Add parallel Print Page Options

Elihu bá Jobu sọ̀rọ̀

33 “Ǹjẹ́ nítorí náà, Jobu, èmí bẹ̀ ọ,
    gbọ́ ọ̀rọ̀ mi kí o sì fetísí ọ̀rọ̀ mi!
Kíyèsi i nísinsin yìí, èmí ya ẹnu mi,
    ahọ́n mi sì sọ̀rọ̀ ní ẹnu mi.
Ọ̀rọ̀ mi yóò sì jásí ìdúró ṣinṣin ọkàn mi,
    ètè mi yóò sì sọ ìmọ̀ mi jáde dájúdájú.
Ẹ̀mí Ọlọ́run ni ó tí dá mi,
    àti ìmísí Olódùmarè ni ó ti fún mi ní ìyè.
Bí ìwọ bá le dá mi lóhùn,
    tò ọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́sẹẹsẹ níwájú mi;
Kíyèsi i, bí ìwọ ṣe jẹ́ ti Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni èmi náà;
    láti amọ̀ wá ni a sì ti dá mi pẹ̀lú.
Kíyèsi i, ẹ̀rù ńlá mi kì yóò bà ọ;
    bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi kì yóò wúwo sí ọ lára.

“Nítòótọ́ ìwọ sọ ní etí mi,
    èmí sì gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ wí pé,
‘Èmi mọ́, láìní ìrékọjá, aláìṣẹ̀ ní èmi;
    bẹ́ẹ̀ àìṣedéédéé kò sí ní ọwọ́ mi.
10 Kíyèsi i, Ọlọ́run ti rí àìṣedéédéé pẹ̀lú mi;
    ó kà mí sì ọ̀tá rẹ̀.
11 Ó kan ẹ̀ṣẹ̀ mi sínú àbà;
    o kíyèsi ipa ọ̀nà mi gbogbo.’

12 “Kíyèsi i, nínú èyí ìwọ ṣìnà!
    Èmi ó dá ọ lóhùn pé, Ọlọ́run tóbi jù ènìyàn lọ!
13 Nítorí kí ni ìwọ ṣe ń bá a jà, wí pé,
    òun kò ní sọ ọ̀rọ̀ kan nítorí iṣẹ́ rẹ̀?
14 Nítorí pe Ọlọ́run sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kan,
    àní, lẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n ènìyàn kò róye rẹ̀.
15 Nínú àlá, ní ojúran òru,
    nígbà tí orun èjìká bá kùn ènìyàn lọ,
    ní sísùn lórí ibùsùn,
16 Nígbà náà ni ó lè sọ̀rọ̀ ní etí wọn,
    yóò sì dẹ́rùbà wọ́n pẹ̀lú ìbáwí,
17 Kí ó lè fa ènìyàn sẹ́yìn kúrò nínú ètè rẹ̀;
    Kí ó sì pa ìgbéraga mọ́ kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn;
18 Ó sì fa ọkàn rẹ̀ padà kúrò nínú isà òkú,
    àti ẹ̀mí rẹ̀ láti ṣègbé lọ́wọ́ idà.

19 “A sì nà án lórí ibùsùn ìrora rẹ̀;
    pẹ̀lúpẹ̀lú a fi ìjà egungun rẹ̀ ti ó dúró pẹ́ nà án,
20 bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀mí rẹ kọ oúnjẹ,
    ọkàn rẹ̀ sì kọ oúnjẹ dídùn.
21 Ẹran-ara rẹ̀ run, títí a kò sì fi lè rí i mọ́
    egungun rẹ̀ tí a kò tí rí sì ta jáde.
22 Àní, ọkàn rẹ̀ sì súnmọ́ isà òkú,
    ẹ̀mí rẹ̀ sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ ikú.
23 Bí angẹli kan ba wà lọ́dọ̀ rẹ̀,
    ẹni tí ń ṣe alágbàwí,
    ọ̀kan nínú ẹgbẹ̀rún láti fi ọ̀nà pípé hàn ni,
24 Nígbà náà ni ó ṣe oore-ọ̀fẹ́ fún un ó sì wí pé,
    gbà á kúrò nínú lílọ sínú isà òkú;
    èmi ti rà á padà.
25 Ara rẹ̀ yóò sì di ọ̀tun bí i ti ọmọ kékeré,
    yóò sì tún padà sí ọjọ́ ìgbà èwe rẹ̀;
26 Ó gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, òun sì ṣe ojúrere rẹ̀,
    o sì rí ojú rẹ̀ pẹ̀lú ayọ̀,
    òhun o san òdodo rẹ̀ padà fún ènìyàn.
27 Ó wá sọ́dọ̀ ènìyàn ó sì wí pé,
    ‘Èmi ṣẹ̀, kò sì ṣí èyí tí o tọ́, mo sì ti yí èyí tí ó tọ́ po,
    a kò sì san ẹ̀san rẹ̀ fún mi;
28 Ọlọ́run ti gba ọkàn mi kúrò nínú lílọ sínú ihò,
    ẹ̀mí mi yóò wà láti jẹ adùn ìmọ́lẹ̀ ayé.’

