Add parallel Print Page Options

Ìdáhùn Jobu

12 Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé:

“Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà,
    ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!
Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin:
    èmi kò kéré sí i yín:
    àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?

“Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀,
    tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn:
    à ń fi olóòtítọ́ ẹni ìdúró ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.
Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà,
    gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ẹni tí ẹsẹ̀ wọn ṣetán láti yọ̀.
Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù;
    àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu,
    àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.

“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́,
    àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.
Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ,
    àwọn ẹja inú Òkun yóò sì sọ fún ọ.
Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan
    wọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?
10 Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà,
    Àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.
11 Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí
    tàbí adùn ẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?
12 Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún,
    àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye.

13 “Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára:
    Òun ló ni ìmọ̀ àti òye.
14 Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́;
    Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan.
15 Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ;
    Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.
16 Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun;
    Ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.
17 Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò,
    A sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.
18 Ó tú ìdè ọba,
    Ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.
19 Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò,
    Ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.
20 Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò,
    Ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè.
21 Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá,
    Ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.
22 Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá,
    Ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.
23 Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n;
    Òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.
24 Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé,
    A sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.
25 Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀,
    Òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.

Job

12 Then Job replied:

“Doubtless you are the only people who matter,
    and wisdom will die with you!(A)
But I have a mind as well as you;
    I am not inferior to you.
    Who does not know all these things?(B)

“I have become a laughingstock(C) to my friends,(D)
    though I called on God and he answered(E)
    a mere laughingstock, though righteous and blameless!(F)
Those who are at ease have contempt(G) for misfortune
    as the fate of those whose feet are slipping.(H)
The tents of marauders are undisturbed,(I)
    and those who provoke God are secure(J)
    those God has in his hand.[a]

“But ask the animals, and they will teach you,(K)
    or the birds in the sky,(L) and they will tell you;(M)
or speak to the earth, and it will teach you,
    or let the fish in the sea inform you.
Which of all these does not know(N)
    that the hand of the Lord has done this?(O)
10 In his hand is the life(P) of every creature
    and the breath of all mankind.(Q)
11 Does not the ear test words
    as the tongue tastes food?(R)
12 Is not wisdom found among the aged?(S)
    Does not long life bring understanding?(T)

13 “To God belong wisdom(U) and power;(V)
    counsel and understanding are his.(W)
14 What he tears down(X) cannot be rebuilt;(Y)
    those he imprisons cannot be released.(Z)
15 If he holds back the waters,(AA) there is drought;(AB)
    if he lets them loose, they devastate the land.(AC)
16 To him belong strength and insight;(AD)
    both deceived and deceiver are his.(AE)
17 He leads rulers away stripped(AF)
    and makes fools of judges.(AG)
18 He takes off the shackles(AH) put on by kings
    and ties a loincloth[b] around their waist.(AI)
19 He leads priests away stripped(AJ)
    and overthrows officials long established.(AK)
20 He silences the lips of trusted advisers
    and takes away the discernment of elders.(AL)
21 He pours contempt on nobles(AM)
    and disarms the mighty.(AN)
22 He reveals the deep things of darkness(AO)
    and brings utter darkness(AP) into the light.(AQ)
23 He makes nations great, and destroys them;(AR)
    he enlarges nations,(AS) and disperses them.(AT)
24 He deprives the leaders of the earth of their reason;(AU)
    he makes them wander in a trackless waste.(AV)
25 They grope in darkness with no light;(AW)
    he makes them stagger like drunkards.(AX)

Footnotes

  1. Job 12:6 Or those whose god is in their own hand
  2. Job 12:18 Or shackles of kings / and ties a belt