Add parallel Print Page Options

Jobu rántí ìbùkún rẹ̀ àtẹ̀yìnwá

29 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Jobu sì tún tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé:

“Háà! ìbá ṣe pé èmi wà bí ìgbà oṣù tí ó kọjá,
    bí ọjọ́ tí Ọlọ́run pa mí mọ́;
Nígbà tí fìtílà rẹ tàn sí mi ní orí,
    àti nípa ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ èmi rìn nínú òkùnkùn já;
Bí mo ti rí nígbà ọ̀dọ́ mi,
    nígbà tí ọ̀rẹ́ Ọlọ́run tímọ́tímọ́ bùkún ilé mi
Nígbà tí Olódùmarè wà pẹ̀lú mi,
    nígbà tí àwọn ọmọ mi wà yí mi ká;
Nígbà tí èmi fi òrí-àmọ́ n wẹ ìṣísẹ̀ mi,
    àti tí apata ń tú ìṣàn òróró jáde fún mi wá.

“Nígbà tí mo jáde la àárín ìlú lọ sí ẹnu ibodè,
    nígbà tí mo tẹ́ ìtẹ́ mi ní ìgboro,
Nígbà náà ni àwọn ọmọkùnrin rí mi,
    wọ́n sì sápamọ́, àwọn àgbà dìde dúró ní ẹsẹ̀ wọn;
Àwọn ọmọ-aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ,
    wọn a sì fi ọwọ́ wọn lé ẹnu;
10 Àwọn ọlọ́lá dákẹ́,
    ahọ́n wọn sì lẹ̀ mọ́ èrìgì ẹnu wọn.
11 Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súre fún mi,
    àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi;
12 Nítorí mo gbà tálákà tí n fẹ́ ìrànlọ́wọ́,
    àti aláìní baba tí kò sí olùrànlọ́wọ́ fún un
13 Ẹni tí ó ń kìlọ̀ súre fún mi,
    èmi sì mú àyà opó kọrin fún ayọ̀.
14 Èmi sì mú òdodo wọ̀ bí aṣọ,
    ẹ̀tọ́ mi dàbí aṣọ ìgúnwà àti adé ọba.
15 Mo ṣe ojú fún afọ́jú mo sì ṣe ẹsẹ̀
    fún amúnkùn ún.
16 Mo ṣe baba fún tálákà, mo ṣe
    ìwádìí ọ̀ràn àjèjì tí èmi kò mọ̀ rí.
17 Mo sì ká eyín ẹ̀rẹ̀kẹ́ ènìyàn búburú,
    mo sì já ohun ọdẹ náà kúrò ní eyín rẹ̀.

18 “Nígbà náà ni mo rò pé, ‘Èmi yóò kú nínú ilé mi,
    èmi yóò sì mú ọjọ́ mi pọ̀ sí i bí iyanrìn.
19 Gbòǹgbò mi yóò ta kan omi,
    ìrì yóò sì sẹ̀ ní gbogbo òru sí ara ẹ̀ka mi.
20 Ògo mi yóò wà ní ọ̀tún ní ọ̀dọ̀
    mi, ọrun mi sì padà di tuntun ní ọwọ́ mi.’

21 “Èmi ni ènìyàn ń dẹtí sílẹ̀ sí,
    wọn a sì dúró, wọn a sì dákẹ́ rọ́rọ́ ní ìmọ̀ràn mi.
22 Lẹ́yìn ọ̀rọ̀ mi, wọn kò tún sọ̀rọ̀ mọ́;
    ọ̀rọ̀ mi wọ̀ wọ́n ní etí ṣinṣin.
23 Wọn a sì dúró dè mí bí ẹni wí pé wọ́n dúró fún ọ̀wọ́ òjò;
    wọn a sì mu nínú ọ̀rọ̀ mi bí ẹní mu nínú òjò àrọ̀kúrò.
24 Èmi sì rẹ́rìn-ín sí wọn nígbà tí wọn kò bá gbà á gbọ́;
    ìmọ́lẹ̀ ojú mi jẹ́ iyebíye sí wọn.
25 Mo la ọ̀nà sílẹ̀ fún wọn, mo sì jókòó bí olóyè wọn;
    Mo jókòó bí ọba ní àárín ológun rẹ̀;
    Mo sì rí bí ẹni tí ń tu ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú.

Job’s Final Defense

29 Job continued his discourse:(A)

“How I long for the months gone by,(B)
    for the days when God watched over me,(C)
when his lamp shone on my head
    and by his light I walked through darkness!(D)
Oh, for the days when I was in my prime,
    when God’s intimate friendship(E) blessed my house,(F)
when the Almighty was still with me
    and my children(G) were around me,(H)
when my path was drenched with cream(I)
    and the rock(J) poured out for me streams of olive oil.(K)

“When I went to the gate(L) of the city
    and took my seat in the public square,
the young men saw me and stepped aside(M)
    and the old men rose to their feet;(N)
the chief men refrained from speaking(O)
    and covered their mouths with their hands;(P)
10 the voices of the nobles were hushed,(Q)
    and their tongues stuck to the roof of their mouths.(R)
11 Whoever heard me spoke well of me,
    and those who saw me commended me,(S)
12 because I rescued the poor(T) who cried for help,
    and the fatherless(U) who had none to assist them.(V)
13 The one who was dying blessed me;(W)
    I made the widow’s(X) heart sing.
14 I put on righteousness(Y) as my clothing;
    justice was my robe and my turban.(Z)
15 I was eyes(AA) to the blind
    and feet to the lame.(AB)
16 I was a father to the needy;(AC)
    I took up the case(AD) of the stranger.(AE)
17 I broke the fangs of the wicked
    and snatched the victims(AF) from their teeth.(AG)

18 “I thought, ‘I will die in my own house,
    my days as numerous as the grains of sand.(AH)
19 My roots will reach to the water,(AI)
    and the dew will lie all night on my branches.(AJ)
20 My glory will not fade;(AK)
    the bow(AL) will be ever new in my hand.’(AM)

21 “People listened to me expectantly,
    waiting in silence for my counsel.(AN)
22 After I had spoken, they spoke no more;(AO)
    my words fell gently on their ears.(AP)
23 They waited for me as for showers
    and drank in my words as the spring rain.(AQ)
24 When I smiled at them, they scarcely believed it;
    the light of my face(AR) was precious to them.[a](AS)
25 I chose the way for them and sat as their chief;(AT)
    I dwelt as a king(AU) among his troops;
    I was like one who comforts mourners.(AV)

Footnotes

  1. Job 29:24 The meaning of the Hebrew for this clause is uncertain.