Jobu 10
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Àròyé Jobu tẹ̀síwájú
10 “Agara ìwà ayé mi dá mi tán,
èmi yóò tú àròyé mi sókè lọ́dọ̀ mi,
èmi yóò máa sọ̀rọ̀ nínú kíkorò ìbìnújẹ́ ọkàn mi.
2 Èmi yóò wí fún Ọlọ́run pé: má ṣe dá mi lẹ́bi;
fihàn mí nítorí ìdí ohun tí ìwọ fi ń bá mi jà.
3 Ó ha tọ́ tí ìwọ ìbá fi máa ni mí lára,
tí ìwọ ìbá fi máa gan iṣẹ́ ọwọ́ rẹ,
tí ìwọ yóò fi máa tàn ìmọ́lẹ̀ sí ìmọ̀ ènìyàn búburú.
4 Ojú rẹ kì ha ṣe ojú ènìyàn bí?
Tàbí ìwọ a máa ríran bí ènìyàn ti í ríran?
5 Ọjọ́ rẹ ha dàbí ọjọ́ ènìyàn,
ọdún rẹ ha dàbí ọjọ́ ènìyàn?
6 Tí ìwọ fi ń béèrè àìṣedéédéé mi,
tí ìwọ sì fi wá ẹ̀ṣẹ̀ mi rí?
7 Ìwọ mọ̀ pé èmi kì í ṣe oníwà búburú,
kò sì sí ẹni tí ó le gbà mí kúrò ní ọwọ́ rẹ?
8 “Ọwọ́ rẹ ni ó mọ mi, tí ó sì da mi.
Síbẹ̀ ìwọ tún yípadà láti jẹ mí run.
9 Èmi bẹ̀ ọ́ rántí pé ìwọ ti mọ mí bí amọ̀;
ìwọ yóò ha sì tún mú mi padà lọ sínú erùpẹ̀?
10 Ìwọ kò ha ti tú mí dà jáde bí i wàrà,
ìwọ kò sì mú mí dìpọ̀ bí i wàràǹkàṣì?
11 Ìwọ sá ti fi àwọ̀ ẹran-ara wọ̀ mí,
ìwọ sì fi egungun àti iṣan ṣọgbà yí mi ká.
12 Ìwọ ti fún mi ní ẹ̀mí àti ojúrere,
ìbẹ̀wò rẹ sì pa ọkàn mi mọ́.
13 “Nǹkan wọ̀nyí ni ìwọ sì ti fi pamọ́ nínú rẹ;
èmi mọ̀ pé, èyí ń bẹ ní ọkàn rẹ.
14 Bí mo bá ṣẹ̀, nígbà náà ni ìwọ yóò máa ṣọ́ mi
ìwọ kì yóò sì dárí àìṣedéédéé mi jì.
15 Bí mo bá ṣe ẹni búburú, ègbé ni fún mi!
Bí mo bá sì ṣe ẹni rere,
bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì le gbe orí mi sókè.
Èmi dààmú, mo si wo ìpọ́njú mi.
16 Bí mo bá gbé orí mi ga. Ìwọ ń dẹ mí kiri bi i kìnnìún;
àti pẹ̀lú, ìwọ a sì fi ara rẹ hàn fún mi ní ìyànjú.
17 Ìwọ sì tún mun àwọn ẹlẹ́rìí rẹ dìde sí mi
di ọ̀tún, Ìwọ sì sọ ìrunú rẹ di púpọ̀ sí mi;
Àwọn ogun rẹ si dìde sinmi bi igbe omi Òkun.
18 “Nítorí kí ni ìwọ ṣe mú mi jáde láti inú wá?
Háà! Èmi ìbá kúkú ti kú, ojúkójú kì bá tí rí mi.
19 Tí kò bá le jẹ́ pé èmi wà láààyè,
À bá ti gbé mi láti inú lọ isà òkú.
20 Ọjọ́ mi kò ha kúrú bí? Rárá!
Dáwọ́ dúró, kí ó sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ mi.
Nítorí kí èmi lè ni ayọ̀ ní ìṣẹ́jú kan.
21 Kí èmi kí ó tó lọ sí ibi tí èmi kì yóò padà sẹ́yìn mọ́,
Àní si ilẹ̀ òkùnkùn àti òjìji ikú.
22 Ilẹ̀ òkùnkùn bí òkùnkùn tìkára rẹ̀,
Àti ti òjìji ikú àti rúdurùdu,
Níbi tí ìmọ́lẹ̀ dàbí òkùnkùn.”
Job 10
King James Version
10 My soul is weary of my life; I will leave my complaint upon myself; I will speak in the bitterness of my soul.
2 I will say unto God, Do not condemn me; shew me wherefore thou contendest with me.
3 Is it good unto thee that thou shouldest oppress, that thou shouldest despise the work of thine hands, and shine upon the counsel of the wicked?
4 Hast thou eyes of flesh? or seest thou as man seeth?
5 Are thy days as the days of man? are thy years as man's days,
6 That thou enquirest after mine iniquity, and searchest after my sin?
7 Thou knowest that I am not wicked; and there is none that can deliver out of thine hand.
8 Thine hands have made me and fashioned me together round about; yet thou dost destroy me.
9 Remember, I beseech thee, that thou hast made me as the clay; and wilt thou bring me into dust again?
10 Hast thou not poured me out as milk, and curdled me like cheese?
11 Thou hast clothed me with skin and flesh, and hast fenced me with bones and sinews.
12 Thou hast granted me life and favour, and thy visitation hath preserved my spirit.
13 And these things hast thou hid in thine heart: I know that this is with thee.
14 If I sin, then thou markest me, and thou wilt not acquit me from mine iniquity.
15 If I be wicked, woe unto me; and if I be righteous, yet will I not lift up my head. I am full of confusion; therefore see thou mine affliction;
16 For it increaseth. Thou huntest me as a fierce lion: and again thou shewest thyself marvellous upon me.
17 Thou renewest thy witnesses against me, and increasest thine indignation upon me; changes and war are against me.
18 Wherefore then hast thou brought me forth out of the womb? Oh that I had given up the ghost, and no eye had seen me!
19 I should have been as though I had not been; I should have been carried from the womb to the grave.
20 Are not my days few? cease then, and let me alone, that I may take comfort a little,
21 Before I go whence I shall not return, even to the land of darkness and the shadow of death;
22 A land of darkness, as darkness itself; and of the shadow of death, without any order, and where the light is as darkness.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.