Add parallel Print Page Options

Ìbéèrè Jobu

24 “Ṣe bí ìgbà kò pamọ́ lọ́dọ̀ Olódùmarè fún ìdájọ́?
    Èéṣe tí ojúlùmọ̀ rẹ̀ kò fi rí ọjọ́ rẹ̀?
Wọ́n a sún ààmì ààlà ilẹ̀,
    wọ́n á fi agbára kó agbo ẹran lọ, wọ́n a sì bọ́ wọn.
Wọ́n á sì da kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ aláìní baba
    lọ, wọ́n a sì gba ọ̀dá màlúù opó ní ohun ògo.
Wọ́n á bi aláìní kúrò lójú ọ̀nà,
    àwọn tálákà ayé a fi agbára sápamọ́.
Kíyèsi i, bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó nínú ijù ni àwọn tálákà jáde lọ sí iṣẹ́ wọn,
    wọ́n a tètè dìde láti wá ohun ọdẹ;
    ijù pèsè oúnjẹ fún wọn àti fún àwọn ọmọ wọn.
Olúkúlùkù a sì sá ọkà oúnjẹ ẹran rẹ̀ nínú oko,
    wọn a sì ká ọgbà àjàrà ènìyàn búburú.
Ní ìhòhò ni wọn máa sùn láìní aṣọ,
    tí wọn kò ní ìbora nínú òtútù.
Ọ̀wààrà òjò òkè ńlá sì pa wọ́n,
    wọ́n sì lẹ̀ mọ́ àpáta nítorí tí kò sí ààbò.
Wọ́n já ọmọ aláìní baba kúrò ní ẹnu ọmú,
    wọ́n sì gbà ọmọ tálákà nítorí gbèsè.
10 Wọ́n rìn kiri ní ìhòhò láìní aṣọ;
    àwọn tí ebi ń pa rẹrù ìdì ọkà,
11 Àwọn ẹni tí ń fún òróró nínú àgbàlá wọn,
    tí wọ́n sì ń tẹ ìfúntí àjàrà, síbẹ̀ òǹgbẹ sì ń gbẹ wọn.
12 Àwọn ènìyàn ń kérora láti ìlú wá,
    ọkàn àwọn ẹni tí ó gbọgbẹ́ kígbe sókè fún ìrànlọ́wọ́
    síbẹ̀ Ọlọ́run kò kíyèsi àṣìṣe náà.

13 “Àwọn ni ó wà nínú àwọn tí ó ṣọ̀tẹ̀ sí ìmọ́lẹ̀;
    Wọn kò mọ̀ ipa ọ̀nà rẹ̀,
    bẹ́ẹ̀ ni wọn kò dúró nípa ọ̀nà rẹ̀.
14 Apànìyàn a dìde ní àfẹ̀mọ́júmọ́,
    a sì pa tálákà àti aláìní,
    àti ní òru a di olè.
15 Ojú alágbèrè pẹ̀lú dúró kí ilẹ̀ ṣú díẹ̀;
    ‘Ó ní, ojú ẹnìkan kì yóò rí mi,’
    ó sì fi ìbòjú bojú rẹ̀.
16 Ní òkùnkùn wọn á rúnlẹ̀ wọlé,
    tí wọ́n ti fi ojú sọ fún ara wọn ní ọ̀sán,
    wọn kò mọ̀ ìmọ́lẹ̀.
17 Nítorí pé bí òru dúdú ní òwúrọ̀ fún gbogbo wọn;
    nítorí tí wọn sì mọ̀ ìbẹ̀rù òkùnkùn.

