Add parallel Print Page Options

Ìdáhùn Jobu

Jobu sì dáhùn ó si wí pé:

“Háà! À bá lè wọ́n ìbìnújẹ́ mi nínú òṣùwọ̀n,
    kí a sì le gbé ọ̀fọ̀ mi lé orí òṣùwọ̀n ṣọ̀kan pọ̀!
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ìbá wúwo jú iyanrìn Òkun lọ:
    nítorí náà ni ọ̀rọ̀ mi ṣe ń tàsé
Nítorí pé ọfà Olódùmarè wọ̀ mi nínú,
    oró èyí tí ọkàn mi mú;
    ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí.
Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko,
    tàbí ọ̀dá màlúù a máa dún lórí ìjẹ rẹ̀?
A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀,
    tàbí adùn ha wà nínú funfun ẹyin?
Ohun ti ọ̀kan mi kọ̀ láti tọ́wò,
    òun ni ó dàbí oúnjẹ tí ó mú mi ṣàárẹ̀.

“Háà! èmi ìbá lè rí ìbéèrè mi gbà;
    àti pé, kí Ọlọ́run lè fi ohun tí èmi ṣàfẹ́rí fún mi.
Àní Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa mí run,
    tí òun ìbá jẹ́ ṣíwọ́ rẹ̀ kì ó sì ké mi kúrò.
10 Nígbà náà ní èmi ìbá ní ìtùnú síbẹ̀,
    àní, èmi ìbá mú ọkàn mi le nínú ìbànújẹ́ mi ti kò dá ni sí:
    nítorí èmi kò fi ọ̀rọ̀ ẹni mímọ́ ni sin rí.

11 “Kí ní agbára mi tí èmi ó fi retí?
    Kí sì ní òpin mi tí èmi ó fi ní sùúrù?
12 Agbára mi ha ṣe agbára òkúta bí?
    Ẹran-ara mi í ṣe idẹ?
13 Ìrànlọ́wọ́ mi kò ha wà nínú mi:
    ọgbọ́n kò ha ti sálọ kúrò lọ́dọ̀ mi bí?

14 “Ẹni tí àyà rẹ̀ yọ́ dànù, ta ni a bá máa ṣàánú fún láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ wá,
    kí ó má ba à kọ ìbẹ̀rù Olódùmarè sílẹ̀?
15 Àwọn ará mi dàbí odò tí kò ṣe gbẹ́kẹ̀lé
    bí ìṣàn omi odò, wọ́n sàn kọjá lọ.
16 Tí ó dúdú nítorí omi dídì,
    àti níbi tí yìnyín dídì gbé di yíyọ́.
17 Nígbàkúgbà tí wọ́n bá gbóná wọn a sì yọ́ sàn lọ,
    nígbà tí oòrùn bá mú, wọn a sì gbẹ kúrò ni ipò wọn.
18 Àwọn oníṣòwò yà kúrò ní ọ̀nà wọn,
    wọ́n gòkè sí ibi asán, wọ́n sì run.
19 Ẹgbẹ́ oníṣòwò Tema ń wá omi,
    àwọn oníṣòwò Ṣeba ń dúró dè wọ́n ní ìrètí.
20 Wọ́n káàárẹ̀, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e;
    wọ́n dé bẹ̀, wọ́n sì dààmú.
21 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin dàbí wọn;
    ẹ̀yin rí ìrẹ̀sílẹ̀ mi àyà sì fò mí.
22 Èmi ó ha wí pé, ‘Ẹ mú ohun fún mi wá,
    tàbí pé ẹ fún mi ní ẹ̀bùn nínú ohun ìní yín?
23 Tàbí, ẹ gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá ni,
    tàbí, ẹ rà mí padà kúrò lọ́wọ́ alágbára nì’?

