Jeremiah 6:21-23
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
21 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Èmi yóò gbé ohun ìdènà síwájú
àwọn ènìyàn wọ̀nyí, àwọn baba
àti ọmọ yóò jùmọ̀ ṣubú lù wọ́n,
àwọn aládùúgbò àti ọ̀rẹ́ yóò ṣègbé.”
22 Báyìí ni Olúwa wí:
“Wò ó, àwọn ọmọ-ogun ń bọ̀ wá láti ilẹ̀ àríwá,
a ó sì gbé orílẹ̀-èdè ńlá dìde
láti òpin ayé wá.
23 Wọ́n sì dìmọ́ra pẹ̀lú ọrun àti ọ̀kọ̀,
Wọ́n jẹ́ ẹni ibi, wọn kò sì ní àánú
wọ́n ń hó bí omi Òkun, bí wọ́n
ti ṣe ń gun àwọn ẹṣin wọn lọ;
wọ́n sì wá bí ọkùnrin tí yóò
jà ọ́ lógun, ìwọ ọmọbìnrin Sioni.”
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.