29 “Wò ó! Nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run
    máa ń ṣe fún ènìyàn nígbà méjì àti nígbà mẹ́ta,
30 Láti mú ọkàn rẹ padà kúrò nínú isà òkú,
    láti fi ìmọ́lẹ̀ alààyè han sí i.

31 “Jobu, kíyèsi i gidigidi kí o sì fetí sí mi;
    pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì máa sọ ọ́
32 Bí ìwọ bá sì ní ohun wí, dá mi lóhùn;
    máa sọ, nítorí pé èmi fẹ́ dá ọ láre.
33 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, gbọ́ tèmi;
    pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì kọ́ ọ ní ọgbọ́n.”

33 “But now, Job, listen(A) to my words;
    pay attention to everything I say.(B)
I am about to open my mouth;
    my words are on the tip of my tongue.
My words come from an upright heart;(C)
    my lips sincerely speak what I know.(D)
The Spirit(E) of God has made me;(F)
    the breath of the Almighty(G) gives me life.(H)
Answer me(I) then, if you can;
    stand up(J) and argue your case before me.(K)
I am the same as you in God’s sight;(L)
    I too am a piece of clay.(M)
No fear of me should alarm you,
    nor should my hand be heavy on you.(N)

“But you have said in my hearing—
    I heard the very words—
‘I am pure,(O) I have done no wrong;(P)
    I am clean and free from sin.(Q)
10 Yet God has found fault with me;
    he considers me his enemy.(R)
11 He fastens my feet in shackles;(S)
    he keeps close watch on all my paths.’(T)

12 “But I tell you, in this you are not right,
    for God is greater than any mortal.(U)
13 Why do you complain to him(V)
    that he responds to no one’s words[a]?(W)
14 For God does speak(X)—now one way, now another(Y)
    though no one perceives it.(Z)
15 In a dream,(AA) in a vision(AB) of the night,(AC)
    when deep sleep(AD) falls on people
    as they slumber in their beds,
16 he may speak(AE) in their ears
    and terrify them(AF) with warnings,(AG)
17 to turn them from wrongdoing
    and keep them from pride,(AH)
18 to preserve them from the pit,(AI)
    their lives from perishing by the sword.[b](AJ)

19 “Or someone may be chastened(AK) on a bed of pain(AL)
    with constant distress in their bones,(AM)
20 so that their body finds food(AN) repulsive
    and their soul loathes the choicest meal.(AO)
21 Their flesh wastes away to nothing,
    and their bones,(AP) once hidden, now stick out.(AQ)
22 They draw near to the pit,(AR)
    and their life to the messengers of death.[c](AS)
23 Yet if there is an angel at their side,
    a messenger,(AT) one out of a thousand,
    sent to tell them how to be upright,(AU)
24 and he is gracious to that person and says to God,
    ‘Spare them from going down to the pit;(AV)
    I have found a ransom for them(AW)
25 let their flesh be renewed(AX) like a child’s;
    let them be restored as in the days of their youth’(AY)
26 then that person can pray to God and find favor with him,(AZ)
    they will see God’s face and shout for joy;(BA)
    he will restore them to full well-being.(BB)
27 And they will go to others and say,
    ‘I have sinned,(BC) I have perverted what is right,(BD)
    but I did not get what I deserved.(BE)
28 God has delivered(BF) me from going down to the pit,(BG)
    and I shall live to enjoy the light of life.’(BH)

29 “God does all these things to a person(BI)
    twice, even three times(BJ)
30 to turn them back(BK) from the pit,(BL)
    that the light of life(BM) may shine on them.(BN)

31 “Pay attention, Job, and listen(BO) to me;(BP)
    be silent,(BQ) and I will speak.
32 If you have anything to say, answer me;(BR)
    speak up, for I want to vindicate you.(BS)
33 But if not, then listen to me;(BT)
    be silent,(BU) and I will teach you wisdom.(BV)

Footnotes

  1. Job 33:13 Or that he does not answer for any of his actions
  2. Job 33:18 Or from crossing the river
  3. Job 33:22 Or to the place of the dead