24 “Ẹ kọ́ mi, èmi ó sì pa ẹnu mi mọ́
    kí ẹ sì mú mi wòye níbi tí mo gbé ti ṣìnà.
25 Wò ó! Bí ọ̀rọ̀ òtítọ́ ti lágbára tó
    ṣùgbọ́n kí ni àròyé ìbáwí yín jásí?
26 Ẹ̀yin ṣè bí ẹ tún ọ̀rọ̀ mi ṣe
    àti ohùn ẹnu tí ó dàbí afẹ́fẹ́ ṣe àárẹ̀.
27 Àní ẹ̀yin ṣe gẹ́gẹ́ bí aláìní baba,
    ẹ̀yin sì da iye lé ọ̀rẹ́ yín.

28 “Nítorí náà, kí èyí kí ó tó fún yín.
    Ẹ má wò mi! Nítorí pé ó hàn gbangba pé:
    Ní ojú yín ni èmi kì yóò ṣèké.
29 Èmi ń bẹ̀ yín, ẹ padà, kí ó má sì ṣe jásí ẹ̀ṣẹ̀;
    àní, ẹ sì tún padà, àre mi ń bẹ nínú ọ̀rọ̀ yìí.
30 Àìṣedéédéé ha wà ní ahọ́n mi?
    Ǹjẹ́ ìtọ́wò ẹnu mi kò kúkú le mọ ohun ti ó burú jù?

Job

Then Job replied:

“If only my anguish could be weighed
    and all my misery be placed on the scales!(A)
It would surely outweigh the sand(B) of the seas—
    no wonder my words have been impetuous.(C)
The arrows(D) of the Almighty(E) are in me,(F)
    my spirit drinks(G) in their poison;(H)
    God’s terrors(I) are marshaled against me.(J)
Does a wild donkey(K) bray(L) when it has grass,
    or an ox bellow when it has fodder?(M)
Is tasteless food eaten without salt,
    or is there flavor in the sap of the mallow[a]?(N)
I refuse to touch it;
    such food makes me ill.(O)

“Oh, that I might have my request,
    that God would grant what I hope for,(P)
that God would be willing to crush(Q) me,
    to let loose his hand and cut off my life!(R)
10 Then I would still have this consolation(S)
    my joy in unrelenting pain(T)
    that I had not denied the words(U) of the Holy One.(V)

11 “What strength do I have, that I should still hope?
    What prospects, that I should be patient?(W)
12 Do I have the strength of stone?
    Is my flesh bronze?(X)
13 Do I have any power to help myself,(Y)
    now that success has been driven from me?

14 “Anyone who withholds kindness from a friend(Z)
    forsakes the fear of the Almighty.(AA)
15 But my brothers are as undependable as intermittent streams,(AB)
    as the streams that overflow
16 when darkened by thawing ice
    and swollen with melting snow,(AC)
17 but that stop flowing in the dry season,
    and in the heat(AD) vanish from their channels.
18 Caravans turn aside from their routes;
    they go off into the wasteland and perish.
19 The caravans of Tema(AE) look for water,
    the traveling merchants of Sheba(AF) look in hope.
20 They are distressed, because they had been confident;
    they arrive there, only to be disappointed.(AG)
21 Now you too have proved to be of no help;
    you see something dreadful and are afraid.(AH)
22 Have I ever said, ‘Give something on my behalf,
    pay a ransom(AI) for me from your wealth,(AJ)
23 deliver me from the hand of the enemy,
    rescue me from the clutches of the ruthless’?(AK)

24 “Teach me, and I will be quiet;(AL)
    show me where I have been wrong.(AM)
25 How painful are honest words!(AN)
    But what do your arguments prove?
26 Do you mean to correct what I say,
    and treat my desperate words as wind?(AO)
27 You would even cast lots(AP) for the fatherless(AQ)
    and barter away your friend.

28 “But now be so kind as to look at me.
    Would I lie to your face?(AR)
29 Relent, do not be unjust;(AS)
    reconsider, for my integrity(AT) is at stake.[b](AU)
30 Is there any wickedness on my lips?(AV)
    Can my mouth not discern(AW) malice?

Footnotes

  1. Job 6:6 The meaning of the Hebrew for this phrase is uncertain.
  2. Job 6:29 Or my righteousness still stands