Add parallel Print Page Options

Jobu tẹ̀síwájú nínú àròyé rẹ̀

14 “Ènìyàn tí a bí nínú obìnrin,
    ọlọ́jọ́ díẹ̀ ni, ó sì kún fún ìpọ́njú.
Ó jáde wá bí ìtànná ewéko, a sì ké e lulẹ̀;
    ó sì ń fò lọ bí òjìji, kò sì dúró pẹ́.
Ìwọ sì ń ṣíjú rẹ wò irú èyí ni?
    Ìwọ sì mú mi wá sínú ìdájọ́ pẹ̀lú rẹ?
Ta ni ó lè mú ohun mímọ́ láti inú àìmọ́ jáde wá?
    Kò sí ẹnìkan!
Ǹjẹ́ a ti pinnu ọjọ́ rẹ̀,
    iye oṣù rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ;
    Ìwọ ti pààlà rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ní òun kò le kọjá rẹ̀.
Yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kí ó lè
    sinmi, títí yóò fi pé ọjọ́ rẹ̀ bí alágbàṣe.

“Nítorí pé ìrètí wà fún igi, bí a bá
    ké e lulẹ̀, pé yóò sì tún sọ,
    àti pé ẹ̀ka rẹ̀ tuntun kì yóò gbẹ.
Bí gbòǹgbò rẹ̀ tilẹ̀ di ogbó nínú ilẹ̀,
    tí kùkùté rẹ̀ si kú ni ilẹ̀;
Síbẹ̀ nígbà tí ó bá gbóòórùn omi,
    yóò sọ, yóò sì yọ ẹ̀ka jáde bí irúgbìn.
10 Ṣùgbọ́n ènìyàn kú, a sì dàánù;
    Àní ènìyàn jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́: Òun kò sì sí mọ́.

Àgékúrú ọjọ́ ọmọ ènìyàn

11 “Bí omi ti í tán nínú ipa odò,
    àti bí odò ṣì tí í fà tí sì gbẹ,
12 bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn dùbúlẹ̀ tí kò sì dìde mọ́;
    títí ọ̀run kì yóò fi sí mọ́,
    wọ́n kì yóò jí, a kì yóò jí wọn kúrò lójú oorun wọn.

13 “Háà! ìwọ ìbá fi mí pamọ́ ní ipò òkú,
    kí ìwọ kí ó fi mí pamọ́ ní ìkọ̀kọ̀,
títí ìbínú rẹ yóò fi rékọjá,
    ìwọ ìbá lànà ìgbà kan sílẹ̀ fún mi, kí ó si rántí mi!
14 Bí ènìyàn bá kú yóò sì tún yè bí?
    Gbogbo ọjọ́ ìgbà tí a là sílẹ̀
    fún mi ni èmi dúró dè, títí àmúdọ̀tún mi yóò fi dé.
15 Ìwọ ìbá pè, èmi ìbá sì dá ọ lóhùn;
    ìwọ ó sì ní ìfẹ́ sì iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
16 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ń kaye ìṣísẹ̀ mi;
    ìwọ kò fa ọwọ́ rẹ kúrò nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mi?
17 A fi èdìdì di ìrékọjá mi sínú àpò,
    ìwọ sì rán àìṣedéédéé mi pọ̀.

18 “Àti nítòótọ́ òkè ńlá tí ó ṣubú, ó dasán,
    a sì ṣí àpáta kúrò ní ipò rẹ̀.
19 Omi a máa yinrin òkúta, ìwọ a sì
    mú omi sàn bo ohun tí ó hù jáde lórí ilẹ̀,
    ìwọ sì sọ ìrètí ènìyàn dí òfo.
20 Ìwọ ṣẹ́gun rẹ̀ láéláé, òun sì kọjá lọ!
    Ìwọ pa awọ ojú rẹ̀ dà, o sì rán an lọ kúrò.
21 Àwọn ọmọ rẹ̀ bọ́ sí ipò ọlá, òun kò sì mọ̀;
    wọ́n sì rẹ̀ sílẹ̀, òun kò sì kíyèsi i lára wọn.
22 Ṣùgbọ́n ẹran-ara rẹ̀ ni yóò rí
    ìrora. Ọkàn rẹ̀ ni yóò sì máa ní ìbìnújẹ́ nínú rẹ̀.”

14 “Mortals, born of woman,(A)
    are of few days(B) and full of trouble.(C)
They spring up like flowers(D) and wither away;(E)
    like fleeting shadows,(F) they do not endure.(G)
Do you fix your eye on them?(H)
    Will you bring them[a] before you for judgment?(I)
Who can bring what is pure(J) from the impure?(K)
    No one!(L)
A person’s days are determined;(M)
    you have decreed the number of his months(N)
    and have set limits he cannot exceed.(O)
So look away from him and let him alone,(P)
    till he has put in his time like a hired laborer.(Q)

“At least there is hope for a tree:(R)
    If it is cut down, it will sprout again,
    and its new shoots(S) will not fail.(T)
Its roots may grow old in the ground
    and its stump(U) die in the soil,
yet at the scent of water(V) it will bud
    and put forth shoots like a plant.(W)
10 But a man dies and is laid low;(X)
    he breathes his last and is no more.(Y)
11 As the water of a lake dries up
    or a riverbed becomes parched and dry,(Z)
12 so he lies down and does not rise;(AA)
    till the heavens are no more,(AB) people will not awake
    or be roused from their sleep.(AC)

13 “If only you would hide me in the grave(AD)
    and conceal me till your anger has passed!(AE)
If only you would set me a time
    and then remember(AF) me!(AG)
14 If someone dies, will they live again?
    All the days of my hard service(AH)
    I will wait for my renewal[b](AI) to come.
15 You will call and I will answer you;(AJ)
    you will long for the creature your hands have made.(AK)
16 Surely then you will count my steps(AL)
    but not keep track of my sin.(AM)
17 My offenses will be sealed(AN) up in a bag;(AO)
    you will cover over my sin.(AP)

18 “But as a mountain erodes and crumbles(AQ)
    and as a rock is moved from its place,(AR)
19 as water wears away stones
    and torrents(AS) wash away the soil,(AT)
    so you destroy a person’s hope.(AU)
20 You overpower them once for all, and they are gone;(AV)
    you change their countenance and send them away.(AW)
21 If their children are honored, they do not know it;
    if their offspring are brought low, they do not see it.(AX)
22 They feel but the pain of their own bodies(AY)
    and mourn only for themselves.(AZ)

Footnotes

  1. Job 14:3 Septuagint, Vulgate and Syriac; Hebrew me
  2. Job 14:14 Or release