18 “Ó yára lọ bí ẹni lójú omi;
    ìpín wọn ní ilé ayé ni a ó parun;
    òun kò rìn lọ mọ́ ní ọ̀nà ọgbà àjàrà.
19 Gẹ́gẹ́ bi ọ̀dá àti òru ní í mú omi òjò-dídì yọ́,
    bẹ́ẹ̀ ní isà òkú í run àwọn tó dẹ́ṣẹ̀.
20 Inú ìbímọ yóò gbàgbé rẹ̀, kòkòrò
    ní yóò máa fi adùn jẹun lára rẹ̀,
a kì yóò rántí ènìyàn búburú
    mọ́; Bẹ́ẹ̀ ní a ó sì ṣẹ ìwà búburú bí ẹní ṣẹ́ igi;
21 Ẹni tí o hù ìwà búburú sí àgàn tí
    kò ṣe rere sí opó.
22 Ọlọ́run fi ipá agbára rẹ̀ fa alágbára,
    bí wọ́n tilẹ̀ fìdímúlẹ̀, kò sí ìrètí ìyè fún wọn.
23 Ọlọ́run sì fi àìléwu fún un,
    àti nínú èyí ni a ó sì tì i lẹ́yìn,
    ojú rẹ̀ sì wà ní ipa ọ̀nà wọn.
24 A gbé wọn lékè nígbà díẹ̀, wọ́n kọjá lọ;
    a sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀; A sì mú wọn kúrò ní ọ̀nà bí àwọn ẹlòmíràn,
    a sì ké wọn kúrò bí orí síírí ọkà bàbà.

25 “Ǹjẹ́, bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ nísinsin yìí, ta ni yóò mú mi ní èké,
    tí yóò sì sọ ọ̀rọ̀ mi di aláìníláárí?”

24 “Why does the Almighty not set times(A) for judgment?(B)
    Why must those who know him look in vain for such days?(C)
There are those who move boundary stones;(D)
    they pasture flocks they have stolen.(E)
They drive away the orphan’s donkey
    and take the widow’s ox in pledge.(F)
They thrust the needy(G) from the path
    and force all the poor(H) of the land into hiding.(I)
Like wild donkeys(J) in the desert,
    the poor go about their labor(K) of foraging food;
    the wasteland(L) provides food for their children.
They gather fodder(M) in the fields
    and glean in the vineyards(N) of the wicked.(O)
Lacking clothes, they spend the night naked;
    they have nothing to cover themselves in the cold.(P)
They are drenched(Q) by mountain rains
    and hug(R) the rocks for lack of shelter.(S)
The fatherless(T) child is snatched(U) from the breast;
    the infant of the poor is seized(V) for a debt.(W)
10 Lacking clothes, they go about naked;(X)
    they carry the sheaves,(Y) but still go hungry.
11 They crush olives among the terraces[a];
    they tread the winepresses,(Z) yet suffer thirst.(AA)
12 The groans of the dying rise from the city,
    and the souls of the wounded cry out for help.(AB)
    But God charges no one with wrongdoing.(AC)

13 “There are those who rebel against the light,(AD)
    who do not know its ways
    or stay in its paths.(AE)
14 When daylight is gone, the murderer rises up,
    kills(AF) the poor and needy,(AG)
    and in the night steals forth like a thief.(AH)
15 The eye of the adulterer(AI) watches for dusk;(AJ)
    he thinks, ‘No eye will see me,’(AK)
    and he keeps his face concealed.
16 In the dark, thieves break into houses,(AL)
    but by day they shut themselves in;
    they want nothing to do with the light.(AM)
17 For all of them, midnight is their morning;
    they make friends with the terrors(AN) of darkness.(AO)

18 “Yet they are foam(AP) on the surface of the water;(AQ)
    their portion of the land is cursed,(AR)
    so that no one goes to the vineyards.(AS)
19 As heat and drought snatch away the melted snow,(AT)
    so the grave(AU) snatches away those who have sinned.
20 The womb forgets them,
    the worm(AV) feasts on them;(AW)
the wicked are no longer remembered(AX)
    but are broken like a tree.(AY)
21 They prey on the barren and childless woman,
    and to the widow they show no kindness.(AZ)
22 But God drags away the mighty by his power;(BA)
    though they become established,(BB) they have no assurance of life.(BC)
23 He may let them rest in a feeling of security,(BD)
    but his eyes(BE) are on their ways.(BF)
24 For a little while they are exalted, and then they are gone;(BG)
    they are brought low and gathered up like all others;(BH)
    they are cut off like heads of grain.(BI)

25 “If this is not so, who can prove me false
    and reduce my words to nothing?”(BJ)

Footnotes

  1. Job 24:11 The meaning of the Hebrew for this word is uncertain.