí iṣẹ́ ìsìn lọ́nà níwájú Ọlọ́run.
5 Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀
rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.
6 Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi;
àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí gbè ọ́.
7 “Ìwọ ha í ṣe ọkùnrin tí a kọ́ bí?
Tàbí a ha dá ọ ṣáájú àwọn òkè?
8 Ìwọ gbúròó àṣírí Ọlọ́run rí, tàbí
ìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?
9 Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀?
Òye kí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?
10 Àwọn arúgbó àti ògbólógbòó ènìyàn wà pẹ̀lú wa,
tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.
11 Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ?
Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?
12 Èéṣe ti ọkàn rẹ fi ń ti ọ kiri,
kí ni ìwọ tẹjúmọ́ tóbẹ́ẹ̀.
13 Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì sí Ọlọ́run,
tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?
14 “Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́,
àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?
15 Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀,
àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀,
16 mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí,
tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi.
17 “Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi;
Èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,
18 ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti
ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́,
19 Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan,
ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.
20 Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá,
pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo,
àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.
21 Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀;
nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.
22 Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn;
a sì ṣà á sápá kan fún idà.
23 Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà?
Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí.
24 Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un
bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun.
25 Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì
sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè,
26 Ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga,
àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.
27 “Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀
lójú, o sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.
28 Òun sì gbé inú ahoro ìlú,
àti nínú ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé
mọ́, tí ó múra tán láti di àlàpà.
29 Òun kò lé di ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kò
lè dúró pẹ́; Bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
30 Òun kì yóò jáde kúrò nínú òkùnkùn;
ọ̀wọ́-iná ni yóò jó ẹ̀ka rẹ̀,
àti nípasẹ̀ ẹ̀mí ẹnu Ọlọ́run ní a ó gba kúrò.
31 Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀lé asán, kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ.
Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.
32 A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípé ọjọ́ rẹ̀,
ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.
33 Yóò dàbí àjàrà tí a gbọn èso àìpọ́n rẹ̀ dànù,
yóò sì rẹ̀ ìtànná rẹ̀ dànù bí i ti igi Olifi.
34 Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebè
yóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
35 Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bí ẹ̀ṣẹ̀,
ikùn wọn sì pèsè ẹ̀tàn.”
Job 15
English Standard Version
Eliphaz Accuses: Job Does Not Fear God
15 Then (A)Eliphaz the Temanite answered and said:
2 “Should (B)a wise man answer with (C)windy knowledge,
and fill his (D)belly with (E)the east wind?
3 Should he argue in unprofitable talk,
or in words with which he can do no good?
4 But you are doing away with the fear of God[a]
and hindering meditation before God.
5 For your iniquity teaches your mouth,
and you choose the tongue of the crafty.
6 Your (F)own mouth condemns you, and not I;
(G)your own lips testify against you.
7 (H)“Are you the first man who was born?
Or (I)were you brought forth (J)before the hills?
8 Have you listened in (K)the council of God?
And do you limit wisdom to yourself?
9 (L)What do you know that we do not know?
What do you understand that is not clear to us?
10 (M)Both the gray-haired and the aged are among us,
older than your father.
11 Are the comforts of God too small for you,
or the word that deals gently with you?
12 Why does your heart carry you away,
and why do your eyes flash,
13 that you turn your (N)spirit against God
and bring such words out of your mouth?
14 (O)What is man, (P)that he can be pure?
Or he who is (Q)born of a woman, that he can be righteous?
15 Behold, God[b] (R)puts no trust in his (S)holy ones,
and the heavens are not pure in his sight;
16 (T)how much less one who is abominable and (U)corrupt,
a man who (V)drinks injustice like water!
17 “I will show you; hear me,
and what I have seen I will declare
18 (what wise men have told,
without hiding it (W)from their fathers,
19 to whom alone the land was given,
and no (X)stranger passed among them).
20 The wicked man writhes in pain all his days,
through all the (Y)years that are laid up for (Z)the ruthless.
21 (AA)Dreadful sounds are in his ears;
in (AB)prosperity the destroyer will come upon him.
22 He does not believe that he will return out of darkness,
and he is marked for the sword.
23 He (AC)wanders abroad for bread, saying, ‘Where is it?’
He knows that a day of darkness is ready at his hand;
24 distress and anguish terrify him;
they (AD)prevail against him, like a king ready for battle.
25 Because he has stretched out his hand against God
and defies the Almighty,
26 (AE)running (AF)stubbornly against him
with a thickly bossed shield;
27 because he has (AG)covered his face with his fat
and gathered fat upon his waist
28 and has lived in desolate cities,
in houses that none should inhabit,
which were ready to become heaps of ruins;
29 he will not be rich, and his wealth will not endure,
nor will his possessions spread over the earth;[c]
30 he will not depart from darkness;
the flame will dry up his shoots,
and by (AH)the breath of his mouth he will depart.
31 Let him not (AI)trust in emptiness, deceiving himself,
for emptiness will be his payment.
32 It will be paid in full (AJ)before his time,
and his branch will not be green.
33 He will shake off his unripe grape like the vine,
and cast off his blossom like the olive tree.
34 For (AK)the company of the godless is barren,
and (AL)fire consumes the tents of bribery.
35 They (AM)conceive trouble and give birth to evil,
and their (AN)womb prepares deceit.”
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
The ESV® Bible (The Holy Bible, English Standard Version®), © 2001 by Crossway, a publishing ministry of Good News Publishers. ESV Text Edition: 2025.
